Jobu 22 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 22:1-30

Èsì Elifasi

1Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé:

222.2,3: Jb 35.6-8.“Ènìyàn lè è ṣe rere fún Ọlọ́run?

Bí ọlọ́gbọ́n ti í ṣe rere fún ara rẹ̀?

3Ohun ayọ̀ ha ni fún Olódùmarè pé olódodo ni ìwọ?

Tàbí èrè kí ni fún un ti ìwọ mú ọ̀nà rẹ̀ pé?

4“Yóò ha bá ọ wí bí, nítorí ìbẹ̀rù

Ọlọ́run rẹ? Yóò ha bá ọ lọ sínú ìdájọ́ bí?

5Ìwà búburú rẹ kò ha tóbi,

àti ẹ̀ṣẹ̀ rẹ láìníye?

6Nítòótọ́ ìwọ béèrè fún ààbò ni ọwọ́ arákùnrin rẹ láìnídìí,

ìwọ sì tú oníhòhò ní aṣọ wọn.

7Ìwọ kò fi omi fún aláàárẹ̀ mu,

ìwọ sì háwọ́ oúnjẹ fún ẹni tí ebi ń pa.

8Bí ó ṣe ti alágbára nì, òun ni ó ní ilẹ̀,

ọlọ́lá sì tẹ̀dó sínú rẹ̀.

9Ìwọ ti rán àwọn opó padà lọ ní ọwọ́ òfo;

Apá àwọn ọmọ aláìní baba ti di ṣiṣẹ́.

10Nítorí náà ni ìdẹ̀kùn ṣe yí ọ káàkiri,

àti ìbẹ̀rù òjijì ń yọ ọ́ lẹ́nu,

11Èéṣe tí òkùnkùn fi pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè ríran;

Èéṣe tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi sì bò ọ́ mọ́lẹ̀.

12“Ọlọ́run kò ha jẹ́ ẹni gíga ọ̀run?

Sá wo orí àwọn ìràwọ̀ bí wọ́n ti ga tó!

13Ìwọ sì wí pé, Ọlọ́run ti ṣe mọ̀?

Òun ha lè ṣe ìdájọ́ láti inú òkùnkùn wá bí?

14Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ tí ó nípọn jẹ ìbora fún un,

tí kò fi lè ríran; ó sì ń rìn nínú àyíká ọ̀run.

15Ǹjẹ́ ìwọ fẹ́ rin ipa ọ̀nà ìgbàanì tí àwọn

ènìyàn búburú tí rìn?

16A ké wọn lulẹ̀ kúrò nínú ayé láìpé ọjọ́ wọn;

ìpìlẹ̀ wọn ti da bí odò ṣíṣàn;

17Àwọn ẹni tí ó wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!

Kí ni Olódùmarè yóò ṣe fún wọn?’

18Síbẹ̀ ó fi ohun rere kún ilé wọn!

Ṣùgbọ́n ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi!

19Àwọn olódodo rí ìparun wọn, wọ́n sì yọ̀,

àwọn aláìlẹ́ṣẹ̀ sì fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà pé,

20‘Lóòtítọ́ àwọn ọ̀tá wa ni a ké kúrò,

iná yóò sì jó oró wọn run.’

21“Fa ara rẹ súnmọ́ Ọlọ́run, ìwọ ó sì rí àlàáfíà;

nípa èyí ni rere yóò wá bá ọ.

22Èmi bẹ̀ ọ́, gba òfin láti ẹnu rẹ̀ wá,

kí o sì to ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí àyà rẹ.

23Bí ìwọ bá yípadà sọ́dọ̀ Olódùmarè, a sì gbé ọ ró:

Bí ìwọ bá sì mú ẹ̀ṣẹ̀ jìnnà réré kúrò nínú àgọ́ rẹ,

24Tí ìwọ bá tẹ́ wúrà dáradára sílẹ̀

lórí erùpẹ̀ àti wúrà ofiri lábẹ́ òkúta odò,

25Nígbà náà ní Olódùmarè yóò jẹ́ wúrà rẹ,

àní yóò sì jẹ́ fàdákà fún ọ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.

26Lóòtítọ́ nígbà náà ní ìwọ ó ní inú dídùn nínú Olódùmarè,

ìwọ ó sì gbé ojú rẹ sókè sọ́dọ̀ Ọlọ́run.

27Bí ìwọ bá gbàdúrà rẹ sọ́dọ̀ rẹ̀, yóò sì gbọ́ tìrẹ,

ìwọ ó sì san ẹ̀jẹ́ rẹ.

