Jobu 7 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 7:1-21

Jobu ha ni ìrètí bí?

1“Ṣé ìjà kò ha si fún ènìyàn lórí ilẹ̀?

Ọjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kò ha dàbí ọjọ́ alágbàṣe?

2Bí ọmọ ọ̀dọ̀ tí máa ń kánjú bojú wo òjìji,

àti bí alágbàṣe ti í kánjú wo ọ̀nà owó iṣẹ́ rẹ̀.

3Bẹ́ẹ̀ ni a mú mi ní ìbànújẹ́ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oṣù,

òru ìdáni-lágara ni a sì là sílẹ̀ fún mi.

4Nígbà ti mo dùbúlẹ̀, èmi wí pé, ‘Nígbà wo ni èmi ó dìde?’

Tí òru yóò sì kọjá, ó sì tó fún mi láti yí síhìn-ín yí sọ́hùn-ún, títí yóò fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.

5Kòkòrò àti ògúlùtu erùpẹ̀ ni á fi wọ̀ mi ni aṣọ,

awọ ara mi bù, o sì di bíbàjẹ́.

6“Ọjọ́ mi yára jù ọkọ̀ ìhunṣọ lọ,

o sì di lílò ní àìní ìrètí.

7Háà! Rántí pé afẹ́fẹ́ ni ẹ̀mí mi;

ojú mi kì yóò padà rí rere mọ́.

8Ojú ẹni tí ó rí mi, kì yóò rí mi mọ́;

ojú rẹ̀ tẹ̀ mọ́ra mi, èmi kò sí mọ́.

9Bí ìkùùkuu tí i túká, tí í sì fò lọ,

bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sí ipò òkú tí kì yóò padà wa mọ́.

10Kì yóò padà sínú ilé rẹ̀ mọ́,

bẹ́ẹ̀ ní ipò rẹ̀ kì yóò mọ̀ ọn mọ́.

11“Nítorí náà èmi kì yóò pa ẹnu mi mọ́,

èmi yóò máa sọ nínú ìrora ọkàn mi,

èmi yóò máa ṣe ìráhùn nínú kíkorò ọkàn mi.

12Èmi a máa ṣe Òkun tàbí ẹ̀mí búburú,

tí ìwọ fi ń yan olùṣọ́ tì mi?

13Nígbà tí mo wí pé, ibùsùn mi yóò tù mí lára,

ìtẹ́ mi yóò mú ara mi fúyẹ́ pẹ̀lú.

14Nígbà náà ni ìwọ fi àlá da yọ mi lénu bò mi,

ìwọ sì fi ìran òru dẹ́rùbà mí.

15Bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mí yàn láti fún pa

àti ikú ju kí ń wà láààyè ní ipò tí ara mí wà yìí lọ.

16O sú mi, èmi kò le wà títí:

jọ̀wọ́ mi jẹ́, nítorí pé asán ni ọjọ́ mi.

177.17: Sm 8.4.“Kí ni ènìyàn tí ìwọ o máa kókìkí rẹ̀?

Àti tí ìwọ ìbá fi gbé ọkàn rẹ lé e?

18Àti ti ìwọ ó fi máa wá í bẹ̀ ẹ́ wò ni òròòwúrọ̀,

ti ìwọ o sì máa dán an wò nígbàkúgbà!

19Yóò ti pẹ́ tó kí ìwọ kí ó tó fi mí sílẹ̀ lọ,

tí ìwọ o fi mí sílẹ̀ jẹ́ẹ́ títí èmi yóò fi lè dá itọ́ mi mì.

20Èmi ti ṣẹ̀, ki ní èmi ó ṣe sí ọ.

Ìwọ Olùsójú ènìyàn?

Èéṣe tí ìwọ fi fi mí ṣe ààmì itasi níwájú rẹ,

bẹ́ẹ̀ ni èmi sì di ẹrẹ̀ wíwo fún ọ?

21Èéṣe tí ìwọ kò sì dárí ìrékọjá mi jìn,

kí ìwọ kí ó sì mú àìṣedéédéé mi kúrò?

Ǹjẹ́ nísinsin yìí ni èmi ìbá sùn nínú erùpẹ̀,

ìwọ ìbá sì wá mi kiri ní òwúrọ̀, èmi kì bá tí sí.”

Nouă Traducere În Limba Română

Iov 7:1-21

1Oare nu are omul o viață plină de trudă1 Vezi Is. 40:2. Termenul ebraic se poate referi și la greutatea serviciului militar. pe pământ?

Oare nu sunt zilele lui ca ale unui zilier1 Sau: mercenar.?

2Ca un rob care tânjește după umbră

sau ca un zilier care își așteaptă plata,

3așa am avut și eu parte de luni de deșertăciune

și nopți de necaz mi s‑au dat.

4Când mă culc, mă întreb: «Când mă voi trezi?»

Dar noaptea e așa de lungă și mă frământ până în zori.

5Carnea îmi este acoperită de viermi și de coji pământii;

pielea îmi crapă și supurează.

6Zilele mele sunt mai iuți decât suveica țesătorului

și se sfârșesc fără speranță.

7Adu‑Ți aminte, Dumnezeule, că viața mi‑e doar o suflare!

Ochii mei nu vor mai vedea binele.

8Ochiul care mă privește nu mă va mai vedea;

ochii Tăi vor fi asupra mea, dar eu nu voi mai fi.

9Ca norul care se risipește și trece,

tot așa cel ce se coboară în Locuința Morților9 Ebr.: Șeol [peste tot în carte]. nu se va mai ridica.

10Nu se va mai întoarce la casa lui

și nu‑și va mai cunoaște locul.

11De aceea eu nu voi tăcea,

ci, în necazul duhului meu, voi vorbi,

în amărăciunea sufletului meu, mă voi plânge!

12Sunt eu Marea sau un monstru al mării,

de ai pus o strajă în jurul meu?

13Când zic: «Patul meu mă va mângâia

și așternutul îmi va alina plângerea!»,

14atunci Tu mă înspăimânți cu vise

și mă îngrozești cu vedenii.

15Așa că aș alege mai bine sugrumarea,

mai bine moartea, decât aceste oase.

16Le disprețuiesc…! Nu voi trăi în veci!

Lasă‑mă, căci doar o suflare îmi sunt zilele!

17Ce este omul, ca să‑l apreciezi

și să‑ți îndrepți inima spre el,

18să‑l cercetezi în fiecare dimineață

și să‑l încerci în orice clipă?

19Nu vei înceta oare să te mai uiți la mine

și să mă lași astfel singur, măcar până‑mi înghit saliva?

20Dacă am păcătuit, ce Ți‑am făcut Ție,

Veghetor al oamenilor?

De ce m‑ai luat drept țintă?

Am devenit o povară pentru Tine?

21De ce nu‑mi ierți fărădelegea

și nu‑mi dai la o parte nelegiuirea?

Căci acum mă voi culca în țărână,

mă vei căuta, dar nu voi mai fi.“