Malaki 2 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Malaki 2:1-17

Ìkìlọ̀ fún àwọn àlùfáà

1“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin àlùfáà, òfin yìí ní fún yín. 2Bí ẹ̀yin kò bá ni gbọ́, bí ẹ̀yin kò bá ní fi í sí àyà láti fi ọ̀wọ̀ fún orúkọ mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí; èmi yóò sì ran ègún sí orí yín, èmi yóò sì fi ìbùkún yín ré. Nítòótọ́ mó ti fi ré ná, nítorí pé, ẹ̀yin kò fi sí ọkàn yín láti bu ọlá fún mi.

3“Nítorí tiyín èmí yóò ba àwọn ọmọ yín wí, èmi ó sì fi ìgbẹ́ rẹ́ yín lójú, àní àwọn ìgbẹ́ ọrẹ ọwọ́ yín wọ̀nyí, a ó sì kó yín lọ pẹ̀lú rẹ̀. 4Ẹ̀yin ó sì mọ̀ pé, èmi ni ó ti rán òfin yìí sí yín, kí májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi lè tẹ̀síwájú” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. 5“Májẹ̀mú mi wà pẹ̀lú rẹ̀, májẹ̀mú ti ìyè àti àlàáfíà wà pẹ̀lú rẹ̀; mo sì fi wọn fún un, nítorí bíbẹ̀rù tí ó bẹ̀rù mi, tí ẹ̀rù orúkọ mi sì bà á. 6Òfin òtítọ́ wà ni ẹnu rẹ̀, a kò sì rí irọ́ ni ètè rẹ̀: ó ba mi rìn ní àlàáfíà àti ni ìdúró ṣinṣin, ó sì yí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.

7“Nítorí ètè àlùfáà ní òye láti máa pa ìmọ̀ mọ́, kí àwọn ènìyàn lè máa wá ìtọ́ni ni ẹnu rẹ̀: nítorí òun ni ìránṣẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun. 8Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yapa kúrò ní ọ̀nà náà; ẹ̀yin sì ti fi ìkọ́ni yín mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kọsẹ̀; ẹ̀yin ti ba májẹ̀mú tí mo da pẹ̀lú Lefi jẹ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. 9“Nítorí náà ni èmi pẹ̀lú ṣe sọ yín di ẹ̀gàn, àti ẹni àìkàsí níwájú gbogbo ènìyàn, nítorí ẹ̀yin kò tẹ̀lé ọ̀nà mi, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ń ṣe ojúsàájú nínú òfin.”

10Baba kan náà kí gbogbo wa ha ní? Ọlọ́run kan náà kọ́ ni ó dá wa bí? Nítorí kín ni àwa ha ṣe sọ májẹ̀mú àwọn baba wa di aláìmọ nípa híhu ìwà àrékérekè olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀?

11Juda ti ń hùwà àrékérekè, a sì ti hùwà ìríra ní Israẹli àti ni Jerusalẹmu: nítorí Juda tí sọ ìwà mímọ́ Olúwa di aláìmọ́, èyí tí ó fẹ́, nípa gbígbé ọmọbìnrin ọlọ́run àjèjì ni ìyàwó. 12Ní ti ẹni tí ó ṣe èyí, ẹni tí ó wù kí ó jẹ, kí Olúwa kí ó gé e kúrò nínú àgọ́ Jakọbu, bí ó tilẹ̀ mú ẹbọ ọrẹ wá fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

13Èyí ni ohun mìíràn tí ẹ̀yin sì túnṣe: Ẹ̀yin fi omijé bo pẹpẹ Olúwa mọ́lẹ̀. Ẹ̀yin sọkún, ẹ̀yin sì ba ara jẹ́ nítorí tì Òun kò ka ọrẹ yín sí mọ́, tàbí kí ó fi inú dídùn gba nǹkan yìí lọ́wọ́ yín. 14Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, “Nítorí kín ní?” Nítorí Olúwa ti ṣe ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti láàrín aya èwe rẹ, ẹni tí ìwọ ti ń hùwà ẹ̀tàn sí i: bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkejì rẹ ni òun jẹ́, àti aya májẹ̀mú rẹ.

