Saamu 37 – YCB & HTB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 37:1-40

Saamu 37

Ti Dafidi.

1Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú,

kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;

2nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko,

wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.

3Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, kí o sì máa ṣe rere;

torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.

4Ṣe inú dídùn sí Olúwa;

òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.

5Fi ọ̀nà rẹ lé Olúwa lọ́wọ́;

gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.

6Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀,

àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.

7Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa,

kí o sì fi sùúrù dúró dè é;

má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn,

nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.

8Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀,

má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.

9Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò,

ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwa àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.

10Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀;

nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.

11Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà,

wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.

12Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́,

wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;

13ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú,

nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.

14Ènìyàn búburú fa idà yọ,

wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn,

láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀,

láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.

15Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ,

àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.

16Ohun díẹ̀ tí olódodo ní,

sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;

17nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú,

ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.

18Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin,

àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé;

19Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi,

àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.

20Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé.

Àwọn ọ̀tá Olúwa yóò dàbí ẹwà oko tútù;

wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.

21Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà,

ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;

22Nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà,

àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.

23Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá,

o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;

24Bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá,

nítorí tí Olúwa di ọwọ́ rẹ̀ mú.

25Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà;

síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀,

tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.

26Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni;

a sì máa bùsi i fún ni.

27Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere;

nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.

28Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́,

kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀.

Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé,

ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.

29Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà,

yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.

30Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n,

ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.

31Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn;

àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.

32Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo,

Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.

33Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi,

nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.

34Dúró de Olúwa,

kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́.

Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà;

nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.

35Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà,

ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,

36ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́;

bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.

37Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin;

nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.

38Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀;

ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.

39Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa;

òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú

40Olúwa yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n;

yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là,

nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.

Het Boek

Psalmen 37:1-40

1Een lied van David.

Erger u niet aan zondaars,

aan mensen die slechte dingen doen.

2Zij verdwijnen net zo snel als het gras

en verwelken als eendagsbloemen.

3Stel heel uw vertrouwen op de Here

en doe wat Hij goed vindt.

Woon rustig in uw woonplaats

en zorg dat u in alles trouw bent.

4Verheug u in de Here,

dan zal Hij u geven wat u nodig hebt

en waar u naar verlangt.

5Vertel alles wat u bezighoudt aan de Here

en vertrouw Hem.

Hij zal in alles voor u zorgen.

6Hij zal u openlijk recht verschaffen

en uw oprechtheid aan het licht brengen.

7Word stil voor de Here

en verwacht alles van Hem.

Wees niet jaloers op wie slechte plannen beraamt

en wie het ogenschijnlijk goed gaat.

8Word niet boos

en laat elke vorm van kwaadheid schieten,

wees ook nooit jaloers,

want dat brengt u van kwaad tot erger.

9Eenmaal worden alle zondaars vernietigd,

maar wie uitzien naar de Here,

zullen alles ontvangen wat zij nodig hebben.

10Nog een klein poosje

en dan zal de zondaar zijn verdwenen,

dan zoekt u hem

en ziet u hem niet meer.

11Maar wie nederig van hart is,

zal in het land mogen wonen

en genieten van een overvloedige vrede.

12De goddeloze beraamt

slechte plannen tegen de gelovige,

hij kan hem niet verdragen.

13Maar de Here lacht erom,

Hij weet dat zijn tijd is gekomen.

14De zondaars grijpen naar de wapens

om arme mensen te doden

en de gelovigen te vernietigen.

15Zij zullen echter door hun eigen geweld worden vernietigd

en hun wapens zullen kapot op de grond liggen.

16Het is beter met een eerlijk hart

weinig te bezitten

dan veel rijkdom te hebben

en God niet te kennen.

17Want de Here zal

de goddelozen machteloos maken

en oprechte mensen ondersteunen.

18De Here zorgt voor zijn volgelingen

en er wacht hun een geweldige toekomst.

19In moeilijke momenten

zal Hij hen niet in de steek laten.

Wanneer er hongersnood is,

zal Hij voor voedsel zorgen.

20De goddeloze zal te gronde gaan.

De tegenstanders van de Here

zullen verdwijnen als bloemen op het veld,

in rook opgaan.

21De goddeloze leent wel,

maar geeft nooit terug.

Maar de oprechte mens

bekommert zich om een ander

en geeft wat nodig is.

22Het is werkelijk waar:

zij die door God gezegend zijn,

mogen in het land wonen en het bezitten.

Maar wie Hij vervloekt,

wordt vernietigd.

23Als de Here instemt met iemands wijze van leven,

zal Hij hem bevestigen in alles wat hij doet.

24Als zo iemand valt,

stort hij niet naar beneden,

omdat de Here zijn hand vasthoudt.

25Gedurende mijn hele, lange leven

heb ik nog nooit een oprecht iemand gezien

die door de Here werd verlaten.

En ook diens kinderen ontbrak het aan niets.

26Zo iemand bekommert zich om anderen

en geeft wat nodig is,

ook zijn kinderen helpen waar dat nodig is.

27Houd u ver van het kwaad en doe wat goed is,

want dan zult u altijd in dit land kunnen wonen.

28De Here heeft oprechtheid lief

en Hij zal zijn volgelingen nooit in de steek laten.

Hij zal hen altijd bewaren en beschermen.

Maar de goddelozen vernietigt Hij.

29De oprechte mensen mogen het land in bezit nemen

en er altijd blijven wonen.

30De oprechte mens spreekt wijze woorden

en alles wat hij zegt, is eerlijk.

31In alles geldt voor hem de wet van God.

Hij raakt nooit uit zijn evenwicht.

32De goddeloze zoekt naar een gelegenheid

om de oprechte mens te vermoorden.

33De Here laat dat niet toe.

De Here zorgt ervoor dat hij,

als hij voor de rechter moet verschijnen,

niet wordt veroordeeld.

34Zie onder alles uit naar de Here

en blijf op zijn weg.

Dan zal Hij u uitkiezen om het land in bezit te nemen

en er altijd te wonen,

en u zult de vernietiging van de goddelozen meemaken.

35Ik zag eens een goddeloos mens.

Het leek heel wat

en hij breidde zich uit als een grote woekerplant,

36maar opeens was hij weg.

Ik zocht nog naar hem,

maar kon hem niet vinden.

37Kijk maar eens naar de gelovige

en let op de oprechte mens:

vredelievende mensen hebben de toekomst.

38De zondaars worden echter allemaal vernietigd,

ook hun kinderen hebben geen toekomst.

39Maar de redding van de oprechten komt van de Here,

Hij beschermt hen in moeilijke tijden.

40De Here helpt hen ontkomen aan de goddelozen

en bevrijdt hen.

Dat komt doordat zij bij Hem schuilen.