Saamu 11 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 11:1-7

Saamu 11

Fún adarí orin. Ti Dafidi.

1Ìgbẹ́kẹ̀lé mi wà nínú Olúwa.

Báwo ní ẹ̀yin ó ṣe sọ fún ọkàn mi pé:

“Fò gẹ́gẹ́ bi ẹyẹ lọ si orí òkè rẹ.

2Wò ó nítorí náà, ènìyàn búburú fa ọfà rẹ̀;

wọn ti fi ọfà wọn sí ojú okùn

láti tafà níbi òjìji

sí àyà ẹni ìdúró ṣinṣin.

3Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́

kí ni olódodo yóò ṣe?”

4Olúwa ń bẹ nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀;

Olúwa ń bẹ lórí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọ̀run.

Ó ń wo àwọn ọmọ ènìyàn;

ojú rẹ̀ ń yẹ̀ wọ́n wò.

5Olúwa ń yẹ olódodo wò,

ṣùgbọ́n ènìyàn búburú àti àwọn tí o fẹ́ ìwà ipá

ni ọkàn rẹ̀ kórìíra.

6Sí orí àwọn ènìyàn búburú ni yóò rọ̀jò

ẹ̀yín iná àti imí-ọjọ́ tí ń jó;

àti ìjì gbígbóná ní yóò jẹ ìpín wọn.

7Nítorí, olódodo ní Olúwa,

o fẹ́ràn òdodo;

ẹni ìdúró ṣinṣin yóò sì rí i.

New International Reader’s Version

Psalm 11:1-7

Psalm 11

For the director of music. A psalm of David.

1I run to the Lord for safety.

So how can you say to me,

“Fly away like a bird to your mountain.

2Look! Evil people are bending their bows.

They are placing their arrows against the strings.

They are planning to shoot from the shadows

at those who have honest hearts.

3When law and order are being destroyed,

what can godly people do?”

4The Lord is in his holy temple.

The Lord is on his throne in heaven.

He watches everyone on earth.

His eyes study them.

5The Lord watches over those who do what is right.

But he really hates sinful people and those who love to hurt others.

6He will pour out flaming coals and burning sulfur

on those who do what is wrong.

A hot and dry wind will destroy them.

7The Lord always does what is right.

So he loves it when people do what is fair.

Those who are honest will enjoy his blessing.