15Ọlọ́run kò ha ti ṣe wọ́n ní ọ̀kan? Ni ara àti ni ẹ̀mí tirẹ̀ ni. Èéṣe tí Ọlọ́run da yín lọ́kàn? Kí òun bá à lè wá irú-ọmọ bí ti Ọlọ́run. Nítorí náà, ẹ tọ́jú ẹ̀mí yín, ẹ má sì ṣe hùwà ẹ̀tàn sí aya èwe yín.

16“Ọkùnrin tí ó bá kórìíra, tí ó sì kọ ìyàwó rẹ̀,” Ṣe ìwà ipá sí ẹni tí ó yẹ kí ó dá ààbò bò, ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.

Nítorí náà, ẹ ṣọ́ ẹ̀mí yín, kí ẹ má ṣe hùwà ẹ̀tàn.

Ọjọ́ ìdájọ́

17Ẹ̀yin ti fi ọ̀rọ̀ yín dá Olúwa ní agara.

Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, “Nínú kín ni àwa fi dá a ní agara?”

Nígbà tí ẹ̀yìn wí pé, “Gbogbo ẹni tí ó ṣe ibi, rere ni níwájú Olúwa, inú rẹ̀ sì dùn sí wọn,” tàbí “Níbo ni Ọlọ́run ìdájọ́ gbé wà?”

New International Reader’s Version

Malachi 2:1-17

The Lord Warns the Priests

1“Now I am giving this warning to you priests. 2Listen to it. Honor me with all your heart,” says the Lord who rules over all. “If you do not, I will send a curse on you. I will turn your blessings into curses. In fact, I have already done that because you have not honored me with all your heart.

3“Because of what you have done, I will punish your children. I will smear the waste from your sacrifices on your faces. And you will be carried off to the dump along with it. 4You will know that I have given you this warning. I have warned you so that my covenant with Levi will continue,” says the Lord who rules over all. 5“My covenant promised Levi life and peace. So I gave them to him. I required him to respect me. And he had great respect for my name. 6True teaching came from his mouth. Nothing but the truth came from his lips. He walked with me in peace. He did what was right. He turned many people away from their sins.

7“The lips of a priest should guard knowledge. After all, he is the messenger of the Lord who rules over all. And people seek instruction from his mouth. 8But you have turned away from the right path. Your teaching has caused many people to trip and fall. You have broken my covenant with Levi,” says the Lord who rules over all. 9“So I have caused all the people to hate you. They have lost respect for you. You have not done what I told you to do. Instead, you have favored one person over another in matters of the law.”

Breaking the Covenant Through Divorce

10People of Judah, all of us have one Father. One God created us. So why do we break the covenant the Lord made with our people of long ago? We do this by being unfaithful to one another.

11And Judah has been unfaithful. A hateful thing has been done in Israel and Jerusalem. The Lord loves his temple. But Judah has made it impure. Their men have married women who worship other gods. 12May the Lord punish the man who marries a woman like this. It doesn’t matter who that man is. May the Lord who rules over all remove him from the tents of Jacob’s people. May the Lord remove him even if he brings an offering to him.

13Here’s something else you do. You flood the Lord’s altar with your tears. You weep and cry because your offerings don’t please him anymore. He doesn’t accept them with pleasure from your hands. 14You ask, “Why?” It’s because the Lord is holding you responsible. He watches how you treat the wife you married when you were young. You have been unfaithful to her. You did it even though she’s your partner. You promised to stay married to her. And the Lord was a witness to it.

15Hasn’t the one God made the two of you one also? Both of you belong to him in body and spirit. And why has the one God made you one? Because he wants his children to be like him. So be careful. Don’t be unfaithful to the wife you married when you were young.

16“Suppose a man hates and divorces his wife,” says the Lord God of Israel. “Then he is harming the one he should protect,” says the Lord who rules over all.

So be careful. And don’t be unfaithful.

Breaking the Covenant by Treating Others Unfairly

17You have worn out the Lord by what you keep saying.

“How have we worn him out?” you ask.

You have done it by saying, “All those who do evil things are good in the Lord’s sight. And he is pleased with them.” Or you ask, “Is God really fair?”