Mika 1 – YCB & JCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 1:1-16

1Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.

2Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn,

fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,

Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín,

1.2: 1Ọb 22.28.Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.

Ìdájọ́ tí o lòdì sí Samaria àti Jerusalẹmu

3Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀;

yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.

4Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀,

àwọn Àfonífojì yóò sì pínyà,

bí idà níwájú iná,

bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.

5Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí,

àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli.

Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu?

Ǹjẹ́ Samaria ha kọ?

Kí ni àwọn ibi gíga Juda?

Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?

6“Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá,

bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà.

Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì.

Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.

7Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́

gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun:

Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run.

Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà,

gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”

Ẹkún òun ọfọ̀

8Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún,

èmi yóò sì pohùnréré ẹkún:

èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò

Èmi yóò ké bí akátá,

èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.

9Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán;

ó sì ti wá sí Juda.

Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi,

àní sí Jerusalẹmu.

10Ẹ má ṣe sọ ní Gati

ẹ má ṣe sọkún rárá.

Ní ilẹ̀ Beti-Ofra

mo yí ara mi nínú eruku.

11Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú,

ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri.

Àwọn tí ó ń gbé ni Ṣaanani

kì yóò sì jáde wá.

Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀;

A ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.

12Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre,

Ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.

13Ìwọ olùgbé Lakiṣi,

dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára.

Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀

sí àwọn ọmọbìnrin Sioni,

nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.

14Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀

fún Moreṣeti Gati.

Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.

15Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa.

Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli

yóò sì wá sí Adullamu.

16Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀

nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára,

sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún,

nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.

Japanese Contemporary Bible

ミカ書 1:1-16

1

1次に述べるのは、ヨタム王、アハズ王、ヒゼキヤ王がユダ王国を治めていた時代に、モレシェテの町に住むミカに伝えられた主からのことばです。それはサマリヤとユダの両国へのことばで、幻によってミカに示されたものです。

2よく聞け。

世界のすべての国々の民よ、耳をすませよ。

主が聖なる神殿の中から、

あなたがたを告発したのだ。

サマリヤとエルサレムに対するさばき

3見よ、主が来ようとしている。

天の王座を離れ、山々の頂の上を歩きながら、

地上に来る。

4山々は、火の中の蝋のように主の足の下で溶け、

丘を流れ落ちる水のように谷へ流れ込む。

5どうしてこんなことが起こっているのか。

イスラエルとユダの罪のせいだ。

どんな罪か。

首都サマリヤとエルサレムを中心に行われている

偶像崇拝と虐待である。

6それゆえ、サマリヤの町は瓦礫の山となり、

開けた野となって、

その通りはぶどうを植えるために掘り返される。

主はその城壁と要塞を壊し、土台をあばき、

その石を下の谷へ流し入れる。

7刻んだ像は一つ残らず粉々に砕かれ、

礼拝者たちの寄進で建てた

きらびやかな偶像の神殿は焼き払われる。

嘆きと悲しみ

8わたしは声をあげて嘆こう。山犬のようにほえ、

夜、泣きながら砂漠を横切る

だちょうのように悲しげに。

はだし、裸で歩こう。

9わたしの民の傷が治せないほど深いからだ。

主はエルサレムを罰しようと、

すでにその門に立っている。

10ガテの町は災いだ。

嘆き悲しむな。

ベテ・レアフラでは、悩み、

恥じてちりの中を転げ回れ。

11シャフィルの民は身ぐるみはがされて、

裸になって恥じたまま、奴隷として引かれて行く。

ツァアナンの民は城壁の外に姿を現そうとしない。

ベテ・エツェルは町の土台ごと一掃される。

12マロテの民は、

これから良い時代になるだろうと望みをかけている。

だが、待ちかまえているのは苦痛だけだ。

主が、今にもエルサレムを打とうとしているからだ。

13急げ、ラキシュの民よ、

一番速い戦車で逃げるのだ。

ユダの町で最初にイスラエルの偶像礼拝の罪に

ならったのは、あなたなのだから。

そして南のすべての町が、

あなたの例にならうようになった。

14ガテのモレシェテに書き送れ。

もう救われる望みはない。

アクジブの町は、できもしない援助を約束して、

イスラエルの王を欺いた。

15マレシャの民よ、あなたは敵の賞品になる。

敵は、「イスラエルの誉れ」である

アドラムにまで侵入する。

16泣け。

子どもたちのために泣き悲しめ。

子どもたちは奪い去られ、二度と会えなくなる。

奴隷として遠くの地へ連れて行かれてしまった。

頭をそって嘆き悲しむがいい。