Nehemiah 1 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 1:1-11

Àdúrà Nehemiah

1Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah:

Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa, 2Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.

3Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”

4Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run. 5Nígbà náà ni mo wí pé:

Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́. 6Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ. 7Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.

8“Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè. 9Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’

10“Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ. 11Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì ṣíjú àánú wò ó níwájú Ọkùnrin yìí.”

Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.

Swedish Contemporary Bible

Nehemja 1:1-11

Muren byggs upp

(1:1—7:3)

Nehemja återvänder till Jerusalem

Dåliga nyheter från Jerusalem

1Nehemjas, Hakaljas sons, berättelse.

I månaden kislev, under det tjugonde året1:1 Syftar troligen på den persiske kungen Artaxerxes I:s tjugonde regeringsår., var jag i Susans borg. 2Då kom Hanani, en av mina bröder, dit tillsammans med några män från Juda. Jag frågade dem om judarna som var kvar efter fångenskapen och hur det stod till i Jerusalem.

3De svarade mig: ”De som är kvar efter fångenskapen och befinner sig i provinsen är i nöd och vanära. Jerusalems mur är nedriven, och dess portar uppbrända.”

Nehemja ber för Israel

4När jag fick höra detta, satte jag mig ner och grät. Under flera dagar sörjde och fastade jag och bad till himlens Gud.

5Jag sa:

Herre, himlens Gud, du store och fruktansvärde Gud, du håller förbundet och är nådig mot dem som älskar dig och håller dina bud. 6Låt ditt öra och dina ögon vara öppna för din tjänares bön, som din tjänare natt och dag ber för dina tjänare israeliterna. Jag bekänner de synder som vi israeliter har begått mot dig. Även jag och min fars familj har syndat mot dig. 7Vi har gjort mycket ont gentemot dig. Vi har inte lytt dina bud, stadgar och lagar som du gav din tjänare Mose.

8Kom ihåg vad du sa till din tjänare Mose: ’Om ni är trolösa ska jag skingra er bland folken, 9men om ni vänder tillbaka till mig och håller mina bud och följer dem, ska jag samla er igen, även om ni blivit förvisade bort till de mest avlägsna delar av världen. Jag ska samla dem och föra dem tillbaka till den plats jag har utvalt, där mitt namn ska bo.’

10De är ju dina tjänare och ditt folk som du befriat genom din stora makt och styrka. 11Herre, hör din tjänares bön och dina tjänares böner, deras som gläder sig i att frukta ditt namn. Ge nu mig, din tjänare, framgång och låt mig få möta välvilja inför denne man.”

Jag var vid den tiden kungens munskänk.