Àdúrà Jona
1Nígbà náà ni Jona gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ láti inú ẹja náà wá, 2Ó sì wí pé:
“Nínú ìpọ́njú mi ni mo kígbe sí Olúwa,
òun sì gbọ́ ohùn mi.
Mo kígbe láti inú ipò òkú, mo pè fún ìrànwọ́,
ìwọ sì gbọ́ ohùn mi.
3Nítorí tí ìwọ ti sọ mí sínú ibú,
ní àárín Òkun,
ìṣàn omi sì yí mi káàkiri;
gbogbo bíbì omi àti rírú omi
rékọjá lórí mi.
4Nígbà náà ni mo wí pé,
‘a ta mí nù kúrò níwájú rẹ;
ṣùgbọ́n síbẹ̀ èmi yóò tún
máa wo ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ.’
5Omi yí mi káàkiri, àní títí dé ọkàn;
ibú yí mi káàkiri,
a fi koríko odò wé mi lórí.
6Èmi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ àwọn òkè ńlá;
ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ìdènà rẹ̀ yí mi ká títí:
ṣùgbọ́n ìwọ ti mú ẹ̀mí mi wá sókè láti inú ibú wá,
Olúwa Ọlọ́run mi.
7“Nígbà tí ó rẹ ọkàn mi nínú mi,
èmi rántí rẹ, Olúwa,
àdúrà mi sì wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,
nínú tẹmpili mímọ́ rẹ.
8“Àwọn tí ń fàmọ́ òrìṣà èké
kọ àánú ara wọn sílẹ̀.
9Ṣùgbọ́n èmi yóò fi orin ọpẹ́, rú ẹbọ sí ọ.
Èmi yóò san ẹ̀jẹ́ tí mo ti jẹ́.
‘Ìgbàlà wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.’ ”
10Olúwa sì pàṣẹ fún ẹja náà, ó sì pọ Jona sí orí ilẹ̀ gbígbẹ.
1Yona firii apataa no yam bɔɔ Awurade ne Onyankopɔn mpaeɛ sɛ. 2Ɔkaa sɛ,
“Mʼahohia mu mefrɛɛ Awurade,
na ɔgyee me so.
Mefiri adamena ase tɔnn srɛɛ mmoa
na wotiee me sufrɛ.
3Wotoo me twenee ebunu mu
wɔ ɛpo ase tɔnn,
na ɔhweam twaa me ho hyiaeɛ;
wʼasorɔkye ne mframa
bu faa me so.
4Na mekaa sɛ, ‘Wɔapam me afiri wʼanim;
nanso mede mʼani bɛkyerɛ
wʼasɔredan kronkron no bio’
5Nsuo a abu afa me so no bɔɔ me hu,
ebunu no twaa me ho hyiaeɛ;
ɛpo mu wira kyekyeree me tiri ho.
6Memem kɔɔ mmepɔ no ase pɛɛ;
asase ase kaa me hyɛɛ mu afebɔɔ.
Nanso wogyee me nkwa firii amena mu,
Ao Awurade, me Onyankopɔn.
7“Ɛberɛ a me nkwa resene akɔ no,
mekaee wo Awurade,
na me mpaeɛbɔ foro baa wo nkyɛn,
wɔ wʼasɔredan kronkron no mu.
8“Wɔn a wɔde wɔn ho bata ahoni huhuo ho no
hwere adom a anka ɛyɛ wɔn dea.
9Nanso me, mede ayɛyie nnwom
bɛbɔ afɔdeɛ ama wo.
Deɛ mahyɛ ho bɔ no, mɛyɛ.
Nkwagyeɛ firi Awurade.”
10Na afei, Awurade hyɛɛ apataa no ma ɔfee Yona too asase so.