Jobu 20 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 20:1-29

Ìdáhùn Sofari

1Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé:

2“Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn,

àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.

3Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye

mi sì dá mi lóhùn.

4“Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́,

láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,

5pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni,

àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?

6Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run,

ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;

7Ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀;

àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’

8Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i,

àní a ó lé e lọ bi ìran òru.

9Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́,

bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.

10Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà,

ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.

11Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀,

tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.

12“Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀,

bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,

13bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀,

tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,

14Ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà,

ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;

15Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde;

Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.

16Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú;

ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.

17Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì,

ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.

18Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì;

gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.

19Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti kẹ́hìndà wọ́n;

Nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.

20“Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀,

kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.

21Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀;

Nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.

22Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a;

àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.

23Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun,

Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́,

yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.

24Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn;

ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.

25O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára;

idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá.

Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;

26òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀.

Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run

yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.

27Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn,

ayé yóò sì dìde dúró sí i.

28Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun

ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.

29Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá,

àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”

New International Reader’s Version

Job 20:1-29

The Second Speech of Zophar

1Then Zophar the Naamathite replied,

2“My troubled thoughts force me to answer you.

That’s because I’m very upset.

3What you have just said dishonors me.

So I really have to reply to you.

4“I’m sure you must know how things have always been.

They’ve been that way

ever since human beings were placed on this earth.

5Those who are evil are happy for only a short time.

The joy of ungodly people lasts only for a moment.

6Their pride might reach all the way up to the heavens.

Their heads might touch the clouds.

7But they will disappear forever,

like the waste from their own bodies.

Anyone who has seen them will say,

‘Where did they go?’

8Like a dream they will fly away.

They will never be seen again.

They will be driven away like visions in the night.

9The eyes that saw them won’t see them anymore.

Even their own families won’t remember them.

10Their children must pay back what they took from poor people.

Their own hands must give back the wealth they stole.

11They might feel young and very strong.

But they will soon lie down in the dust of their graves.

12“Anything that is evil tastes sweet to them.

They keep it under their tongues for a while.

13They can’t stand to let it go.

So they hold it in their mouths.

14But their food will turn sour in their stomachs.

It will become like the poison of a serpent inside them.

15They will spit out the rich food they swallowed.

God will make their stomachs throw it up.

16They will suck the poison of a serpent.

The fangs of an adder will kill them.

17They won’t enjoy streams that flow with honey.

They won’t enjoy rivers that flow with cream.

18What they worked for they must give back

before they can eat it.

They won’t enjoy what they have earned.

19They’ve crushed poor people and left them with nothing.

They’ve taken over houses they didn’t even build.

20“No matter how much they have,

they always long for more.

But their treasure can’t save them.

21There isn’t anything left for them to eat up.

Their success won’t last.

22While they are enjoying the good life,

trouble will catch up with them.

Terrible suffering will come on them.

23When they’ve filled their stomachs,

God will pour out his great anger on them.

He’ll strike them down with blow after blow.

24They might run away from iron weapons.

But arrows that have bronze tips will wound them.

25They will pull the arrows out of their backs.

They will remove the shining tips from their livers.

They will be filled with terror.

26Total darkness hides and waits for their treasures.

God will send a fire that will destroy them.

It will burn up everything that’s left in their tents.

27Heaven will show their guilt to everyone.

The earth will be a witness against them.

28A flood will carry their houses away.

Rushing water will wash them away

on the day when God judges.

29Now you know what God will do to sinful people.

Now you know what he has planned for them.”