Jobu 5 – YCB & KSS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 5:1-27

Ìjìyà jẹ́ èso àìṣòdodo

1“Ó jẹ́ pé nísinsin yìí bí ẹnìkan bá wà tí yóò dá wa lóhùn?

Tàbí ta ni nínú àwọn ènìyàn mímọ́ tí ìwọ ó yípadà sí?

2Nítorí pé ìbínú pa aláìmòye,

ìrunú a sì pa òpè ènìyàn.

3Èmi ti rí aláìmòye ti ó ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lulẹ̀,

ṣùgbọ́n lójúkan náà mo fi ibùjókòó rẹ̀ bú.

4Àwọn ọmọ rẹ̀ kò jìnnà sí ewu,

a sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ lójú ibodè,

bẹ́ẹ̀ ni kò sí aláàbò kan.

5Ìkórè oko ẹni tí àwọn tí ebi ń pa sọ̀ di jíjẹ,

tí wọ́n sì wọ inú ẹ̀gún lọ kó,

àwọn ìgárá ọlọ́ṣà sì gbé ohun ìní wọn mì.

6Bí ìpọ́njú kò bá ti inú erùpẹ̀ jáde wá ni,

tí ìyọnu kò ti ilẹ̀ jáde wá.

7Ṣùgbọ́n a bí ènìyàn sínú wàhálà,

gẹ́gẹ́ bí ìpẹ́pẹ́ iná ti máa ń ta sókè.

8“Ṣùgbọ́n bí ó ṣe tèmi, ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní èmi yóò ti ṣìpẹ̀,

ní ọwọ́ Ọlọ́run ní èmi yóò máa fi ọ̀rọ̀ mi lé.

9Ẹni tí ó ṣe ohun tí ó tóbi tí a kò lè ṣe àwárí,

ohun ìyanu láìní iye.

10Tí ń rọ̀jò sí orí ilẹ̀ ayé

tí ó sì ń rán omi sínú ilẹ̀kílẹ̀.

11Láti gbé àwọn orílẹ̀-èdè lékè

kí á lè gbé àwọn ẹni ìbànújẹ́ ga sí ibi aláìléwu.

125.12-13: 1Kọ 3.19.Ó yí ìmọ̀ àwọn alárékérekè po,

bẹ́ẹ̀ ní ọwọ́ wọn kò lè mú ìdáwọ́lé wọn ṣẹ.

13Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n nínú àrékérekè ara wọn,

àti ìmọ̀ àwọn òǹrorò ní ó tì ṣubú ní ògèdèǹgbé.

14Wọ́n sáré wọ inú òkùnkùn ní ọ̀sán;

wọ́n sì fọwọ́ tálẹ̀ ní ọ̀sán gangan bí ẹni pé ní òru ni.

15Ṣùgbọ́n ó gba tálákà là ní ọwọ́ idà,

lọ́wọ́ ẹnu wọn àti lọ́wọ́ àwọn alágbára.

16Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí wà fún tálákà,

àìṣòótọ́ sì pa ẹnu rẹ̀ mọ́.

17“Kíyèsi i, ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run bá wí,

nítorí náà, má ṣe gan ìbáwí Olódùmarè.

18Nítorí pé òun a máa pa ni lára, síbẹ̀ òun a sì tún dì í ní ìdì ìtura,

ó sá lọ́gbẹ́, a sì fi ọwọ́ rẹ̀ di ojú ọgbẹ̀ náà jiná.

19Yóò gbà ọ́ nínú ìpọ́njú mẹ́fà,

àní nínú méje, ibi kan kì yóò bá ọ

20Nínú ìyanu yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú

àti nínú ogun, yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.

21A ó pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ iná ahọ́n,

bẹ́ẹ̀ ní ìwọ kì yóò bẹ̀rù ìparun tí ó bá dé.

22Ìwọ yóò rẹ́rìn-ín nínú ìparun àti ìyàn,

bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò bẹ̀rù ẹranko ilẹ̀ ayé.

23Nítorí pé ìwọ ti bá òkúta igbó mulẹ̀,

àwọn ẹranko igbó yóò wà pẹ̀lú rẹ ní àlàáfíà.

24Ìwọ ó sì mọ̀ pé àlàáfíà ni ibùjókòó rẹ wà,

ìwọ yóò sì máa ṣe ìbẹ̀wò ibùjókòó rẹ, ìwọ kì yóò ṣìnà.

25Ìwọ ó sì mọ̀ pẹ̀lú pé irú-ọmọ rẹ ó sì pọ̀

àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ yóò rí bí koríko igbó.

