Jobu 21 – YCB & TCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 21:1-34

Jobu dá Sofari lóhùn

1Jobu wá dáhùn, ó sì wí pé:

2“Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ dáradára sì àwọn ọ̀rọ̀ mi,

kí èyí kí ó jásí ìtùnú fún mi.

3Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbà

ìwọ le máa fi mi ṣẹ̀sín ń ṣo.

4“Àròyé mi ha ṣe sí ènìyàn bí?

Èétise tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?

5Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín,

kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.

6Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí,

ìwárìrì sì mú mi lára.

7Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà ní

ayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?

8Irú-ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojú

wọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ ọmọ wọn ní ojú wọn.

9Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀

ni ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run kò sí lára wọn.

10Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì í sì

tàsé; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun;

11Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọn

wẹ́wẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jo kiri.

12Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àti

haapu, wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè.

13Wọ́n n lo ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọn

sì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà.

14Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!’

Nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ.

15Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máa sìn in?

Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?

16Kíyèsi i, àlàáfíà wọn kò sí nípa

ọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi réré.

17“Ìgbà mélòó mélòó ní a ń pa fìtílà ènìyàn búburú kú?

Ìgbà mélòó mélòó ní ìparun wọn dé bá wọn,

tí Ọlọ́run sì í máa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?

18Wọ́n dàbí àgékù koríko níwájú afẹ́fẹ́,

àti bí ìyàngbò, tí ẹ̀fúùfù ńlá fẹ́ lọ.

19Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’

Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.

20Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀,

yóò sì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.

21Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀,

nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?

22“Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni le kọ Ọlọ́run ní ìmọ̀?

Òun ní í sá à ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.

23Ẹnìkan a kú nínú pípé agbára rẹ̀,

ó wà nínú ìrora àti ìdákẹ́ pátápátá.

24Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú,

egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.

25Ẹlòmíràn a sì kú nínú kíkorò ọkàn rẹ̀,

tí kò sì fi inú dídùn jẹun.

26Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínú erùpẹ̀,

kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.

27“Kíyèsi i, èmi mọ̀ èrò inú yín àti

àrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.

28Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní ilé ọmọ-aládé,

àti níbo ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’

29Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjá lọ ní ọ̀nà?

Ẹ̀yin kò mọ̀ ààmì wọn, pé

30ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fún ọjọ́ ìparun.

A ó sì mú wọn jáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.

31Ta ni yóò tako ipa ọ̀nà rẹ̀ lójúkojú,

ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?

32Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú,

a ó sì máa ṣọ́ ibojì òkú.

33Ògúlùtu àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn.

Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́

lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ síwájú rẹ̀.

34“Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínú lásán,

bí ò ṣe pé ní ìdáhùn yín, àrékérekè wa níbẹ̀!”

Tagalog Contemporary Bible

Job 21:1-34

Nagsalita si Job

1Sumagot si Job, 2“Pakinggan ninyo akong mabuti upang mapasaya rin ninyo ako. 3Makinig kayo habang nagsasalita ako at kapag akoʼy tapos na, tuyain ninyo ako kung gusto ninyo.

4“Ang hinaing koʼy hindi laban sa tao kundi sa Dios. Ito ang dahilan kung bakit maikli ang pasensya ko. 5Tingnan ninyo ako. Sa nakita ninyo sa akin makakapagsalita pa ba kayo? 6Kung iisipin ko ang mga nangyayari sa akin, manginginig ako sa takot.

7“Bakit patuloy na nabubuhay ang mga masama? Tumatanda sila at nagiging maunlad. 8Nakikita nila ang paglaki ng kanilang mga anak at apo. 9Namumuhay sila sa kanilang tahanan na ligtas sa panganib at walang kinatatakutan. Hindi sila pinaparusahan ng Dios. 10Walang tigil ang panganganak ng kanilang mga baka at hindi ito nakukunan. 11Marami silang anak, parang kawan ng tupa sa dami.21:11 Marami … sa dami: o, Pinaglalaro nila ang kanilang mga anak tulad ng mga tupa. Nagsasayawan sila, 12nag-aawitan, at nagkakatuwaan sa tugtog ng tamburin, alpa at plauta. 13Namumuhay sila sa kasaganaan at payapang namamatay. 14Pero sinasabi nila sa Dios, ‘Pabayaan mo kami! Ayaw naming malaman ang iyong mga pamamaraan. 15Sino kang Makapangyarihan na dapat naming paglingkuran? At ano ba ang mapapala namin kung mananalangin kami sa iyo?’ 16Pero ang totoo, ang pag-unlad nilaʼy hindi galing sa sarili nilang pagsisikap. Kaya anuman ang ipapayo ng masasamang taong ito ay hindi ko tatanggapin.

17“Pero madalang ang taong masasama na namamatay. Bihirang dumating sa kanila ang kahirapan o parusang ipinapadala ng Dios dahil sa kanyang galit. 18Bihira nilang maranasan ang mapalayas tulad ng ipa na tinatangay ng malakas na hangin. 19Sinasabi ninyo na kapag hindi sila parurusahan ng Dios ang mga anak nila ang parurusahan. Pero sa ganang akin, ang nagkasala ang siyang dapat parusahan ng Dios para maranasan nila 20at makita ang kanilang kapahamakan. Matikman sana nila ang galit ng Makapangyarihang Dios. 21Kapag patay na sila, hindi na nila malalaman ang mga nangyayari sa kanilang sambahayan.

22“Matuturuan ba ng tao ang Dios, na siya ngang pinakamataas na hukom? 23May mga taong namamatay sa gitna ng kasaganaan at panatag na kalagayan, 24at malusog na pangangatawan. 25May mga tao ring namamatay sa kahirapan, at hindi nakaranas ng kahit kaunting kaginhawahan sa buhay. 26Pero pareho rin silang ililibing sa lupa at kakainin ng mga uod.

27“Alam ko kung ano ang nasa isip ninyo. Alam ko kung ano ang binabalak ninyo laban sa akin. 28Sasabihin ninyo sa akin ang tungkol sa mga taong mayaman na nawasak ang tahanan dahil sa kanilang kasamaan. 29Pero tanungin mo ang mga dumadaan at pakinggan ang sinasabi nila. Sapagkat sasabihin nila sa inyo na 30palaging naliligtas ang masasamang tao sa araw ng pagpaparusa ng Dios. 31Walang hayagang sumasaway sa taong masama. Walang gumaganti sa masama niyang ginawa. 32-33At kapag namatay siya at inihatid sa kanyang huling hantungan, marami ang nakikipaglibing. Tinatanggap ng lupa ang katawan niya at binibigyan ng kapahingahan. Binabantayan pa ang kanyang libingan.

34“Kaya paano ninyo ako maaaliw sa pamamagitan ng mga salita ninyong walang kabuluhan? Ang mga sinasabi ninyoʼy walang katotohanan!”