Jobu 27 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 27:1-23

1Pẹ̀lúpẹ̀lú Jobu sì tún sọkún ọ̀rọ̀ òwe rẹ̀, ó sì wí pé:

2“Bí Ọlọ́run ti ń bẹ, ẹni tí ó gba ìdájọ́ mi lọ,

àti Olódùmarè tí ó bà mi ní ọkàn jẹ́;

3(Níwọ́n ìgbà tí ẹ̀mí mi ń bẹ nínú mi,

àti tí ẹ̀mí Ọlọ́run ń bẹ nínú ihò imú mi.)

4Ètè mi kì yóò sọ̀rọ̀ èké,

Bẹ́ẹ̀ ni ahọ́n mi kì yóò sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.

5Kí a má rí i pé èmi ń dá yín láre;

títí èmi ó fi kú, èmi kì yóò ṣí ìwà òtítọ́ mi kúrò lọ́dọ̀ mi.

6Òdodo mi ni èmi dìímú ṣinṣin, èmi kì yóò sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́;

àyà mi kì yóò sì gan ọjọ́ kan nínú ọjọ́ ayé mi.

7“Kí ọ̀tá mi kí ó dàbí ènìyàn búburú,

àti ẹni tí ń dìde sí mi kí ó dàbí ẹni aláìṣòdodo.

8Nítorí kí ni ìrètí àgàbàgebè,

nígbà tí Ọlọ́run bá ké ẹ̀mí rẹ̀ kúrò, nígbà tí ó sì fà á jáde?

9Ọlọ́run yóò ha gbọ́ àdúrà rẹ̀,

nígbà tí ìpọ́njú bá dé sí i?

10Òun ha le ní inú dídùn sí Olódùmarè?

Òun ha lé máa ké pe Ọlọ́run nígbà gbogbo?

11“Èmi ó kọ́ yín ní ẹ̀kọ́ ní ti ọwọ́ Ọlọ́run:

ọ̀nà tí ń bẹ lọ́dọ̀ Olódùmarè ni èmi kì yóò fi pamọ́.

12Kíyèsi i, gbogbo yín ni ó ti rí i;

kín ni ìdí ọ̀rọ̀ asán yín?

13“Ẹ̀yin ni ìpín ènìyàn búburú lọ́dọ̀ Ọlọ́run,

àti ogún àwọn aninilára, tí wọ́n ó gbà lọ́wọ́ Olódùmarè:

14Bí àwọn ọmọ rẹ bá di púpọ̀, fún idà ni;

àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ kì yóò yó fún oúnjẹ.

15Àwọn tí ó kù nínú tirẹ̀ ni a ó sìnkú nínú àjàkálẹ̀-ààrùn:

àwọn opó rẹ̀ kì yóò sì sọkún fún wọn.

16Bí ó tilẹ̀ kó fàdákà jọ bí erùpẹ̀,

tí ó sì dá aṣọ jọ bí amọ̀;

17àwọn ohun tí ó tò jọ àwọn olóòtítọ́ ni yóò lò ó;

àwọn aláìṣẹ̀ ni yóò sì pín fàdákà rẹ̀.

18Òun kọ́ ilé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí kòkòrò aṣọ,

àti bí ahéré tí olùṣọ́ kọ́.

19Ọlọ́rọ̀ yóò dùbúlẹ̀, ṣùgbọ́n òun kì yóò túnṣe bẹ́ẹ̀ mọ́;

Nígbà tí ó bá la ojú rẹ̀, gbogbo rẹ̀ a lọ

20Ẹ̀rù ńlá bà á bí omi ṣíṣàn;

ẹ̀fúùfù ńlá jí gbé lọ ní òru.

21Ẹ̀fúùfù ìlà-oòrùn gbé e lọ, òun sì lọ;

àti bí ìjì ńlá ó sì fà á kúrò ní ipò rẹ̀.

22Nítorí pé Olódùmarè yóò kọlù ú, kì yóò sì dá sí;

òun ìbá yọ̀ láti sá kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.

23Àwọn ènìyàn yóò sì ṣápẹ́ sí i lórí,

wọn yóò sì ṣe síọ̀ sí i kúrò ní ipò rẹ̀.”

Nouă Traducere În Limba Română

Iov 27:1-23

1Iov și‑a continuat discursul și a zis:

2„Viu este Dumnezeu, Care nu‑mi dă dreptate,

Cel Atotputernic, Care mi‑a amărât sufletul,

3că atâta vreme cât am suflare,

cât am suflarea lui Dumnezeu în nările mele,

4buzele mele nu vor rosti vreo nedreptate

și limba mea nu va spune nimic înșelător.

5Departe de mine gândul să vă dau dreptate;

îmi voi apăra integritatea până îmi voi da suflarea!

6Îmi voi susține neclintit dreptatea;

inima nu mă va mustra pentru niciuna din zilele mele.

7Fie ca dușmanul meu să aibă soarta celui rău

și cel ce se ridică împotriva mea să aibă soarta celui nedrept.

8Ce speranță mai are cel lipsit de evlavie

când Dumnezeu îi taie firul vieții,

când Dumnezeu îi ia viața?

9Îi va auzi Dumnezeu strigătul

când va veni necazul asupra lui?

10Se va desfăta el în Cel Atotputernic?

Va chema el pe Dumnezeu în orice vreme?

11Vă voi învăța despre puterea 11 Lit.: mâna.lui Dumnezeu!

Nu voi ascunde ceea ce este cu Cel Atotputernic.

12Iată, voi înșivă ați văzut cu toții aceasta.

De ce atunci vorbiți deșertăciune?

13Aceasta este partea omului nelegiuit de la Dumnezeu

și moștenirea celor groaznici de la Cel Atotputernic.

14Dacă i se înmulțesc fiii, ei sunt pentru sabie,

și odraslele lui nu se vor sătura niciodată de pâine.

15Pe supraviețuitorii lui îi va îngropa moartea,

iar văduvele lor nu‑i vor plânge.

16Deși adună argintul precum adună țărâna,

și hainele precum grămezile de lut,

17ceea ce el pregătește, va fi îmbrăcat de cel drept,

iar cel nevinovat va împărți argintul lui.

18El își zidește casa ca o molie

și ca o colibă făcută de un străjer.

19Când se culcă este bogat, dar nu va mai fi așa;

când își deschide ochii toate s‑au dus.

20Spaimele îl cuprind ca un șuvoi;

o vijelie îl smulge în timpul nopții.

21Vântul de răsărit îl ia și îl duce,

îl smulge din locul său ca o furtună.

22Vuiește asupra lui fără milă

când el fuge grăbit de puterea lui.

23Îi bate din palme în derâdere

și‑l alungă din locul lui cu fluierături.