Saamu 26 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 26:1-12

Saamu 26

Ti Dafidi.

1Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa,

nítorí tí mo ti ń rìn nínú ìwà òtítọ́ ọ̀ mi,

mo sì ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa

Ǹjẹ́ ẹsẹ̀ mi kì yóò yẹ̀.

2Wádìí mi wò, Ìwọ Olúwa, kí o sì dán mi wò,

dán àyà àti ọkàn mi wò;

3Nítorí ìfẹ́ ẹ̀ rẹ tí ó dúró ṣinṣin ń bẹ níwájú mi,

èmí sì ti rìn nínú òtítọ́ rẹ.

4Èmi kò jókòó pẹ̀lú aláìṣòótọ́,

bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò bá àwọn àgàbàgebè wọlé;

5Èmi ti kórìíra àwùjọ àwọn ènìyàn búburú

èmi kì yóò sì bá àwọn ènìyàn ìkà jókòó.

6Èmí ó wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀,

bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò sì yí pẹpẹ rẹ ká Olúwa.

7Èmi yóò kọrin sókè àní orin ọpẹ́,

èmi yóò sì máa sọ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.

8Háà Olúwa, èmí ń fẹ́ ilé rẹ níbi tí ìwọ ń gbé,

àní níbi tí ògo rẹ̀ wà.

9Má ṣe gbá mi dànù pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,

tàbí ẹ̀mí mi pẹ̀lú àwọn ọkùnrin tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ,

10Àwọn tí ọwọ́ wọn kún fún ìwà ibi,

tí ọwọ́ ọ̀tún wọn kún fún àbẹ̀tẹ́lẹ̀.

11Ṣùgbọ́n èmi ó máa rìn nínú ìwà títọ́;

rà mí padà, kí o sì ṣàánú fún mi.

12Ẹsẹ̀ mi dúró lórí ilẹ̀ tí ó tẹ́jú;

nínú ìjọ ńlá èmi yóò fi ìbùkún fún Olúwa.