28Ìwọ ó sì gbìmọ̀ ohun kan pẹ̀lú, yóò sì fi ìdí múlẹ̀ fún ọ;

ìmọ́lẹ̀ yóò sì mọ́ sípa ọ̀nà rẹ.

29Nígbà tí ipa ọ̀nà rẹ bá lọ sísàlẹ̀,

nígbà náà ni ìwọ o wí pé, ‘Ìgbésókè ń bẹ!’

Ọlọ́run yóò sì gba onírẹ̀lẹ̀ là!

30Yóò gba ẹni tí kì í ṣe aláìjẹ̀bi là,

a ó sì gbà á nípa mímọ́ ọwọ́ rẹ̀.”

Persian Contemporary Bible

ايوب 22:1-30

گفتگوی سوم

(22‏:1‏—27‏:23)

اليفاز سخن می‌گويد: گناه ايوب بزرگ است

1آنگاه اليفاز تيمانی پاسخ داد:

2آيا از انسان فايده‌ای به خدا می‌رسد؟ حتی از خردمندترين انسانها نيز فايده‌ای به او نمی‌رسد! 3اگر تو عادل و درستكار باشی آيا نفع آن به خدا می‌رسد؟ 4اگر تو خداترس باشی آيا او تو را مجازات می‌كند؟ 5هرگز! مجازات تو برای شرارت و گناهان بی‌شماری است كه در زندگی مرتكب شده‌ای! 6تو بدون شک از دوستان محتاجی كه به تو مقروض بودند تمام لباسهایشان را گرو گرفته، چيزی برايشان باقی نگذاشته‌ای. 7به تشنگان آب نداده‌ای و شكم گرسنگان را سير نكرده‌ای، 8هر چند تو آدم توانگر و ثروتمندی بودی و املاک زيادی داشتی. 9بيوه‌زنان را دست خالی از پيش خود رانده و به يتيمان رحم نكرده‌ای. 10‏-11برای همين است كه اكنون دچار دامها و ترسهای غيرمنتظره شده‌ای و ظلمت و امواج وحشت، تو را فرا گرفته‌اند.

12خدا بالاتر از آسمانها و بالاتر از بلندترين ستارگان است. 13ولی تو می‌گويی: «خدا چگونه می‌تواند از پس ابرهای تيره، اعمال مرا مشاهده و داوری كند؟ 14ابرها او را احاطه كرده‌اند و او نمی‌تواند ما را ببيند. او در آن بالا، بر گنبد آسمان حركت می‌كند.»

15آيا می‌خواهی به راهی بروی كه گناهكاران در گذشته از آن پيروی كرده‌اند؟ 16كسانی كه اساس زندگيشان فرو ريخت و نابهنگام مردند؟ 17زيرا به خدای قادر مطلق گفتند: «ای خدا از ما دور شو! تو چه كاری می‌توانی برای ما انجام دهی؟» 18در حالی که خدا خانه‌هايشان را سرشار از بركت ساخته بود. بنابراين من خود را از راههای شروران دور نگه خواهم داشت. 19‏-20درستكاران و بی‌گناهان هلاكت شروران را می‌بينند و شاد شده، می‌خندند و می‌گويند: «دشمنان ما از بين رفتند و اموالشان در آتش سوخت.»

21ای ايوب، از مخالفت با خدا دست بردار و با او صلح كن تا لطف او شامل حال تو شود. 22دستورات او را بشنو و آنها را در دل خود جای بده. 23اگر به سوی خدا بازگشت نموده، تمام بديها را از خانهٔ خود دور كنی، آنگاه زندگی تو همچون گذشته سروسامان خواهد گرفت. 24اگر طمع را از خود دور كنی و طلای خود را دور بريزی، 25آنگاه خدای قادر مطلق خودش گنج و نقرهٔ خالص برای تو خواهد بود! 26به او اعتماد خواهی كرد و از وجود او لذت خواهی برد. 27نزد او دعا خواهی نمود و او دعای تو را اجابت خواهد كرد و تو تمام نذرهايت را به جا خواهی آورد. 28دست به هر كاری بزنی موفق خواهی شد و بر راههايت هميشه نور خواهد تابيد. 29اگر كسی به تو حمله كند و تو را به زمين افكند، می‌دانی كسی هست كه دوباره تو را بلند كند. بلی، او فروتنان را نجات می‌دهد؛ 30پس اگر فروتن شده، خود را از گناه پاکسازی او تو را خواهد رهانيد.