Rutu 4 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Rutu 4:1-22

Boasi gbé Rutu ní ìyàwó

1Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.

2Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀, 3ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa. 4Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.”

Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”

5Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”

6Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”

74.7: De 25.8-10.Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.

8Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnrarẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.

9Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi. 10Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”

11Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu. 12Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”

Èyí ni ìran Dafidi

13Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan. 14Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli. 15Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”

16Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀. 17Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.

18Èyí ni ìran Peresi:

Peresi ni baba Hesroni,

19Hesroni ni baba Ramu,

Ramu ni baba Amminadabu

20Amminadabu ni baba Nahiṣoni,

Nahiṣoni ni baba Salmoni,

21Salmoni ni baba Boasi,

Boasi ni baba Obedi,

22Obedi ní baba Jese,

Jese ni baba Dafidi.

Persian Contemporary Bible

روت 4:1-22

ازدواج بوعز با روت

1بوعز به دروازهٔ شهر كه محل اجتماع مردم شهر بود رفت و در آنجا نشست. آنگاه آن مرد كه نزديكترين خويشاوند شوهر نعومی بود به آنجا آمد. بوعز او را صدا زده گفت: «بيا اينجا! می‌خواهم چند كلمه‌ای با تو صحبت كنم.» او آمد و نزد بوعز نشست. 2آنگاه بوعز ده نفر از ريش‌سفيدان شهر را دعوت كرد تا شاهد باشند.

3بوعز به خويشاوند خود گفت: «تو می‌دانی كه نعومی از سرزمين موآب برگشته است. او در نظر دارد ملک برادرمان اليملک را بفروشد. 4فكر كردم بهتر است در اين باره با تو صحبت كنم تا اگر مايل باشی، در حضور اين جمع آن را خريداری نمايی. اگر خريدار آن هستی همين حالا بگو. در غير اين صورت خودم آن را می‌خرم. اما تو بر من مقدم هستی و بعد از تو حق من است كه آن ملک را خريداری نمايم.»

آن مرد جواب داد: «بسيار خوب، من آن را می‌خرم.»

5بوعز به او گفت: «تو كه زمين را می‌خری موظف هستی با روت نيز ازدواج كنی تا بچه‌دار شود و فرزندانش وارث آن زمين گردند و به اين وسيله نام شوهرش زنده بماند.»

6آن مرد گفت: «در اين صورت من از حق خريد زمين می‌گذرم، زيرا فرزند روت وارث ملک من نيز خواهد بود. تو آن را خريداری كن.»

7(در آن روزگار در اسرائيل مرسوم بود كه هرگاه شخصی می‌خواست حق خريد ملكی را به ديگری واگذار كند، كفشش را از پا در می‌آورند و به او می‌داد. اين عمل، معامله را در نظر مردم معتبر می‌ساخت.)

8پس آن مرد وقتی به بوعز گفت: «تو آن زمين را خريداری كن»، كفشش را از پا درآورد و به او داد.

9آنگاه بوعز به ريش‌سفيدان محل و مردمی كه در آنجا ايستاده بودند گفت: «شما شاهد باشيد كه امروز من تمام املاک اليملک، كليون و محلون را از نعومی خريدم. 10در ضمن با روت موآبی، زن بيوهٔ محلون ازدواج خواهم كرد تا او پسری بياورد كه وارث شوهر مرحومش گردد و به اين وسيله نام او در خاندان و در زادگاهش زنده بماند.»

11همهٔ ريش‌سفيدان و مردمی كه در آنجا بودند گفتند: «ما شاهد بر اين معامله هستيم. خداوند اين زنی را كه به خانهٔ تو خواهد آمد، مانند راحيل و ليه بسازد كه فرزندانی برای يعقوب آوردند. باشد كه تو در افراته و بيت‌لحم معروف و كامياب شوی. 12با فرزندانی كه خداوند بوسيلهٔ اين زن به تو می‌بخشد، خاندان تو مانند خاندان فارَص پسر تامار و يهودا باشد.»

نسب نامهٔ داوود پادشاه

13پس بوعز با روت ازدواج كرد و خداوند به آنها پسری بخشيد. 14زنان شهر بيت‌لحم به نعومی گفتند: «سپاس بر خداوند كه تو را بی‌سرپرست نگذاشت و نوه‌ای به تو بخشيد. باشد كه او در اسرائيل معروف شود. 15عروست كه تو را دوست می‌دارد و برای تو از هفت پسر بهتر بوده، پسری به دنیا آورده است. اين پسر جان تو را تازه خواهد كرد و در هنگام پيری از تو مراقبت خواهد نمود.»

16نعومی نوزاد را در آغوش گرفت و دايهٔ او شد. 17زنان همسايه آن نوزاد را عوبيد ناميده گفتند: «پسری برای نعومی متولد شد!» (عوبيد پدر يسی و پدر بزرگ داوود پادشاه است.)

18‏-22اين است نسب نامهٔ بوعز كه از فارص شروع شده، به داوود ختم می‌شود: فارص، حصرون، رام، عميناداب، نحشون، سلمون، بوعز، عوبيد، يسی و داوود.