Jobu 30 – YCB & CARS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 30:1-31

Ọ̀rọ̀ ìbànújẹ́ Jobu

1“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí,

àwọn tí mo gbà ní àbúrò ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà

baba ẹni tí èmi kẹ́gàn

láti tò pẹ̀lú àwọn ajá nínú agbo ẹran mi.

2Kí ni ìwúlò agbára ọwọ́ wọn sí mi,

níwọ̀n ìgbà tí agbára wọn ti fi wọ́n sílẹ̀?

3Wọ́n rù nítorí àìní àti ìyàn

wọ́n ń rìn káàkiri ní ilẹ̀ gbígbẹ

ní ibi ìkọ̀sílẹ̀ ní òru.

4Àwọn ẹni tí ń já ewé iyọ̀ ní ẹ̀bá igbó;

gbogbo igikígi ni oúnjẹ jíjẹ wọn.

5A lé wọn kúrò láàrín ènìyàn,

àwọn ènìyàn sì pariwo lé wọn lórí bí ẹní pariwo lé olè lórí.

6A mú wọn gbe inú pàlàpálá òkúta Àfonífojì,

nínú ihò ilẹ̀ àti ti òkúta.

7Wọ́n ń dún ní àárín igbó

wọ́n kó ara wọn jọ pọ̀ ní abẹ́ ẹ̀gún neteli.

8Àwọn ọmọ ẹni tí òye kò yé,

àní àwọn ọmọ lásán, a sì lé wọn jáde kúrò ní orí ilẹ̀.

9“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àwọn ọmọ wọn ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà nínú orin;

àní èmi di ẹni ìṣọ̀rọ̀ sí láàrín wọn.

10Wọ́n kórìíra mi; wọ́n sá kúrò jìnnà sí mi,

wọn kò sì bìkítà láti tutọ́ sí mi lójú.

11Nítorí Ọlọ́run ti tú okùn ìyè mi, ó sì pọ́n mi lójú;

àwọn pẹ̀lú sì dẹ ìdẹ̀kùn níwájú mi.

12Àwọn ènìyàn lásán dìde ní apá ọ̀tún mi;

wọ́n tì ẹsẹ̀ mi kúrò,

wọ́n sì la ipa ọ̀nà ìparun sílẹ̀ dè mí.

13Wọ́n da ipa ọ̀nà mi rú;

wọ́n sì sọ ìparun mi di púpọ̀,

àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.

14Wọ́n ya sí mi bí i omi tí ó ya gbuuru;

ní ariwo ńlá ni wọ́n rọ́ wá.

15Ẹ̀rù ńlá bà mí;

wọ́n lépa ọkàn mi bí ẹ̀fúùfù,

àlàáfíà mi sì kọjá lọ bí àwọ̀ sánmọ̀.

16“Àti nísinsin yìí, ayé mi n yòrò lọ díẹ̀díẹ̀;

ọjọ́ ìpọ́njú mi dì mímú.

17Òru gún mi nínú egungun mi,

èyí tí ó bù mí jẹ kò sì sinmi.

18Nípa agbára ńlá rẹ̀ Ọlọ́run wà bí aṣọ ìbora fún mi,

ó sì lẹ̀ mọ́ mi ní ara yíká bí aṣọ ìlekè mi.

19Ọlọ́run ti mú mi lọ sínú ẹrẹ̀,

èmi sì dàbí eruku àti eérú.

20“Èmi ké pè ọ́ ìwọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi lóhùn;

èmi dìde dúró ìwọ sì wò mí lásán.

21Ìwọ padà di ẹni ìkà sí mi; ọwọ́

agbára rẹ ni ìwọ fi dè mí ní ọ̀nà.

22Ìwọ gbé mi sókè sí inú ẹ̀fúùfù, ìwọ mú mi fò lọ,

bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì sọ mí di asán pátápátá.

23Èmi sá à mọ̀ pé ìwọ yóò mú mi lọ sínú ikú,

sí ilé ìpéjọ tí a yàn fún gbogbo alààyè.

