Saamu 44 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 44:1-26

Saamu 44

Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Maskili.

1À ti fi etí wa gbọ́, Ọlọ́run

àwọn baba wa tí sọ fún wa

ohun tí ìwọ ṣe ní ọjọ́ wọn,

ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn.

2Ìwọ fi ọwọ́ rẹ lé orílẹ̀-èdè jáde

Ìwọ sì gbin àwọn baba wa;

Ìwọ run àwọn ènìyàn náà

Ìwọ sì mú àwọn baba wa gbilẹ̀.

3Kì í ṣe nípa idà wọn ni wọ́n gba ilẹ̀ náà,

bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe apá wọn ní ó gbà wọ́n bí kò ṣe;

ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti, apá rẹ;

àti ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ̀, nítorí ìwọ fẹ́ wọn.

4Ìwọ ni ọba àti Ọlọ́run mi,

ẹni tí ó pàṣẹ ìṣẹ́gun fún Jakọbu.

5Nípasẹ̀ rẹ ni àwa ó bi àwọn ọ̀tá wa ṣubú;

nípasẹ̀ orúkọ rẹ ni àwa ó tẹ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wa mọ́lẹ̀

6Èmi kì yóò gbẹ́kẹ̀lé ọrun mi

idà mi kì yóò mú ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wá,

7Ṣùgbọ́n ìwọ fún wa ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wa,

ìwọ sì ti dójúti àwọn tí ó kórìíra wa.

8Nínú Ọlọ́run àwa ń ṣògo ní gbogbo ọjọ́,

àwa ó sì yin orúkọ rẹ títí láé. Sela.

9Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ ti kọ̀ wá, ìwọ sì ti dójútì wá;

Ìwọ kò sì bá àwọn ọmọ-ogun wa jáde mọ́.

10Ìwọ ti bá wa jà,

ìwọ sì ti ṣẹ́gun wa níwájú àwọn ọ̀tá wa,

àwọn ọ̀tá wa ti gba ilẹ̀ wa,

wọ́n sì fi ipá gba oko wa.

11Ìwọ fi wá fún jíjẹ bí ẹran àgùntàn

Ìwọ sì ti tú wa ká sí àárín àwọn kèfèrí.

12Ìwọ ta àwọn ènìyàn rẹ fún owó kékeré,

Ìwọ kò sì jẹ èrè kankan lórí iye tí ìwọ tà wọ́n.

13Ìwọ sọ wá di ẹni ẹ̀sín ní ọ̀dọ̀ àwọn aládùúgbò wa,

ẹlẹ́yà àti ẹni àbùkù sí àwọn tí ó yí wa ká.

14Ìwọ ti sọ wá di ẹni ìfisọ̀rọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè;

àwọn ènìyàn ń mi orí wọn sí wa.

15Ìdójútì mi ń bẹ pẹ̀lú mi ní gbogbo ọjọ́,

ìtìjú sì bojú mi mọ́lẹ̀,

16nítorí ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn

ní ojú àwọn ọ̀tá àti olùgbẹ̀san.

17Gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí ń ṣẹlẹ̀ sí wa,

síbẹ̀ àwa kò gbàgbé rẹ

bẹ́ẹ̀ ni a kò ṣèké sí májẹ̀mú rẹ̀.

18Ọkàn wa kò padà sẹ́yìn;

bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wa kò yẹ̀ kúrò ní ọ̀nà rẹ̀.

19Ṣùgbọ́n wọ́n kọlù wá,

ìwọ sì sọ wá di ẹran ọdẹ fún àwọn ẹranko búburú,

tí wọn sì fi òkùnkùn biribiri bò wá mọ́lẹ̀.

20Bí àwa bá ti gbàgbé orúkọ Ọlọ́run wa

tàbí tí a na ọwọ́ wa sí ọlọ́run àjèjì.

21Ǹjẹ́ Ọlọ́run kì yóò rí ìdí rẹ̀,

níwọ̀n ìgbà tí ó mọ ohun ìkọ̀kọ̀ inú ọkàn?

2244.22: Ro 8.36.Síbẹ̀, nítorí rẹ̀ àwa da àyà kọ ikú, ní ojoojúmọ́

a ń kà wá sí bí àgùntàn fún pípa.

23Jí, Olúwa! Èéṣe tí ìwọ ń sùn?

Dìde fúnrarẹ̀! Má ṣe kọ̀ wá sílẹ̀ láéláé.

24Èéṣe tí ìwọ ń pa ojú rẹ mọ́

tí ìwọ sì gbàgbé ìpọ́njú àti ìnira wa?

25Nítorí a tẹrí ọkàn wa ba sínú eruku;

ara wa sì dì mọ́ erùpẹ̀ ilẹ̀.

26Dìde kí o sì ràn wá lọ́wọ́;

rà wá padà nítorí ìfẹ́ rẹ tí ó dúró ṣinṣin.

New International Reader’s Version

Psalm 44:1-26

Psalm 44

For the director of music. A maskil of the Sons of Korah.

1God, we have heard what you did.

Those who came before us have told us

what you did in their days,

in days long ago.

2By your power you drove out the nations.

You gave our people homes in the land.

You crushed the people who were there.

And you made our people do well.

3They didn’t win the land with their swords.

They didn’t gain success by their own power.

Your powerful right hand and your mighty arm gave them victory.

You gave them success because you loved them.

4You are my King and my God.

You give victories to the people of Jacob.

5With your help we push back our enemies.

By your power we walk all over them.

6I put no trust in my bow.

My sword doesn’t bring me victory.

7But you give us victory over our enemies.

You put them to shame.

8All day long we talk about how great God is.

We will praise your name forever.

9But now you have turned your back on us and made us humble.

You don’t march out with our armies anymore.

10You made us turn and run from our enemies.

They have taken what belongs to us.

11You handed us over to be eaten up like sheep.

You have scattered us among the nations.

12You sold your people for very little.

You didn’t gain anything when you sold them.

13You have made us something that our neighbors laugh at.

Those who live around us make fun of us and tease us.

14The nations make jokes about us.

They shake their heads at us.

15All day long I have to live with my shame.

My face is covered with it.

16That’s because they laugh at me and attack me with their words.

They want to get even with me.

17All of this happened to us,

even though we had not forgotten you.

We had not broken the covenant you made with us.

18Our hearts had not turned away from you.

Our feet had not wandered from your path.

19But you crushed us and left us to the wild dogs.

You covered us over with deep darkness.

20We didn’t forget our God.

We didn’t spread out our hands in prayer to a false god.

21If we had, God would have discovered it.

He knows the secrets of our hearts.

22But because of you, we face death all day long.

We are considered as sheep to be killed.

23Lord, wake up! Why are you sleeping?

Get up! Don’t say no to us forever.

24Why do you turn your face away from us?

Why do you forget our pain and troubles?

25We are brought down to the dust.

Our bodies lie flat on the ground.

26Rise up and help us.

Save us because of your faithful love.