Jobu 1 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 1:1-22

Ìbẹ̀rẹ̀ ìgbé ayé Jobu

1Ọkùnrin kan wà ní ilẹ̀ Usi, orúkọ ẹni tí í jẹ́ Jobu; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́, ó dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó kórìíra ìwà búburú, 2A sì bi ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta fún un. 3Ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin (7,000) àgùntàn, àti ẹgbẹ̀ẹ́dógún (3,000) ìbákasẹ, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (500) àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (500) abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì pọ̀; bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin yìí sì pọ̀jù gbogbo àwọn ará ìlà-oòrùn lọ.

4Àwọn ọmọ rẹ̀ a sì máa lọ í jẹun àsè nínú ilé ara wọn, olúkúlùkù ní ọjọ́ rẹ̀; wọn a sì máa ránṣẹ́ pé arábìnrin wọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta láti jẹun àti láti pẹ̀lú wọn. 5Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ àsè wọn pé yíká, ni Jobu ránṣẹ́ lọ í yà wọ́n sí mímọ́, ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì rú ẹbọ sísun níwọ̀n iye gbogbo wọn; nítorí tí Jobu wí pé: bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣọpẹ́ fún Ọlọ́run lọ́kàn wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Jobu máa ń ṣe nígbà gbogbo.

Ìdánwò Jobu àkọ́kọ́

6Ǹjẹ́ ó di ọjọ́ kan, nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá í pé níwájú Olúwa, Satani sì wá pẹ̀lú wọn. 7Olúwa sì bi Satani wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?”

Nígbà náà ní Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Ní ìlọ-síwá-sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé, àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”

8Olúwa sì sọ fún Satani pé, “Ìwọ ha kíyèsi Jobu ìránṣẹ́ mi, pé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí í ṣe olóòtítọ́, tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti ó sì kórìíra ìwà búburú.”

9Nígbà náà ni Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Jobu ha bẹ̀rù Ọlọ́run ní asán bí?” 10“Ìwọ kò ha ti ṣọgbà yìí ká, àti yí ilé rẹ̀ àti yí ohun tí ó ní ká, ní ìhà gbogbo? Ìwọ bùsi iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì ń pọ̀ si ní ilẹ̀. 11Ǹjẹ́, nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó sì fi tọ́ ohun gbogbo tí ó ni; bí kì yóò sì bọ́hùn ni ojú rẹ.”

12Olúwa sì dá Satani lóhùn wí pé, “Kíyèsi i, ohun gbogbo tí ó ní ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, kìkì òun tìkára rẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ rẹ kàn.”

Bẹ́ẹ̀ ni Satani jáde lọ kúrò níwájú Olúwa.

13Ó sì di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, tí wọ́n mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n wọn ọkùnrin, 14oníṣẹ́ kan sì tọ Jobu wá wí pé: “Àwọn ọ̀dá màlúù ń tulẹ̀, àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì ń jẹ ní ẹ̀gbẹ́ wọn; 15Àwọn ará Sabeani sì kọlù wọ́n, wọ́n sì ń kó wọn lọ pẹ̀lú, wọ́n ti fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa, èmi nìkan ṣoṣo ní ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ.”

16Bí ó ti ń sọ ní ẹnu; ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé, “Iná ńlá Ọlọ́run ti ọ̀run bọ́ sí ilẹ̀, ó sì jó àwọn àgùntàn àti àwọn ìránṣẹ́; èmi nìkan ṣoṣo ní ó sálà láti ròyìn fún ọ.”

17Bí ó sì ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan sì dé pẹ̀lú tí ó wí pé, “Àwọn ará Kaldea píngun sí ọ̀nà mẹ́ta, wọ́n sì kọlù àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì kó wọn lọ, pẹ̀lúpẹ̀lú wọ́n sì fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ!”

18Bí ó ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin ń jẹ, wọ́n ń mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n. 19Sì kíyèsi i, ẹ̀fúùfù ńláńlá ti ìhà ijù fẹ́ wá kọlu igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilé, ó sì wó lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wọ́n sì kú, èmi nìkan ṣoṣo ni ó yọ láti ròyìn fún ọ.

20Nígbà náà ni Jobu dìde, ó sì fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, ó sì fá orí rẹ̀ ó wólẹ̀ ó sì gbàdúrà 21wí pé:

“Ní ìhòhò ní mo ti inú ìyá mi jáde wá,

ni ìhòhò ní èmi yóò sì tún padà lọ.

Olúwa fi fún ni, Olúwa sì gbà á lọ,

ìbùkún ni fún orúkọ Olúwa.”

