Orin Solomoni 3 – YCB & NAV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Orin Solomoni 3:1-11

1Ní orí ibùsùn mi ní òru

mo wá ẹni tí ọkàn mí fẹ́;

mo wá a, ṣùgbọ́n èmi kò rí i.

2Èmi yóò dìde nísinsin yìí, èmi yóò sì rìn lọ káàkiri ìlú,

ní àwọn òpópónà àti ní àwọn gbangba òde;

Èmi yóò wá ẹni tí ọkàn mi fẹ́.

Bẹ́ẹ̀ ni mo wá a ṣùgbọ́n èmi kò rí i.

3Àwọn ọdẹ tí ń ṣọ́ ìlú rí mi

bí wọ́n ṣe ń rìn yíká ìlú.

“Ǹjẹ́ ìwọ ti rí ẹni tí ọkàn mi fẹ́?”

4Gẹ́rẹ́ tí mo fi wọ́n sílẹ̀

ni mo rí ẹni tí ọkàn mi fẹ́.

Mo dìímú, èmi kò sì jẹ́ kí ó lọ

títí tí mo fi mú u wá sílé ìyá mi,

sínú yàrá ẹni tí ó lóyún mi

5Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu,

Mo fi àwọn abo egbin àti abo àgbọ̀nrín igbó fi yín bú

kí ẹ má ṣe rú olùfẹ́ mi sókè

kí ẹ má sì ṣe jí i títí yóò fi wù ú.

6Ta ni ẹni tí ń ti ijù jáde wá

bí ọ̀wọ̀n èéfín

tí a ti fi òjìá àti tùràrí kùn lára

pẹ̀lú gbogbo ìpara olóòórùn oníṣòwò?

7Wò ó! Àkéte rẹ̀ tí í ṣe ti Solomoni,

àwọn akọni ọgọ́ta ni ó wà yí i ká,

àwọn akọni Israẹli,

8Gbogbo wọn ni ó mú idà lọ́wọ́,

gbogbo wọn ní ìmọ̀ nínú ogun,

idà oníkálùkù wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀,

wọ́n múra sílẹ̀ fún ìdágìrì òru

9Solomoni ọba ṣe àkéte fún ara rẹ̀;

o fi igi Lebanoni ṣe é.

10Ó fi fàdákà ṣe òpó rẹ̀

o fi wúrà ṣe ibi ẹ̀yìn rẹ̀

Ó fi elése àlùkò ṣe ibùjókòó rẹ̀,

inú rẹ̀ ni ó ko àwọn ọ̀rọ̀ ìfẹ́ wọ̀nyí sí

“Pẹ̀lú ìfẹ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Jerusalẹmu.”

11Ẹ jáde wá, ẹ̀yin ọmọbìnrin Sioni,

kí ẹ sì wo ọba Solomoni tí ó dé adé,

adé tí ìyá rẹ̀ fi dé e

ní ọjọ́ ìgbéyàwó rẹ̀,

ní ọjọ́ ayọ̀ ọkàn rẹ̀.

Ketab El Hayat

نشيد الأنشاد 3:1-11

1(الْمَحْبُوبَةُ): طَوَالَ اللَّيْلِ عَلَى مَضْجَعِي طَلَبْتُ بِشَوْقٍ مَنْ تُحِبُّهُ نَفْسِي، فَمَا وَجَدْتُهُ. 2سَأَنْهَضُ الآنَ أَطُوفُ فِي الْمَدِينَةِ وَأَتَجَوَّلُ فِي شَوَارِعِهَا وَسَاحَاتِهَا، أَلْتَمِسُ مَنْ تُحِبُّهُ نَفْسِي. وَهَكَذَا رُحْتُ أَلْتَمِسُهُ فَمَا وَجَدْتُهُ. 3وَعَثَرَ عَلَيَّ الْحُرَّاسُ الْمُتَجَوِّلُونَ فِي الْمَدِينَةِ، فَسَأَلْتُ: أَشَاهَدْتُمْ مَنْ تُحِبُّهُ نَفْسِي؟ 4وَمَا كِدْتُ أَتَجَاوَزُهُمْ حَتَّى وَجَدْتُ مَنْ تُحِبُّهُ نَفْسِي، فَتَشَبَّثْتُ بِهِ وَلَمْ أُطْلِقْهُ حَتَّى أَدْخَلْتُهُ بَيْتَ أُمِّي وَمُخْدَعَ مَنْ حَمَلَتْ بِي. 5أَسْتَحْلِفُكُنَّ يَا بَنَاتِ أُورُشَلِيمَ بِظِبَاءِ الصَّحْرَاءِ وَأَيَائِلِهَا أَلّا تُوْقِظْنَ أَوْ تُنَبِّهْنَ الْحَبِيبَ حَتَّى يَشَاءَ.

6(نَشِيدُ بَنَاتِ أُورُشَلِيمَ): مَنْ هَذِهِ الصَّاعِدَةُ مِنَ الْقَفْرِ كَأَعْمِدَةٍ مِنْ دُخَانٍ مُعَطَّرَةٍ بِالْمُرِّ وَاللُّبَانِ وَكُلِّ عُطُورِ التَّاجِرِ؟

7هَا هِيَ أَرِيكَةُ سُلَيْمَانَ يَحِفُّ بِهِ سِتُّونَ بَطَلاً مِنْ جَبَابِرَةِ إِسْرَائِيلَ. 8جَمِيعُهُمْ مُدَجَّجُونَ بِالسُّيُوفِ مُتَمَرِّسُونَ عَلَى الْحَربِ، تَتَدَلَّى سُيُوفُهُمْ عَلَى جَوَانِبِهِمْ تَأَهُّباً لأَهْوَالِ اللَّيْلِ.

9قَدْ صَنَعَ الْمَلِكُ سُلَيْمَانُ كُرْسِيَّ الْعَرْشِ مِنْ خَشَبِ لُبْنَانَ. 10وَصَنَعَ أَعْمِدَتَهُ فِضَّةً وَمُتَّكَأَهُ ذَهَباً وَمَقْعَدَهُ أُرْجُوَاناً، وَغِطَاؤُهْ الدَّاخِلِيُّ رَصَّعَتْهُ بَنَاتُ أُورُشَلِيمَ مَحَبَّةً.

11(الْمَحْبُوبَةُ): اُخْرُجْنَ يَا بَنَاتِ صِهْيَوْنَ وَانْظُرْنَ الْمَلِكَ سُلَيْمَانَ مُكَلَّلاً بِالتَّاجِ الَّذِي تَوَّجَتْهُ بِهِ أَمُّهُ فِي يَوْمِ عُرْسِهِ، فِي يَوْمِ بَهَجَةِ قَلْبِهِ.