Jobu 28 – YCB & AKCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 28:1-28

Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n àti òye Jobu

1Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ,

àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.

2Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin,

bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.

3Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn,

ó sì ṣe àwárí ìṣúra

láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.

4Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè,

àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀,

wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.

5Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá,

àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná

6Òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta Safire,

o sì ní erùpẹ̀ wúrà.

7Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀,

àti ojú gúnnugún kò rí i rí;

8Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí,

bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.

9Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta,

ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.

10Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta,

ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.

11Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya,

ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.

12Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí,

níbo sì ni òye ń gbe?

13Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀,

bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.

14Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”;

omi Òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”

15A kò le è fi wúrà rà á,

bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òṣùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.

16A kò le è fi wúrà ofiri,

tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta Safire díye lé e.

17Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀;

bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.

18A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi;

iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.

19Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀;

bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.

20Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá?

Tàbí níbo ni òye ń gbé?

21A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo,

ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.

22Ibi ìparun àti ikú wí pé,

àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.

23Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀,

òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.

24Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé,

ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,

25Láti dà òṣùwọ̀n fún afẹ́fẹ́,

ó sì fi òṣùwọ̀n wọ́n omi.

26Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò,

tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,

27Nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde;

ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.

28Àti fún ènìyàn ni ó wí pé,

“Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n,

àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”

Akuapem Twi Contemporary Bible

Hiob 28:1-28

1“Beae a wotu dwetɛ wɔ hɔ

ne beae a wɔnan sika kɔkɔɔ.

2Wotu dade fi fam,

na wɔnan kɔbere fi dadebo mu.

3Onipa ma sum ba awiei;

na ɔhwehwɛ kɔ akyirikyiri asase mu

kɔhwehwɛ dadebo wɔ sum kabii mu.

4Wɔde fagudetu afiri hyɛ beae a ɛmmɛn ɔdesani atenae,

mmeae a nnipa anan nsii hɔ da,

baabi a ɛmmɛn nnipa no, ɛhɔ na wodi aforosian.

5Asase a ɛbɔ aduan no,

wɔdan ase no te sɛ nea wɔde ogya na ayɛ;

6hoabo fi nʼabotan mu

na sikakɔkɔɔ mpɔw nso wɔ ne mfutuma mu.

7Ɔkɔre biara nnim saa kwan a ahintaw no,

akoroma biara ani nhuu ɛ.

8Mmoa ahantanfo nsi hɔ

na gyata nkɔdɛɛdɛɛ wɔ hɔ.

9Onipa nsa paapae abotan dennen

na ɔma mmepɔw ase da hɔ.

10Otwa aka fa abotan mu,

na ohu nʼademude nyinaa.

11Ɔhwehwɛ baabi a nsubɔnten ti wɔ

na ɔda nneɛma a ahintaw adi.

12“Nanso ɛhe na yebehu nea nyansa hyɛ?

Ɛhe na ntease te?

13Onipa renhu ne bo a ɛsom;

wɔrenhu wɔ ateasefo asase so.

14Na ebun ka se, ‘Enni me mu’;

na po nso se, ‘Enni me nkyɛn.’

15Wɔrentumi mfa sikakɔkɔɔ ankasa ntɔ,

na wɔrentumi mfa dwetɛ nkari ne bo.

16Wɔrentumi mfa Ofir sikakɔkɔɔ ntɔ

apopobibiribo anaa hoabo nso saa ara.

17Wɔrentumi mfa ahwehwɛ anaa sikakɔkɔɔ ntoto ho,

na wɔrentumi mfa sikakɔkɔɔ nnwinne nsesa.

18Ɛnsɛ sɛ yɛbɔ ahene panyin ne ahwehwɛbo din;

nyansa bo sen nhene pa.

19Etiopia akraatebo ne no nsɛ;

wɔrentumi mfa sikakɔkɔɔ kronkron ntɔ.

20“Ɛno de, na ɛhe na nyansa fi?

Ɛhe na ntease te?

21Wɔde asie abɔde biara ani,

wɔde asie wim nnomaa mpo.

22Ɔsɛe ne Owu ka se,

‘Yɛate no huhuhuhu kɛkɛ.’

23Onyankopɔn te ɔkwan a ɛkɔ hɔ ase,

na ɔno nko ara na onim faako a ɛte,

24efisɛ ɔhwɛ kodu nsase ano

na ohu biribiara a ɛwɔ ɔsoro ase.

25Bere a ɔhyɛɛ mframa ano den too hɔ

na osusuw nsuwa no,

26bere a ɔkaa no ɔhyɛ so kyerɛɛ osutɔ

na otwaa kwan maa aprannaa no,

27afei ɔhwɛɛ nyansa na ɔkarii no hwɛe;

na ogyee no too mu na ɔsɔɔ no hwɛe.

28Na ɔka kyerɛɛ onipa se,

Awurade suro, ɛno ne nyansa;

na sɛ wokyi bɔne, yɛ ntease.’ ”