Nehemiah 1 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 1:1-11

Àdúrà Nehemiah

1Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah:

Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa, 2Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.

3Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”

4Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run. 5Nígbà náà ni mo wí pé:

Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́. 6Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ. 7Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.

8“Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè. 9Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’

10“Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ. 11Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì ṣíjú àánú wò ó níwájú Ọkùnrin yìí.”

Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.

La Bible du Semeur

Néhémie 1:1-11

Néhémie reçoit des nouvelles de Jérusalem

1Histoire de Néhémie, fils de Hakalia. La vingtième année du règne d’Artaxerxès1.1 En 446 av. J.-C. (Artaxerxès Ier a régné de 465 à 424 av. J.-C.), 91 ans après le retour des premiers exilés. Les mots : du règne d’Artaxerxès ne se trouvent pas dans l’hébreu. Ils sont rajoutés d’après 2.1., au mois de Kislev1.1 En novembre-décembre., je me trouvais dans la citadelle de Suse1.1 Résidence d’hiver des rois perses, dans la vallée ensoleillée du Tigre (voir Est 1.2).. 2Hanani, l’un de mes parents, arriva avec un groupe d’hommes de Juda. Je leur demandai des nouvelles du reste des Juifs revenus d’exil, et de Jérusalem. 3Ils me répondirent : Ceux qui ont survécu à la captivité et qui vivent dans le district de Juda1.3 Voir note sur Esd 2.1. se trouvent dans une grande misère et dans une situation très humiliante ; il y a des brèches dans la muraille de Jérusalem et ses portes ont été détruites par le feu.

Prière

4Lorsque j’entendis ces nouvelles, je m’assis et me mis à pleurer. Pendant plusieurs jours, je restai abattu. Je jeûnai et je priai constamment devant le Dieu du ciel. 5Je suppliai : Ah ! Eternel, Dieu du ciel, Dieu grand et redoutable, toi qui restes fidèle à ton alliance et qui conserves ta bienveillance à ceux qui t’aiment et qui obéissent à tes commandements, 6prête attention à la prière de ton serviteur ! Que tes yeux soient ouverts pour voir que je suis en prière devant toi en ce moment, jour et nuit, pour intercéder en faveur de tes serviteurs les Israélites et pour confesser leurs péchés. Car nous avons péché contre toi. Oui, moi et mon peuple, nous avons péché. 7Nous sommes vraiment coupables envers toi, car nous avons désobéi aux commandements, aux ordonnances et aux lois que tu as donnés à Moïse, ton serviteur.

8Souviens-toi, cependant, je te prie, de ces paroles que tu as ordonné à ton serviteur Moïse de prononcer : « Lorsque vous serez infidèles, je vous disperserai parmi d’autres peuples1.8 Pour les v. 8-9, voir Lv 26.33 ; Dt 4.27 ; 28.64 ; 30.1-5.. 9Mais si vous revenez à moi pour obéir à mes commandements et les appliquer, alors, même si vous vous trouvez éloignés jusqu’aux extrémités de la terre, je vous rassemblerai, et je vous ramènerai de là au lieu que j’ai choisi pour y établir ma présence. » 10Ils sont tes serviteurs et ton peuple, que tu as délivrés par ta grande force et par tes interventions puissantes. 11Je t’en prie, Seigneur, veuille prêter attention à la prière de ton serviteur et à celle de tes autres serviteurs qui désirent te craindre ! De grâce, fais réussir aujourd’hui la démarche que je vais entreprendre et que cet homme1.11 C’est-à-dire le roi Artaxerxès dont Néhémie était l’échanson. m’accueille avec compassion !

Or, à cette époque, j’étais chargé de servir les boissons à la table de l’empereur.