Nahumu 1 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nahumu 1:1-15

1Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ nípa Ninefe. Ìwé ìran Nahumu ará Elkoṣi.

Ìbínú Olúwa sí Ninefe

2Ọlọ́run ń jẹ owú, ó sì ń gbẹ̀san.

Olúwa ń gbẹ̀san, ó sì kún fún ìbínú

Olúwa ń gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀,

Ìbínú rẹ̀ kò sì yí padà lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀

31.3: Isa 10.5-34; Sf 2.12-15.Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì tóbi ní agbára;

Olúwa kì yóò fi àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sílẹ̀ láìjìyà.

Ọ̀nà rẹ̀ wà nínú afẹ́fẹ́ àti nínú ìjì,

Ìkùùkuu sánmọ̀ sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.

4Ó bá Òkun wí, ó sì mú kí ó gbẹ;

Ó sìsọ gbogbo odò di gbígbẹ.

Baṣani àti Karmeli sì rọ,

Ìtànná Lebanoni sì rẹ̀ sílẹ̀.

5Àwọn òkè ńlá wárìrì níwájú rẹ̀,

àwọn òkè kéékèèkéé sì di yíyọ́,

ilẹ̀ ayé sì jóná níwájú rẹ̀,

àní ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

6Ta ni ó lé dúró níwájú ìbínú rẹ̀?

Ta ni ó lé faradà gbígbóná ìbínú rẹ̀?

Ìbínú rẹ̀ tú jáde bí iná;

àwọn àpáta sì fọ́ túútúú níwájú rẹ̀.

7Rere ni Olúwa,

òun ni ààbò ní ọjọ́ ìpọ́njú.

Òun sì tọ́jú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e,

8Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìkún omi ńlá

ní òun yóò fi ṣe ìparun láti ibẹ̀ dé òpin;

òkùnkùn yóò sì máa lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀.

9Kí ni ẹ̀yìn ń gbìmọ̀ lòdì sí Olúwa?

Òun yóò fi òpin sí i,

ìpọ́njú kì yóò wáyé ní ìgbà kejì

10Wọn yóò sì lọ́lù papọ̀ bí ẹ̀gún òṣùṣú

wọn yóò sì mu àmupara nínú ọtí wáìnì wọn

a ó sì run wọn gẹ́gẹ́ bi àgékù koríko gbígbẹ

11Láti ọ̀dọ̀ rẹ, ìwọ Ninefe, ni ẹnìkan ti jáde wá

tí ó ń gbèrò ibi sí Olúwa

ti ó sì ń gbìmọ̀ búburú.

12Báyìí ni Olúwa wí:

“Bí wọ́n tilẹ̀ ni ìfọwọ́sowọ́pọ̀, tí wọ́n sì pọ̀ níye,

Ṣùgbọ́n, báyìí ní a ó ké wọn lulẹ̀,

nígbà tí òun ó bá kọjá.

Bí mo tilẹ̀ ti pọ́n ọ lójú ìwọ Juda, èmi kì yóò pọ́n ọ lójú mọ́.

13Nísinsin yìí ni èmi yóò já àjàgà wọn kúrò ní ọrùn rẹ

èmi yóò já ṣẹkẹ́ṣẹkẹ̀ rẹ dànù.”

14Olúwa ti fi àṣẹ kan lélẹ̀ nítorí tìrẹ Ninefe:

“Ìwọ kì yóò ni irú-ọmọ láti máa jẹ́ orúkọ rẹ mọ́,

Èmi yóò pa ère fínfín àti ère dídà run

tí ó wà nínú tẹmpili àwọn ọlọ́run rẹ.

Èmi yóò wa ibojì rẹ,

nítorí ẹ̀gbin ni ìwọ.”

151.15: Isa 40.9; 52.7; Ap 10.36; Ro 10.15.Wò ó, lórí àwọn òkè,

àwọn ẹsẹ̀ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ̀ wá,

ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà,

Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ́,

kí ó sì san àwọn ẹ̀jẹ́ rẹ.

Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ́ mọ́;

wọn yóò sì parun pátápátá.

Bibelen på hverdagsdansk

Nahums Bog 1:1-14

Herrens dom over Nineve og trøst til Juda

1Nahum fra Elkosh modtog følgende budskab fra Herren om Nineves undergang:

2Herren er en nidkær Gud,

som straffer fjendens ondskab.

Han er ikke bange for at vise sin vrede

og afsige en hård dom over sine modstandere.

3Der skal meget til, før han bliver vred,

men hans magt er stor, og han straffer de skyldige.

Når han går til angreb, er det med orkanagtig styrke,

stormskyerne er som støv fra hans fødder.

4Når han truer ad havet, tørrer det ud,

han tørlægger alle floder.

Bashans og Karmels frodige marker svides af,

og blomsterne visner i Libanons bjerge.

5Når Herren rykker frem, skælver bjergene,

og højene dukker sig,

hele jorden bæver,

og alle dens indbyggere gyser.

6Hvem kan holde stand mod hans vrede?

Hvem kan standse hans harme?

Hans glødende vrede vælder frem som ild.

Selv bjergene splintres i småstykker.

7Men Herren er god mod dem, der søger ham,

han værner dem mod deres fjender.

Han beskytter alle,

der søger ly hos ham.

8Men de, der sætter sig op imod ham,

skyller han bort som med en flodbølge,

han driver sine fjender ind i dødens mørke.

9Tvivler I på Herrens magt?1,9 Ordret: „Hvad tænker I om Herren?” Nahum taler til Judas folk, når han bruger „I”. Assyrerne omtales i tredje person. Herren slog 185.000 assyrere ihjel, da de tidligere havde belejret Jerusalem, jf. 2.Kong. 18–19. Assyrien vil snart blive helt tilintetgjort, så de ikke igen udgør en trussel mod Jerusalem.

Han vil gøre fuldstændig ende på dem,

så I ikke kommer i samme nødsituation igen.

10De er som et sammenfiltret tjørnekrat,

som drankere, der kun tænker på deres vin.

De bliver fuldstændigt tilintetgjort

som en stubmark, der brændes af.

11Fra dig, Nineve,1,11 Ordret: „Fra dig”. Her taler Nahum til Nineve, hovedstaden i Assyrien. Sandsynligvis tænkes på Sankerib, der i sin tid var lige ved at erobre Jerusalem. kom der en,

der satte sig op mod Herren selv.

Han havde lagt onde planer,

12men Herren siger til Juda:

„Selv om de har en stor og stærk hær,

vil de blive klippet som får,

og gå helt til grunde.

Jeg har før brugt dem til at ydmyge jer,

men det gør jeg ikke igen.

13Nu vil jeg fjerne det åg, de lagde på jeres skuldre,

og sprænge de lænker, I sidder i.”

14Og til Nineves konge siger Herren:

„Din kongeslægt skal uddø.

Jeg gør det af med gudebillederne i dit afgudstempel.

Jeg gør graven klar til dig,

for du er ikke bedre værd.”