Jobu 10 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 10:1-22

Àròyé Jobu tẹ̀síwájú

1“Agara ìwà ayé mi dá mi tán,

èmi yóò tú àròyé mi sókè lọ́dọ̀ mi,

èmi yóò máa sọ̀rọ̀ nínú kíkorò ìbìnújẹ́ ọkàn mi.

2Èmi yóò wí fún Ọlọ́run pé: má ṣe dá mi lẹ́bi;

fihàn mí nítorí ìdí ohun tí ìwọ fi ń bá mi jà.

3Ó ha tọ́ tí ìwọ ìbá fi máa ni mí lára,

tí ìwọ ìbá fi máa gan iṣẹ́ ọwọ́ rẹ,

tí ìwọ yóò fi máa tàn ìmọ́lẹ̀ sí ìmọ̀ ènìyàn búburú.

4Ojú rẹ kì ha ṣe ojú ènìyàn bí?

Tàbí ìwọ a máa ríran bí ènìyàn ti í ríran?

5Ọjọ́ rẹ ha dàbí ọjọ́ ènìyàn,

ọdún rẹ ha dàbí ọjọ́ ènìyàn?

6Tí ìwọ fi ń béèrè àìṣedéédéé mi,

tí ìwọ sì fi wá ẹ̀ṣẹ̀ mi rí?

7Ìwọ mọ̀ pé èmi kì í ṣe oníwà búburú,

kò sì sí ẹni tí ó le gbà mí kúrò ní ọwọ́ rẹ?

8“Ọwọ́ rẹ ni ó mọ mi, tí ó sì da mi.

Síbẹ̀ ìwọ tún yípadà láti jẹ mí run.

9Èmi bẹ̀ ọ́ rántí pé ìwọ ti mọ mí bí amọ̀;

ìwọ yóò ha sì tún mú mi padà lọ sínú erùpẹ̀?

10Ìwọ kò ha ti tú mí dà jáde bí i wàrà,

ìwọ kò sì mú mí dìpọ̀ bí i wàràǹkàṣì?

11Ìwọ sá ti fi àwọ̀ ẹran-ara wọ̀ mí,

ìwọ sì fi egungun àti iṣan ṣọgbà yí mi ká.

12Ìwọ ti fún mi ní ẹ̀mí àti ojúrere,

ìbẹ̀wò rẹ sì pa ọkàn mi mọ́.

13“Nǹkan wọ̀nyí ni ìwọ sì ti fi pamọ́ nínú rẹ;

èmi mọ̀ pé, èyí ń bẹ ní ọkàn rẹ.

14Bí mo bá ṣẹ̀, nígbà náà ni ìwọ yóò máa ṣọ́ mi

ìwọ kì yóò sì dárí àìṣedéédéé mi jì.

15Bí mo bá ṣe ẹni búburú, ègbé ni fún mi!

Bí mo bá sì ṣe ẹni rere,

bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì le gbe orí mi sókè.

Èmi dààmú, mo si wo ìpọ́njú mi.

16Bí mo bá gbé orí mi ga. Ìwọ ń dẹ mí kiri bi i kìnnìún;

àti pẹ̀lú, ìwọ a sì fi ara rẹ hàn fún mi ní ìyànjú.

17Ìwọ sì tún mun àwọn ẹlẹ́rìí rẹ dìde sí mi

di ọ̀tún, Ìwọ sì sọ ìrunú rẹ di púpọ̀ sí mi;

Àwọn ogun rẹ si dìde sinmi bi igbe omi Òkun.

18“Nítorí kí ni ìwọ ṣe mú mi jáde láti inú wá?

Háà! Èmi ìbá kúkú ti kú, ojúkójú kì bá tí rí mi.

19Tí kò bá le jẹ́ pé èmi wà láààyè,

À bá ti gbé mi láti inú lọ isà òkú.

20Ọjọ́ mi kò ha kúrú bí? Rárá!

Dáwọ́ dúró, kí ó sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ mi.

Nítorí kí èmi lè ni ayọ̀ ní ìṣẹ́jú kan.

21Kí èmi kí ó tó lọ sí ibi tí èmi kì yóò padà sẹ́yìn mọ́,

Àní si ilẹ̀ òkùnkùn àti òjìji ikú.

22Ilẹ̀ òkùnkùn bí òkùnkùn tìkára rẹ̀,

Àti ti òjìji ikú àti rúdurùdu,

Níbi tí ìmọ́lẹ̀ dàbí òkùnkùn.”

Swedish Contemporary Bible

Job 10:1-22

Job beklagar att han blivit född

1Jag är trött på livet.

Jag vill klaga öppet!

Jag ska tala ut om min innerliga bitterhet.

2Jag ska säga till Gud:

Döm mig inte,

utan låt mig få veta vad du anklagar mig för!

3Gläds du åt att förtrycka,

förkasta en som du själv har skapat,

samtidigt som du ler åt de ogudaktigas planer?

4Har du en människas ögon?

Ser du som de dödliga ser?

5Är dina dagar som den dödliges,

dina år som en människas?

6Du söker ju fel hos mig,

letar efter mina synder,

7fastän du vet att jag inte är skyldig.

Det finns ingen räddning ur din hand.

8Du har skapat mig och allt i mig med dina händer,

och ändå bryter du ner mig.

9Tänk på att du formade mig som lera.

Vill du nu låta mig återvända till stoft igen?

10Du tömde ut mig som mjölk

och lät mig stelna som en ost.

11Du klädde mig i hud och kött

och band mig samman med ben och senor.

12Du gav mig livet

och var nådig mot mig,

min ande bevarades genom din omsorg.

13Men detta hade du i sinnet,

jag visste dina tankar:

14om jag syndade,

skulle du vakta på mig

och aldrig befria mig från min skuld.

15Ve mig om jag är skyldig!

Och om jag är oskyldig

kan jag ändå inte lyfta mitt huvud.

Jag är full av skam och inser mitt elände.

16Om jag försöker resa mig från marken,

rusar du på mig snabbt som ett lejon

och låter mig känna av din förunderliga makt.

17Du skaffar nya vittnen mot mig,

öser över mig din ständigt växande vrede

och låter nya härar anfalla mig.10:17 Grundtextens innebörd är osäker.

18Varför lät du mig då komma ut ur moderlivet?

Varför fick jag inte dö innan någon såg mig?

19Då hade jag varit som om jag aldrig hade funnits,

jag skulle ha burits direkt från moderlivet till graven.

20Mina dagar är ju korta.

Låt mig få vara i fred,

så att jag kan få ett kort ögonblick av glädje,

21innan jag går till landet utan återvändo,

till det djupaste mörkrets land,

22till ett land av mörkaste natt, djupaste skugga och förvirring,

där ljuset är likt mörker.