Jobu 38 – YCB & HOF

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 38:1-41

Ọlọ́run pe Jobu níjà

1Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àjàyíká wá, ó sì wí pé:

2“Ta ni èyí tí ń fi ọ̀rọ̀ àìlóye

láti fi ṣókùnkùn bo ìmọ̀ mi?

3Di ẹ̀gbẹ́ ara rẹ ní àmùrè bí ọkùnrin nísinsin yìí,

nítorí pé èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ

kí o sì dá mi lóhùn.

4“Níbo ni ìwọ wà nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀?

Wí bí ìwọ bá mòye.

5Ta ni ó fi ìwọ̀n rẹ lélẹ̀, dájú bí ìwọ bá mọ̀ ọ́n?

Tàbí ta ni ó ta okùn wíwọ̀n sórí rẹ?

6Lórí ibo ni a gbé kan ìpìlẹ̀ rẹ̀ mọ́,

tàbí ta ni ó fi òkúta igun rẹ̀ lélẹ̀,

7Nígbà náà àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ jùmọ̀ kọrin pọ̀,

tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọ́run hó ìhó ayọ̀?

8“Tàbí ta ni ó fi ìlẹ̀kùn sé omi Òkun mọ́,

nígbà tí ó ya padà bí ẹni pé ó ti inú jáde wá,

9Nígbà tí mo fi àwọsánmọ̀ ṣe aṣọ rẹ̀,

tí mo sì fi òkùnkùn biribiri ṣe ọ̀já ìgbà inú rẹ̀,

10Nígbà tí mo ti pàṣẹ ìpinnu mi fún un,

tí mo sì ṣe bèbè àti ìlẹ̀kùn,

11Tí mo sì wí pé níhìn-ín ni ìwọ ó dé, kí o má sì rékọjá,

níhìn-ín sì ni ìgbéraga rẹ yóò gbé dúró mọ?

12“Ìwọ pàṣẹ fún òwúrọ̀ láti ìgbà ọjọ́ rẹ̀ wá,

ìwọ sì mú ìlà-oòrùn mọ ipò rẹ̀,

13Kí ó lè di òpin ilẹ̀ ayé mú,

ki a lè gbọ́n àwọn ènìyàn búburú kúrò nínú rẹ̀?

14Kí ó yí padà bí amọ̀ fún èdìdì amọ̀,

kí gbogbo rẹ̀ kí ó sì fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni pé nínú aṣọ ìgúnwà.

15A sì fa ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn búburú,

apá gíga ni a sì ṣẹ́.

16“Ìwọ ha wọ inú ìsun Òkun lọ rí bí?

Ìwọ sì rìn lórí ìsàlẹ̀ ibú ńlá?

17A ha ṣílẹ̀kùn ikú sílẹ̀ fún ọ rí bí,

ìwọ sì rí ìlẹ̀kùn òjìji òkú?

18Ìwọ mòye ìbú ayé bí?

Sọ bí ìwọ bá mọ gbogbo èyí.

19“Ọ̀nà wo ni ìmọ́lẹ̀ ń gbé?

Bí ó ṣe ti òkùnkùn, níbo ni ipò rẹ̀,

20Tí ìwọ í fi mú un lọ sí ibi àlá rẹ̀,

tí ìwọ ó sì le mọ ipa ọ̀nà lọ sínú ilé rẹ̀?

21Ìwọ mọ èyí, nítorí nígbà náà ni a bí ọ?

Iye ọjọ́ rẹ sì pọ̀.

22“Ìwọ ha wọ inú ìṣúra ìdì òjò lọ rí bí,

ìwọ sì rí ilé ìṣúra yìnyín rí,

23Tí mo ti fi pamọ́ de ìgbà ìyọnu,

dé ọjọ́ ogun àti ìjà?

24Ọ̀nà wo ni ó lọ sí ibi tí ìmọ́lẹ̀ fi ń la,

tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ń tàn káàkiri lórí ilẹ̀ ayé?

25Ta ni ó la ipadò fún ẹ̀kún omi,

àti ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,

26láti mú u rọ̀jò sórí ayé níbi tí ènìyàn kò sí,

ní aginjù níbi tí ènìyàn kò sí;

27láti mú ilẹ̀ tútù, ijù àti aláìro

láti mú àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ewéko rú jáde?

28Òjò ha ní baba bí?

Tàbí ta ni o bí ìkún ìṣe ìrì?

29Láti inú ta ni ìdì omi ti jáde wá?

Ta ni ó bí ìrì dídì ọ̀run?

30Nígbà tí omi di líle bí òkúta,

nígbà tí ojú ibú ńlá sì dìpọ̀.

31“Ìwọ ha le fi ọ̀já de àwọn ìràwọ̀ Pleiadesi dáradára?

Tàbí ìwọ le tún di Ìràwọ̀ Orioni?

32Ìwọ le mú àwọn ààmì méjìlá ìràwọ̀ Masaroti jáde wá nígbà àkókò wọn?

Tàbí ìwọ le ṣe amọ̀nà Beari pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀?

33Ǹjẹ́ ìwọ mọ ìlànà ọ̀run?

Ìwọ le fi ìjọba Ọlọ́run lélẹ̀ lórí ayé?

34“Ìwọ le gbé ohùn rẹ sókè dé àwọsánmọ̀

kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kí ó lè bò ọ́?

35Ìwọ le rán mọ̀nàmọ́ná kí wọn kí ó le lọ,

ní ọ̀nà wọn kí wọn kí ó sì wí fún wọn pé, ‘àwa nìyí’?

36Ta ni ó fi ọgbọ́n pamọ́ sí odò ikùn

tàbí tí ó fi òye sínú àyà?