26Ìwọ yóò wọ isà òkú rẹ ní ògbólógbòó ọjọ́,

bí síírí ọkà tí ó gbó tí á sì kó ní ìgbà ìkórè rẹ̀.

27“Kíyèsi i, àwa ti wádìí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní ó rí!

Gbà á gbọ́, kí o sì mọ̀ pé fún ìre ara rẹ ni.”

Kurdi Sorani Standard

ئەیوب 5:1-27

1«ئێستا بانگ بکە، بزانە کێ وەڵامت دەداتەوە؟

ڕوو لە کام لە پیرۆزان دەکەیت؟

2قین گێل دەکوژێت و

بەغیلیش ساویلکە دەمرێنێت.

3من گێلێکم بینی ڕەگی داکوتا،

بەڵام لەناکاو ماڵەکەی بە نەفرەت کرا:

4با کوڕەکانی لە ئاسوودەیی بەدوور بن،

لە دادگا تێکبشکێنرێن و کەس فریایان نەکەوێت.

5دروێنەکەیان کەسانی برسی دەیخۆن،

ئەگەر لەناو دڕکیش بێت هەر دەیبەن،

تینووش سامانەکەی هەڵدەقورتێنێت،

6چونکە بەڵا لەناو خۆڵەوە دەرناچێت و

چەرمەسەریش لە زەوییەوە ناڕووێت.

7بەڵام مرۆڤ بۆ چەرمەسەری لەدایک دەبێت،

وەک چۆن پریشکی ئاگر هەڵدەستێت.

8«بەڵام ئەگەر من لە جێی تۆ بوومایە داوام لە خودا دەکرد و

کێشەی خۆمم دەدایە دەست ئەو.

9ئەوەی کارە مەزنەکانی کردووە کە ناپشکێنرێن و

کارە سەرسوڕهێنەرەکان کە لە ژماردن نایەن.

10ئەوەی باران بەسەر ڕووی زەویدا دەبارێنێت و

ئاو بۆ سەر ڕووی دەشتودەر دەنێرێت.

11ئەوەی بێفیزەکان بەرزدەکاتەوە،

هەروەها خەمبارەکان بەرەو دڵنیایی دەبات.

12ئەو تەگبیری تەڵەکەبازان پووچ دەکاتەوە

بۆ ئەوەی هیچ کارێک لەسەر دەستی ئەوان سەرکەوتوو نەبێت.

13ئەوەی داناکان بە فێڵبازی خۆیانەوە دەگرێت،

ڕاوێژی تەڵەکەبازان ڕادەماڵێت.

14لە ڕۆژدا تاریکی بەسەریاندا دێت،

لە نیوەڕۆشدا بە پەلکوتان دەڕۆن وەک بە شەو.

15ئەو نەدار لە دەمی خراپەکار و

لە دەستی ستەمکار ڕزگار دەکات.

16جا زەلیل بە هیوا دەبێت و

ناڕەوا دەمی دادەخات.

17«سەرزەنشتکردن لەلایەن خوداوە بەرەکەتە،

لەبەر ئەوە تەمبێکردنی خودای هەرە بەتوانا ڕەت مەکەرەوە.

18لەبەر ئەوەی ئەو بریندار دەکات و برینیش ساڕێژ دەکات،

وردوخاش دەکات و بە دەستەکانی خۆی دەیگرێتەوە.

19لە شەش بەڵا ڕزگارت دەکات و

لە حەوتەمیش خراپەت لێ ناکەوێت.

20لە قاتوقڕیدا لە مردن دەتکڕێتەوە و

لە جەنگیشدا لە دەمی شمشێر.

21لە خەنجەری زمان پارێزراو دەبیت،

کە وێرانە ڕووت تێ دەکات ناترسیت.

22بە وێرانی و قاتوقڕی پێدەکەنیت و

لە ئاژەڵە دڕندەکان ناترسیت،

23چونکە لەگەڵ بەردەکانی دەشتودەر پەیمانت دەبێت و

ئاژەڵە کێوییەکان ئاشتیت لەگەڵ دەبەستن.

24جا دەزانیت کە ڕەشماڵەکەت سەلامەتە و

سەرژمێری ماڵەکەت دەکەیت و هیچت ون نەبووە.

25ئەو کاتە دەزانیت کە منداڵت چەند زۆر دەبن و

نەوەکانت وەک گیای زەوی دەبن.

26لەوپەڕی تەندروستیدا دەچیتە ناو گۆڕەوە

وەک هەڵگرتنی کۆڵێک لە کاتی خۆیدا.

27«ئێمە لەمە وردبووینەوە و بینیمان کە ڕاستە،

جا تۆش گوێ بگرە و لە ژیانی خۆتدا پەیڕەوی بکە.»