24“Bí ó ti wù kí ó rí, ẹnìkan kí yóò ha nawọ́ rẹ̀ nígbà ìṣubú rẹ̀,

tàbí kì yóò ké nínú ìparun rẹ̀.

25Èmi kò ha sọkún bí fún ẹni tí ó wà nínú ìṣòro?

Ọkàn mi kò ha bàjẹ́ fún tálákà bí?

26Nígbà tí mo fojú ṣọ́nà fún àlàáfíà, ibi sì dé;

nígbà tí mo dúró de ìmọ́lẹ̀, òkùnkùn sì dé.

27Ikùn mí n ru kò sì sinmi;

Ọjọ́ ìpọ́njú ti dé bá mi.

28Èmí ń rìn kiri nínú ọ̀fọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú oòrùn;

èmi dìde dúró ní àwùjọ mo sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́.

29Èmi ti di arákùnrin ìkookò,

èmi di ẹgbẹ́ àwọn ògòǹgò.

30Àwọ̀ mi di dúdú ní ara mi;

egungun mi sì jórun fún ooru.

31Ohun èlò orin mi pẹ̀lú sì di ti ọ̀fọ̀,

àti ìpè orin mi sì di ohùn àwọn tí ń sọkún.

Священное Писание

Аюб 30:1-31

1А теперь они надо мной смеются –

те, кто младше меня,

чьих отцов я бы погнушался

поместить с собаками при моих стадах.

2И к чему мне сила их рук,

если в них истощилась мощь?

3Нищетой и голодом изнурены,

бродят они в опалённой земле30:3 Или: «гложут они опалённую землю».,

в разорённом краю, во мраке.

4У кустов собирают горькие травы,

и корни дрока – их еда30:4 Или: «дрова»..

5Гонят их из среды людей

и, как ворам, кричат им вслед.

6Им велят селиться в оврагах долин,

среди скал и в расщелинах земли.

7Воют они среди зарослей

и жмутся друг к другу под тёрном.

8Отверженный, безымянный сброд,

изгнанный из страны.

9А теперь они песней меня язвят,

посмешищем для них я стал.

10Гнушаются меня, избегают меня

и в лицо мне плевать не стыдятся.

11Всевышний сделал меня слабым и беспомощным30:11 Букв.: «Он развязал мою верёвку и поразил меня».,

и они распоясались предо мной.

12Эти отродья нападают на меня с правого боку,

гоняют меня с места на место

и на погибель мне готовят осаду.

13Заграждают мне путь;

всё творят на беду мне –

и никто их не сдерживает30:13 Или: «безо всякой помощи»..

14Как сквозь брешь на меня идут,

всё круша, на меня бросаются.

15Ужасы ринулись на меня;

моя слава развеяна, точно ветром,

и уплыло, как облако, благоденствие.

16И теперь угасает во мне моя жизнь;

обступили меня дни скорби.

17Ночью ноют кости мои;

боль меня гложет, не зная покоя.

18Всевышний хватает одежду мою неистово;

Он давит меня, как воротник рубахи.

19В грязь поверг Он меня,

я стал как прах и пепел.

20Я зову Тебя, о Всевышний, но нет ответа;

встаю, но Ты лишь смотришь на меня.

21Ты безжалостным стал ко мне;

мощью руки Своей гонишь меня.

22Ты подхватил, помчал меня в вихре;

Ты швыряешь меня прямо в рокочущую бурю.

23Я знаю: Ты к смерти меня ведёшь,

в дом, уготованный всем живущим.

24О, никто не поднимет руку на бедняка,

когда тот зовёт на помощь в своём несчастье!

25Не плакал ли я о тех, кто в беде?

Разве о бедных душа моя не скорбела?

26Но когда я ждал добра, пришло зло;

уповал я на свет, но настала тьма.

27Сердце тревогой объято, покоя не ведает;

для меня настали дни скорби.

28Хожу почерневший, но не от солнца;

встаю перед людьми и взываю о помощи.

29Я теперь брат шакалам

и друг совам.

30Кожа моя чернеет и шелушится;

в лихорадке горит тело.

31На плач настроена моя арфа,

и свирель моя – на напев печальный.