Jobu 5 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 5:1-27

Ìjìyà jẹ́ èso àìṣòdodo

1“Ó jẹ́ pé nísinsin yìí bí ẹnìkan bá wà tí yóò dá wa lóhùn?

Tàbí ta ni nínú àwọn ènìyàn mímọ́ tí ìwọ ó yípadà sí?

2Nítorí pé ìbínú pa aláìmòye,

ìrunú a sì pa òpè ènìyàn.

3Èmi ti rí aláìmòye ti ó ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lulẹ̀,

ṣùgbọ́n lójúkan náà mo fi ibùjókòó rẹ̀ bú.

4Àwọn ọmọ rẹ̀ kò jìnnà sí ewu,

a sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ lójú ibodè,

bẹ́ẹ̀ ni kò sí aláàbò kan.

5Ìkórè oko ẹni tí àwọn tí ebi ń pa sọ̀ di jíjẹ,

tí wọ́n sì wọ inú ẹ̀gún lọ kó,

àwọn ìgárá ọlọ́ṣà sì gbé ohun ìní wọn mì.

6Bí ìpọ́njú kò bá ti inú erùpẹ̀ jáde wá ni,

tí ìyọnu kò ti ilẹ̀ jáde wá.

7Ṣùgbọ́n a bí ènìyàn sínú wàhálà,

gẹ́gẹ́ bí ìpẹ́pẹ́ iná ti máa ń ta sókè.

8“Ṣùgbọ́n bí ó ṣe tèmi, ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní èmi yóò ti ṣìpẹ̀,

ní ọwọ́ Ọlọ́run ní èmi yóò máa fi ọ̀rọ̀ mi lé.

9Ẹni tí ó ṣe ohun tí ó tóbi tí a kò lè ṣe àwárí,

ohun ìyanu láìní iye.

10Tí ń rọ̀jò sí orí ilẹ̀ ayé

tí ó sì ń rán omi sínú ilẹ̀kílẹ̀.

11Láti gbé àwọn orílẹ̀-èdè lékè

kí á lè gbé àwọn ẹni ìbànújẹ́ ga sí ibi aláìléwu.

125.12-13: 1Kọ 3.19.Ó yí ìmọ̀ àwọn alárékérekè po,

bẹ́ẹ̀ ní ọwọ́ wọn kò lè mú ìdáwọ́lé wọn ṣẹ.

13Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n nínú àrékérekè ara wọn,

àti ìmọ̀ àwọn òǹrorò ní ó tì ṣubú ní ògèdèǹgbé.

14Wọ́n sáré wọ inú òkùnkùn ní ọ̀sán;

wọ́n sì fọwọ́ tálẹ̀ ní ọ̀sán gangan bí ẹni pé ní òru ni.

15Ṣùgbọ́n ó gba tálákà là ní ọwọ́ idà,

lọ́wọ́ ẹnu wọn àti lọ́wọ́ àwọn alágbára.

16Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí wà fún tálákà,

àìṣòótọ́ sì pa ẹnu rẹ̀ mọ́.

17“Kíyèsi i, ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run bá wí,

nítorí náà, má ṣe gan ìbáwí Olódùmarè.

18Nítorí pé òun a máa pa ni lára, síbẹ̀ òun a sì tún dì í ní ìdì ìtura,

ó sá lọ́gbẹ́, a sì fi ọwọ́ rẹ̀ di ojú ọgbẹ̀ náà jiná.

19Yóò gbà ọ́ nínú ìpọ́njú mẹ́fà,

àní nínú méje, ibi kan kì yóò bá ọ

20Nínú ìyanu yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú

àti nínú ogun, yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.

21A ó pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ iná ahọ́n,

bẹ́ẹ̀ ní ìwọ kì yóò bẹ̀rù ìparun tí ó bá dé.

22Ìwọ yóò rẹ́rìn-ín nínú ìparun àti ìyàn,

bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò bẹ̀rù ẹranko ilẹ̀ ayé.

23Nítorí pé ìwọ ti bá òkúta igbó mulẹ̀,

àwọn ẹranko igbó yóò wà pẹ̀lú rẹ ní àlàáfíà.

24Ìwọ ó sì mọ̀ pé àlàáfíà ni ibùjókòó rẹ wà,

ìwọ yóò sì máa ṣe ìbẹ̀wò ibùjókòó rẹ, ìwọ kì yóò ṣìnà.

25Ìwọ ó sì mọ̀ pẹ̀lú pé irú-ọmọ rẹ ó sì pọ̀

àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ yóò rí bí koríko igbó.

26Ìwọ yóò wọ isà òkú rẹ ní ògbólógbòó ọjọ́,

bí síírí ọkà tí ó gbó tí á sì kó ní ìgbà ìkórè rẹ̀.

27“Kíyèsi i, àwa ti wádìí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní ó rí!

Gbà á gbọ́, kí o sì mọ̀ pé fún ìre ara rẹ ni.”

Bibelen på hverdagsdansk

Jobs Bog 5:1-27

1Beklag dig bare, så meget du vil,

der er ingen, der hører dit råb.

Tror du, englene vil tale din sag?

2Vrede kan tage livet af en tåbe,

deres bitterhed kan koste dem livet.

3En tåbe kan klare sig godt for en tid,

men pludselig ligger alt i ruiner.

4Hans familie er prisgivet andres begær,

der er ingen til at forsvare dem i retten.

5De sultne kommer og stjæler hans høst,

de lader intet tilbage på marken,

begærlige folk overtager hans ejendele.

6Ingen bliver straffet uden grund,

ulykker kommer ikke af sig selv.

7Nej, årsagen findes i mennesket selv,

der kommer jo kun røg, hvor der er ild.

8Derfor må du bekende din synd for Gud

og lade ham være din dommer.

9Hans visdom og storhed er grænseløs,

hans undere kan man ikke tælle.

10Han sender regn på jorden

og vander både haver og marker.

11Han rejser de ydmyge op

og bringer de forliste i sikkerhed.

12Men de listige spænder han ben for,

så der intet kommer ud af deres onde planer.

13Han fanger de kloge i deres egen snedighed,

så deres kunstfærdige planer går i vasken.

14De famler sig frem som i blinde,

de kan ikke finde vej selv ved højlys dag.

15Men de magtesløse redder han fra de stærkes kløer,

han frelser dem fra de magtfuldes intriger.

16Han giver de svage nyt håb

og standser uretfærdigheden imod dem.

17Det er en velsignelse at blive irettesat af Gud!

Vær taknemmelig, når den Almægtige straffer dig!

18For selv om han slår og sårer,

så forbinder han også og helbreder.

19Gang på gang beskytter han dig,

både seks og syv gange redder han dig.

20Under hungersnød redder han dig fra sultedøden,

under krig redder han dig fra sværdets hug.

21Han beskytter dig mod ondskabsfuld sladder

og redder dig fra voldelige overfald.

22Du kan le ad ulykker så vel som hungersnød,

selv de vilde dyr behøver du ikke at frygte.

23Markens sten skader ikke din plov,

du kan passe din jord i fred for vilde dyr.

24Du kan bo i tryghed i dit hus

uden frygt for at miste dine ejendele.

25Dine efterkommere bliver mange,

så frodige som det grønne græs.

26Som korn, der modnes, før det høstes,

skal du nå en moden alder, før du dør.

27Jeg har talt ud fra min egen erfaring,

så hør efter og følg mit råd.”