Nehemiah 1 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 1:1-11

Àdúrà Nehemiah

1Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah:

Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa, 2Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.

3Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”

4Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run. 5Nígbà náà ni mo wí pé:

Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́. 6Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ. 7Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.

8“Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè. 9Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’

10“Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ. 11Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì ṣíjú àánú wò ó níwájú Ọkùnrin yìí.”

Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.

Bibelen på hverdagsdansk

Nehemiasʼ Bog 1:1-11

Nehemias’ bøn for Jerusalem

1-2Denne beretning er skrevet af Nehemias, søn af Hakalja.

Jeg arbejdede som mundskænk for kong Artaxerxes af Persien i det kongelige palads i Susa. I kislev1,1-2 Årets niende måned, svarende til november-december. måned i hans 20. regeringsår fik jeg besøg af en af mine slægtninge ved navn Hanani og nogle andre mænd, der lige var kommet fra Juda. Jeg spurgte dem, hvordan det gik med alle de judæere, der var vendt tilbage fra eksilet, og hvordan det stod til i Jerusalem.

3„Det går rigtig dårligt,” svarede de. „Folk lever i stor nød og elendighed. Jerusalems mur ligger stadig i ruiner, og de nedbrændte porte er ikke blevet istandsat.”

4Da jeg hørte det, satte jeg mig ned og græd og sørgede i flere dage, mens jeg fastede og bad til Himlens Gud.

5„Herre, du store og almægtige Gud!” bad jeg. „Vi ved, at du er en Gud, der holder dine pagtsløfter og er trofast over for dem, der elsker dig og adlyder dine befalinger. 6-7Hør nu din tjeners bøn, lyt til, hvad jeg har på hjerte. Se i nåde til mig, mens jeg dag og nat går i forbøn for dit folk Israel! Jeg erkender, at Israels folk har syndet imod dig, ja også jeg og min familie har syndet ved ikke at adlyde de befalinger, love og forskrifter, som du gav os gennem din tjener Moses. 8Opfyld nu det løfte du i sin tid gav Moses. Du sagde godt nok, at hvis vi var troløse over for dig, ville du sprede os blandt folkene. 9Men du sagde også, at hvis vi erkendte vores synder og lovede at adlyde dine befalinger, ville du føre os tilbage til Jerusalem—det sted, du har udvalgt til din bolig—om du så skulle hente os fra verdens fjerneste afkroge.

10Herre, vi er dine tjenere—det folk, du befriede ved din vældige magt. 11Hør nu min bøn! Lyt til dem, som ønsker at ære dig! Vær med mig, når jeg træder frem for kongen for at bede ham gøre mig en tjeneste. Gør ham venligt stemt over for min anmodning.”