Mika 6 – YCB & CARST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 6:1-16

Ọlọ́run pe Israẹli níjà

1Ẹ fi etí sí ohun tí Olúwa wí:

“Dìde dúró, bẹ ẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ rẹ níwájú òkè ńlá;

sì jẹ́ kí àwọn òkè kéékèèkéé gbọ́ ohun tí ó fẹ́ wí.

2“Gbọ́, ìwọ òkè ńlá, ẹ̀sùn Olúwa;

gbọ́, ìwọ ìpìlẹ̀ ilé ayérayé.

Nítorí Olúwa ń bá àwọn ènìyàn rẹ̀ wíjọ́;

òun yóò sì bá Israẹli rojọ́.

3“Ẹ̀yin ènìyàn mi, kí ni mo ṣe fún yín?

Àti nínú kí ni mo ti dá yin lágara? Dá mi lóhùn.

4Nítorí èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá,

mo sì rà yín padà láti ilẹ̀ ẹrú wá.

Mo rán Mose láti darí yín,

bákan náà mo rán Aaroni àti Miriamu síwájú rẹ̀.

5Ìwọ ènìyàn mi,

rántí ohun tí Balaki ọba Moabu gbèrò

àti ohun tí Balaamu ọmọ Beori dáhùn.

Rántí ìrìnàjò rẹ̀ láti Ṣittimu dé Gilgali,

kí ìwọ ba le mọ òdodo Olúwa.”

6Kí ni èmi yóò ha mú wá síwájú Olúwa

tí èmi ó fi tẹ ara mi ba níwájú Ọlọ́run gíga?

Kí èmi ha wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun,

pẹ̀lú ọmọ màlúù ọlọ́dún kan?

7Ǹjẹ́ Olúwa yóò ní inú dídùn sí ẹgbẹgbàarùn-ún àgbò,

tàbí sí ẹgbẹgbàarùn-ún ìṣàn òróró?

Èmi yóò ha fi àkọ́bí mi sílẹ̀ fún ìré-òfin-kọjá mi,

èso inú ara mi fún ẹ̀ṣẹ̀ ọkàn mi?

8Ó ti fihàn ọ́, ìwọ ènìyàn, ohun tí ó dára,

àti ohun tí Olúwa ń béèrè lọ́wọ́ rẹ?

Bí kò ṣe láti ṣe òtítọ́, kí o sì fẹ́ràn àánú,

àti kí o rìn ní ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.

Ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli àti ìjìyà wọn

9Gbọ́! Ohùn Olúwa kígbe sí ìlú ńlá náà,

láti jẹ ọlọ́gbọ́n ni láti bẹ̀rù orúkọ rẹ.

“Ẹ kíyèsi ọ̀pá rẹ̀ gbọ́ ọ̀pá àti Ẹni náà tí ó yàn án

10Ǹjẹ́ ìṣúra ìwà búburú ha wà

ní ilé ènìyàn búburú síbẹ̀,

àti òṣùwọ̀n àìkún tí ó jẹ́ ohun ìbínú?

11Ǹjẹ́ èmi ha lè kà wọ́n sí mímọ́

pẹ̀lú òṣùwọ̀n búburú,

pẹ̀lú àpò òṣùwọ̀n ẹ̀tàn?

12Àwọn ọlọ́rọ̀ inú rẹ̀ kún fún ìwà ipá;

àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ ti ọ̀rọ̀ èké

àti ahọ́n wọn ń sọ ẹ̀tàn?

13Nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ ṣàìsàn ní lílù ọ́,

láti sọ ọ́ dahoro nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.

14Ìwọ yóò jẹun ṣùgbọ́n kì yóò yó;

ìyàn yóò wà láàrín rẹ;

Ìwọ yóò kó pamọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò lò láìléwu,

nítorí ohun tí ìwọ kò pamọ́ ni èmi yóò fi fún idà.

15Ìwọ yóò gbìn ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò kórè

ìwọ yóò tẹ olifi,

ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò fi òróró rẹ̀ kún ara rẹ;

ìwọ yóò tẹ èso àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò mu wáìnì.

16Nítorí tí ìwọ ti pa òfin Omri mọ́,

àti gbogbo iṣẹ́ ilé Ahabu,

tí ó sì ti tẹ̀lé ìmọ̀ràn wọn,

nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ fún ìparun

àti àwọn ènìyàn rẹ fún ìfiṣe ẹlẹ́yà;

ìwọ yóò sì ru ẹ̀gàn àwọn ènìyàn mi.”

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

Михей 6:1-16

Всевышний обвиняет Исроил

1Послушайте, что говорит Вечный:

– Поднимись, изложи своё дело перед горами;

пусть слышат холмы то, что ты говоришь.

2Слушайте, горы, тяжбу Вечного,

и вы, прочные основания земли!

У Вечного тяжба с Его народом,

Он будет состязаться с Исроилом.

3Народ Мой, что Я сделал тебе?

Чем измучил тебя? Ответь Мне.

4Я вывел тебя из Египта,

выкупил из края неволи.

Я послал Мусо, Хоруна и Марьям,

чтобы вести тебя.

5Вспомни, народ Мой,

что задумал Валак, царь Моава,

и что ответил ему Валаам, сын Беора6:5 Валак и Валаам – см. Чис. 22–24.,

и что случилось по пути из Шиттима в Гилгал6:5 См. Иеш. 3–4.;

вспомни, чтобы постичь праведные дела Вечного.

6С чем мне предстать перед Вечным,

с чем мне склониться перед Богом небесным?

Предстать ли со всесожжениями,

с телятами годовалыми?

7Можно ли Вечному угодить тысячами баранов,

нескончаемыми реками масла?

Отдам ли первенца в жертву за грех мой,

плод тела – за грех моей души?

8О человек, Вечный сказал тебе, что есть добро

и чего Он требует от тебя:

действовать справедливо, любить милосердие

и смиренно жить перед твоим Богом.

Вина и наказание Исроила

9Голос Вечного взывает к городу

(и мудрость – бояться Его имени):

– Внимайте жезлу и Тому,

Кто его поставил.

10Забуду ли, о дом злодеев, злодейством нажитое богатство

и меру уменьшенную, которая Мне ненавистна?

11Потерплю ли неправильные весы

и обманные гири?

12Богачи твои кровожадны,

твои обитатели лгут,

обман у них на устах.

13За это Я начал губить тебя,

разорять дотла за твои грехи.

14Будешь есть, но не наешься;

желудок твой останется пустым.

Будешь копить, но не сбережёшь,

а то, что сбережёшь, Я предам мечу.

15Будешь сеять, а жать не будешь;

будешь давить оливки, но не будешь умащаться маслом;

будешь топтать виноград, но вина пить не будешь.

16Ты соблюдал злые уставы царя Омри

и сохранил все нечестивые обычаи дома царя Ахава6:16 Омри и Ахав – см. 3 Цар. 16:21-34. Об этих царях говорится, что они делали больше зла, чем все их предшественники.;

всем их традициям следовал.

За это предам тебя разорению,

а твоих обитателей – позору;

ты будешь сносить глумление народов6:16 Или: «поругание Моего народа»..