Mika 1 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 1:1-16

1Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.

2Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn,

fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,

Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín,

1.2: 1Ọb 22.28.Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.

Ìdájọ́ tí o lòdì sí Samaria àti Jerusalẹmu

3Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀;

yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.

4Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀,

àwọn Àfonífojì yóò sì pínyà,

bí idà níwájú iná,

bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.

5Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí,

àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli.

Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu?

Ǹjẹ́ Samaria ha kọ?

Kí ni àwọn ibi gíga Juda?

Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?

6“Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá,

bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà.

Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì.

Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.

7Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́

gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun:

Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run.

Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà,

gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”

Ẹkún òun ọfọ̀

8Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún,

èmi yóò sì pohùnréré ẹkún:

èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò

Èmi yóò ké bí akátá,

èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.

9Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán;

ó sì ti wá sí Juda.

Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi,

àní sí Jerusalẹmu.

10Ẹ má ṣe sọ ní Gati

ẹ má ṣe sọkún rárá.

Ní ilẹ̀ Beti-Ofra

mo yí ara mi nínú eruku.

11Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú,

ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri.

Àwọn tí ó ń gbé ni Ṣaanani

kì yóò sì jáde wá.

Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀;

A ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.

12Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre,

Ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.

13Ìwọ olùgbé Lakiṣi,

dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára.

Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀

sí àwọn ọmọbìnrin Sioni,

nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.

14Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀

fún Moreṣeti Gati.

Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.

15Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa.

Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli

yóò sì wá sí Adullamu.

16Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀

nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára,

sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún,

nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.

Swedish Contemporary Bible

Mika 1:1-16

Domsord över Juda och Israel

(1:2—3:12)

1Detta är Herrens ord som kom till Mika från Moreshet under de judiska kungarna Jotams, Achas och Hiskias regeringar, vad han fick se angående Samaria och Jerusalem.

2Hör, alla folk,

lyssna, du jord

och allt som finns där!

Herren, Herren, vittnar mot er,

Herren från sitt heliga tempel.

Dom över Samaria och Jerusalem

3Se! Herren kommer!

Han stiger ner från sin boning

och träder fram över jordens höjder.

4Bergen smälter under honom

och dalarna spricker upp,

som vax för elden

och som vatten störtar utför branten.

5Allt detta är för Jakobs överträdelse

och israeliternas synd.

Vad är Jakobs överträdelse?

Är det inte Samaria?

Vad är Judas offerplatser1:5 Enligt bl.a. Septuaginta synd.?

Är de inte Jerusalem?

6”Därför ska jag göra Samaria

till en stenhög på en åker,

till en plats där vingårdar kan planteras.

Jag ska vräka ner hennes stenar i dalen

och blotta hennes grundvalar.

7Alla hennes gudabilder

ska slås i stycken,

allt som hon tjänat som prostituerad

ska eldas upp,

och alla hennes avgudar

ska jag förgöra.

Med lönen för prostitution har hon skaffat dem,

och lön för prostitution ska de åter bli.”

Gråt och klagan

8Över detta gråter och klagar jag.

Jag går barfota och naken,

ylar som en schakal,

klagar som en berguv.

9Hennes sår kan inte läkas.

Det har kommit till Juda

och nått till mitt folks port,

till Jerusalem.

10Tala inte om det i Gat,

gråt inte!

Vältra er i stoftet

i Bet Leafra!1:10 Grundtexten innehåller mycket ordlek som inte låter sig översättas, och mycket av innebörden i detta avsnitt är osäkert. För v. 10f. jfr 2 Sam 1:20.

11Dra bort, Shafirs invånare,

i nakenhet och skam.

De som bor i Saanan

kan inte komma undan.

I Bet Haesel sörjer man,

dess beskydd har tagits ifrån er.

12Marots invånare vrider sig av smärta

och hoppas på något bättre,

för det onda som kommer från Herren

har nått Jerusalems portar.

13Spänn för stridsvagnar,

befolkningen i Lakish.

Det var början till dotter Sions synd

att man hos dig fann Israels överträdelser.

14Därför ska ni ge avskedsgåvor åt Moreshet Gat.

Husen i Aksiv har lurat kungarna i Israel.

15Jag ska åter låta erövrare komma mot er,

Mareshas invånare.

Israels härlighet ska komma

till Adullam.

16Raka ditt huvud och skär av ditt hår

för dina barns skull som var din glädje.

Gör dig skallig som gamen,

för de har förts bort från dig.