Jobu 14 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 14:1-22

Jobu tẹ̀síwájú nínú àròyé rẹ̀

1“Ènìyàn tí a bí nínú obìnrin,

ọlọ́jọ́ díẹ̀ ni, ó sì kún fún ìpọ́njú.

2Ó jáde wá bí ìtànná ewéko, a sì ké e lulẹ̀;

ó sì ń fò lọ bí òjìji, kò sì dúró pẹ́.

3Ìwọ sì ń ṣíjú rẹ wò irú èyí ni?

Ìwọ sì mú mi wá sínú ìdájọ́ pẹ̀lú rẹ?

4Ta ni ó lè mú ohun mímọ́ láti inú àìmọ́ jáde wá?

Kò sí ẹnìkan!

5Ǹjẹ́ a ti pinnu ọjọ́ rẹ̀,

iye oṣù rẹ̀ ń bẹ ní ọwọ́ rẹ;

Ìwọ ti pààlà rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ní òun kò le kọjá rẹ̀.

6Yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kí ó lè

sinmi, títí yóò fi pé ọjọ́ rẹ̀ bí alágbàṣe.

7“Nítorí pé ìrètí wà fún igi, bí a bá

ké e lulẹ̀, pé yóò sì tún sọ,

àti pé ẹ̀ka rẹ̀ tuntun kì yóò gbẹ.

8Bí gbòǹgbò rẹ̀ tilẹ̀ di ogbó nínú ilẹ̀,

tí kùkùté rẹ̀ si kú ni ilẹ̀;

9Síbẹ̀ nígbà tí ó bá gbóòórùn omi,

yóò sọ, yóò sì yọ ẹ̀ka jáde bí irúgbìn.

10Ṣùgbọ́n ènìyàn kú, a sì dàánù;

Àní ènìyàn jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́: Òun kò sì sí mọ́.

Àgékúrú ọjọ́ ọmọ ènìyàn

11“Bí omi ti í tán nínú ipa odò,

àti bí odò ṣì tí í fà tí sì gbẹ,

12bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn dùbúlẹ̀ tí kò sì dìde mọ́;

títí ọ̀run kì yóò fi sí mọ́,

wọ́n kì yóò jí, a kì yóò jí wọn kúrò lójú oorun wọn.

13“Háà! ìwọ ìbá fi mí pamọ́ ní ipò òkú,

kí ìwọ kí ó fi mí pamọ́ ní ìkọ̀kọ̀,

títí ìbínú rẹ yóò fi rékọjá,

ìwọ ìbá lànà ìgbà kan sílẹ̀ fún mi, kí ó si rántí mi!

14Bí ènìyàn bá kú yóò sì tún yè bí?

Gbogbo ọjọ́ ìgbà tí a là sílẹ̀

fún mi ni èmi dúró dè, títí àmúdọ̀tún mi yóò fi dé.

15Ìwọ ìbá pè, èmi ìbá sì dá ọ lóhùn;

ìwọ ó sì ní ìfẹ́ sì iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.

16Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ń kaye ìṣísẹ̀ mi;

ìwọ kò fa ọwọ́ rẹ kúrò nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mi?

17A fi èdìdì di ìrékọjá mi sínú àpò,

ìwọ sì rán àìṣedéédéé mi pọ̀.

18“Àti nítòótọ́ òkè ńlá tí ó ṣubú, ó dasán,

a sì ṣí àpáta kúrò ní ipò rẹ̀.

19Omi a máa yinrin òkúta, ìwọ a sì

mú omi sàn bo ohun tí ó hù jáde lórí ilẹ̀,

ìwọ sì sọ ìrètí ènìyàn dí òfo.

20Ìwọ ṣẹ́gun rẹ̀ láéláé, òun sì kọjá lọ!

Ìwọ pa awọ ojú rẹ̀ dà, o sì rán an lọ kúrò.

21Àwọn ọmọ rẹ̀ bọ́ sí ipò ọlá, òun kò sì mọ̀;

wọ́n sì rẹ̀ sílẹ̀, òun kò sì kíyèsi i lára wọn.

22Ṣùgbọ́n ẹran-ara rẹ̀ ni yóò rí

ìrora. Ọkàn rẹ̀ ni yóò sì máa ní ìbìnújẹ́ nínú rẹ̀.”