Jobu 35 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 35:1-16

Olóòtítọ́ ni Ọlọ́run

1Elihu sì wí pe:

2“Ìwọ rò pé èyí ha tọ́, tí ìwọ wí pé,

òdodo mi ni èyí níwájú Ọlọ́run?

3Nítorí tí ìwọ wí pé èrè kí ní yóò jásí fún ọ,

tàbí èrè kí ni èmi yóò fi jẹ́ ju èrè ẹ̀ṣẹ̀ mi lọ.

4“Èmi ó dá ọ lóhùn

àti àwọn ẹgbẹ́ rẹ pẹ̀lú rẹ.

5Síjú wo ọ̀run; kí o rí i, kí ó sì

bojú wo àwọsánmọ̀ tí ó ga jù ọ́ lọ.

6Bí ìwọ bá dẹ́ṣẹ̀, kí ni ìwọ fi sẹ̀ sí?

Tàbí bí ìrékọjá rẹ di púpọ̀, kí ni ìwọ fi èyí nì ṣe sí i?

7Bí ìwọ bá sì ṣe olódodo, kí ni ìwọ fi fún un,

tàbí kí ni òun rí gbà láti ọwọ́ rẹ wá?

8Ìwà búburú rẹ ni fún ènìyàn bí ìwọ;

òdodo rẹ sì ni fún ọmọ ènìyàn.

9“Nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìninilára, wọ́n mú ni kígbe;

wọ́n kígbe nípa apá àwọn alágbára.

10Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó wí pé,

‘Níbo ni Ọlọ́run Ẹlẹ́dàá mi wà tí ó sì fi orin fún mi ní òru;

11Tí òun kọ́ wa ní ẹ̀kọ́ jù àwọn ẹranko ayé lọ,

tí ó sì mú wa gbọ́n ju àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run lọ?’

12Nígbà náà ni wọ́n ń ké ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò dáhùn

nítorí ìgbéraga ènìyàn búburú.

13Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ asán;

bẹ́ẹ̀ ní Olódùmarè kì yóò kà á sí.

14Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ìwọ wí pé ìwọ kì í rí i,

ọ̀rọ̀ ìdájọ́ ń bẹ níwájú rẹ,

ẹni tí ìwọ sì gbọdọ̀ dúró dè.

15Ṣùgbọ́n nísinsin yìí nítorí tí ìbínú rẹ̀ kò tí fìyà jẹ ni,

òun kò ni ka ìwà búburú si?

16Nítorí náà ní Jobu ṣe ya ẹnu rẹ̀

lásán ó sọ ọ̀rọ̀ di púpọ̀ láìsí ìmọ̀.”

Nouă Traducere În Limba Română

Iov 35:1-16

1Elihu a răspuns și a zis:

2„Crezi că lucrul acesta este drept?

Tu zici: «Sunt drept înaintea lui Dumnezeu.»

3Însă mai spui: «Ce folos am3 Sau: ai.

și ce câștig dacă nu păcătuiesc?»

4Îți voi răspunde ție

și prietenilor tăi care sunt cu tine.

5Uită‑te la ceruri și vezi;

privește cât sunt de sus norii față de tine!

6Dacă ai păcătuit, ce‑I faci Lui?

Iar dacă ți se înmulțesc fărădelegile, ce‑I faci Lui?

7Dacă ești drept, ce‑I dai Lui?

Ce primește El din mâna Ta?

8Răutatea ta este doar pentru un om ca tine,

iar dreptatea ta este doar pentru fiul omului.

9Oamenii strigă din cauza mulțimii asupririlor,

strigă după ajutor din cauza brațului celor mulți,

10dar nimeni nu zice: «Unde este Dumnezeu, Creatorul meu,

Care ne dă cântări de veselie noaptea,

11Care ne învață prin11 Sau: ne învață mai mult decât pe. animalele pământului

și ne face înțelepți prin11 Sau: ne face mai înțelepți decât. păsările cerului?»

12El nu răspunde când oamenii strigă,

din cauza mândriei celor răi.

13Într-adevăr, Dumnezeu nu ascultă strigătul lor zadarnic;

Cel Atotputernic nu‑i dă atenție.

14Deși zici că nu‑L vezi,

cauza ta este înaintea Lui. Să‑L aștepți,

15chiar dacă acum mânia Sa nu pedepsește

și nu‑I pasă prea mult de nesăbuință.

16Prin urmare, Iov își deschide gura degeaba

și spune o mulțime de vorbe fără cunoștință.“