22Nínú gbogbo èyí Jobu kò ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi òmùgọ̀ pe Ọlọ́run lẹ́jọ́.

Persian Contemporary Bible

ايوب 1:1-22

ايوب و خانواده‌اش

1در سرزمين عوص مردی زندگی می‌كرد به نام ايوب. او مردی بود درستكار و خداترس كه از گناه دوری می‌ورزيد. 2‏-3ايوب هفت پسر و سه دختر داشت و صاحب هفت هزار گوسفند، سه هزار شتر، پانصد جفت گاو، پانصد الاغ ماده و نوكران بسيار بود. او ثروتمندترين مرد سراسر آن ناحيه به شمار می‌رفت.

4هر يک از پسران ايوب به نوبت در خانهٔ خود جشنی بر پا می‌كردند و همهٔ برادران و خواهران خود را دعوت می‌نمودند تا در آن جشن شركت كنند. 5وقتی روزهای جشن به پايان می‌رسيد، ايوب صبح زود برمی‌خاست و برای طهارت هر كدام از فرزندانش به خداوند قربانی تقديم می‌كرد. ايوب اين كار را مرتب انجام می‌داد، تا اگر احياناً پسرانش ندانسته نسبت به خدا گناه كرده باشند، بدين وسيله گناهشان آمرزيده شود.

آزمايش ايمان ايوب

6يک روز كه فرشتگان در حضور خداوند حاضر شده بودند، شيطان نيز همراه ايشان بود.

7خداوند از شيطان پرسيد: «كجا بودی؟»

شيطان پاسخ داد: «دور زمين می‌گشتم و در آن سير می‌كردم.»

8آنگاه خداوند از او پرسيد: «آيا بندهٔ من ايوب را ديدی؟ بر زمين، كسی همچون او پيدا نمی‌شود. او مردی درستكار و خداترس است و از گناه دوری می‌ورزد.»

9شيطان گفت: «اگر خداترسی برای او سودی نمی‌داشت اين كار را نمی‌كرد. 10ايوب و خانواده و اموالش را از هر گزندی محفوظ داشته‌ای. دسترنج او را بركت داده‌ای و ثروت زياد به او بخشيده‌ای. 11دارايی‌اش را از او بگير، آنگاه خواهی ديد كه آشكارا به تو كفر خواهد گفت!»

12خداوند در پاسخ شيطان گفت: «برو و هر كاری كه می‌خواهی با دارايی‌اش بكن، فقط آسيبی به خود او نرسان.» پس شيطان از بارگاه خداوند بيرون رفت.

13يک روز وقتی پسران و دختران ايوب در خانهٔ برادر بزرگشان میهمان بودند، 14‏-15قاصدی پيش ايوب آمد و به او گفت: «گاوهايت شخم می‌زدند و ماده الاغهايت كنار آنها می‌چريدند كه ناگهان سابی‌ها1‏:14‏و15 «سابی‌ها» قبيله‌ای وحشی و غارتگر بودند.‏ به ما حمله كرده، حيوانات را بردند و تمام كارگران تو را كشتند. تنها من جان به در بردم و آمدم تا به تو خبر دهم.»

16سخنان اين مرد هنوز پايان نيافته بود كه قاصد ديگری از راه رسيده، گفت: «آتش خدا از آسمان نازل شده، تمام گوسفندان و همهٔ چوپانانت را سوزاند و تنها من جان به در برده، آمدم تا به تو خبر دهم.»

17پيش از آنكه حرفهای وی تمام شود قاصدی ديگر وارد شده، گفت: «كلدانيان در سه دسته به ما حمله كردند و شترهايت را بردند و كارگرانت را كشتند، تنها من جان به در بردم و آمده‌ام تا به تو خبر دهم.»

18سخنان آن قاصد هم هنوز تمام نشده بود كه قاصد ديگری از راه رسيد و گفت: «پسران و دخترانت در خانهٔ برادر بزرگشان میهمان بودند، 19كه ناگهان باد شديدی از طرف بيابان وزيده، خانه را بر سر ايشان خراب كرد و همه زير آوار جان سپردند و تنها من جان به در بردم و آمده‌ام تا اين خبر را به تو برسانم.»

20آنگاه ايوب برخاسته، از شدت غم لباس خود را پاره كرد. سپس موی سر خود را تراشيد و در حضور خدا به خاک افتاده، 21گفت: «از شكم مادر برهنه به دنيا آمدم و برهنه هم از اين دنيا خواهم رفت. خداوند داد و خداوند گرفت. نام خداوند متبارک باد.»

22با همهٔ اين پيش‌آمدها، ايوب گناه نكرد و به خدا ناسزا نگفت.