37Ta ni ó fi ọgbọ́n ka iye àwọsánmọ̀?

Ta ni ó sì mú ìgò ọ̀run dà jáde,

38Nígbà tí erùpẹ̀ di líle,

àti ògúlùtu dìpọ̀?

39“Ìwọ ha dẹ ọdẹ fún abo kìnnìún bí?

Ìwọ ó sì tẹ ebi ẹgbọrọ kìnnìún lọ́rùn,

40Nígbà tí wọ́n bá mọ́lẹ̀ nínú ihò

tí wọ́n sì ba ní ibùba de ohun ọdẹ?

41Ta ni ó ń pèsè ohun jíjẹ fún ẹyẹ ìwò,

nígbà tí àwọn ọmọ rẹ ń ké pe Ọlọ́run,

tí wọ́n sì máa ń fò kiri nítorí àìní ohun jíjẹ?

Hoffnung für Alle

Hiob 38:1-41

Gottes Antwort an Hiob

(Kapitel 38–41)

Der mächtige Schöpfer

1Dann aber redete der Herr mit Hiob. Er antwortete ihm aus dem Sturm:

2»Wer bist du, dass du meine Weisheit anzweifelst

mit Worten ohne Verstand?

3Tritt mir gegenüber wie ein Mann

und gib mir Antwort auf meine Fragen!

4Wo warst du,

als ich das Fundament der Erde legte?

Sag es doch, wenn du so viel weißt!

5Wer hat ihre Maße festgelegt

und wer die Messschnur über sie gespannt?

Du weißt es doch, oder etwa nicht?

6Worin sind die Pfeiler der Erde eingesenkt,

und wer hat ihren Grundstein gelegt?

7Damals sangen alle Morgensterne,

und die Gottessöhne jubelten vor Freude.

8Wer schloss die Schleusentore,

um das Meer zurückzuhalten,

als es hervorbrach aus dem Mutterschoß der Erde?

9Ich hüllte es in Wolken

und in dichtes Dunkel wie in Windeln;

10ich setzte dem Meer eine Grenze,

schloss seine Tore und Riegel

11und sprach:

›Bis hierher sollst du kommen und nicht weiter!

Hier müssen sich deine mächtigen Wogen legen!‹

12Sag, hast du je das Tageslicht herbeigerufen

und der Morgenröte ihren Weg gewiesen?

13Sie fasst die Erde bei den Zipfeln

und schüttelt die Übeltäter von ihr ab.

14In ihrem Licht färbt die Erde sich bunt wie ein Kleid;

ihre Gestalt tritt hervor,

deutlich wie ein Siegelabdruck auf Ton.

15Dann wird den Übeltätern das schützende Dunkel38,15 Wörtlich: ihr Licht. genommen,

und ihr drohend erhobener Arm wird zerbrochen.

16Bist du hinab zu den Quellen des Meeres gereist,

hast du den Abgrund des Ozeans durchwandert?

17Haben sich dir die Tore des Todes geöffnet,

die den Eingang ins dunkle Land verschließen?

18Hast du die Weiten der Erde überblickt?

Sag es mir, wenn du das alles weißt!

19Woher kommt das Licht,

und wie gelangt man dorthin?

Woher kommt die Finsternis?

20Kannst du Licht und Dunkelheit an ihre Orte bringen,

kennst du den Weg zu ihrem Land?

21Ganz gewiss, denn du warst schon geboren,

als ich sie schuf, du lebst ja seit uralten Zeiten!

22Hast du die Vorratskammern gesehen,

in denen ich Schnee und Hagel aufbewahre?

23Ich spare sie auf für den Unglückstag,

für Kriegszeiten und Schlachtgetümmel.

24Weißt du, wo das Licht herkommt

und von wo der Ostwind loszieht?

Wie gelangt man dorthin?

25Wer schafft den Regenfluten eine Bahn,

wer ebnet Blitz und Donner den Weg,

26damit Gewitterregen niedergehn

auf unbewohntes Land, über unwegsame Wüsten,

27damit die ausgedörrte Steppe durchtränkt wird

und frisches Grün aus dem Boden sprießt?

28Hat der Regen einen Vater?

Wer lässt den Tau entstehen?

29Wer bringt Eis und Frost hervor,

30wenn das Wasser hart wird wie Stein,

wenn Seen und Flüsse zugefroren sind?

31Knüpfst du die Bänder des Siebengestirns,

kannst du den Gürtel des Orion öffnen?

32Lässt du die Sternbilder erscheinen,

je nach Jahreszeit,

bringst du den Großen und den Kleinen Wagen herauf?

33Hast du die Gesetze des Himmels entdeckt,

und kannst du sie auf die Erde übertragen?

34Rufst du den Wolken einen Befehl zu,

damit sie Regen auf dich herabströmen lassen?

35Schleuderst du die Blitze in ihr Ziel?

Sagen sie: ›Wir stehen dir zu Diensten‹?

36Wer lässt die Wolken wohlgeordnet ziehen?

Wer bestimmt das Wetter nach einem weisen Plan?38,36 Der hebräische Text in Vers 36 ist nicht sicher zu deuten.

37Wer ist so klug, dass er die Zahl der Wolken kennt?

Wer schüttet ihr Wasser auf die Erde nieder,38,37 Wörtlich: Wer kippt die Krüge des Himmels um.

38wenn dort der Boden hart geworden ist wie Eisen

und die Schollen aneinander kleben?

39Erjagst du die Beute für die Löwin,

stillst du den Hunger ihrer Jungen,

40wenn sie sich in Höhlen verkriechen,

im Dickicht auf der Lauer liegen?

41Wer lässt den Raben Futter finden,

wenn seine Jungen zu Gott schreien,

wenn sie hungrig und hilflos umherirren?