Joẹli 3 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Joẹli 3:1-21

A dá orílẹ̀-èdè lẹ́jọ́

1“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àti ní àkókò náà,

nígbà tí èmi tún mú ìgbèkùn Juda àti Jerusalẹmu padà bọ̀.

2Èmi yóò kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ

pẹ̀lú èmi yóò sì mú wọn wá sí Àfonífojì Jehoṣafati.

Èmi yóò sì bá wọn wíjọ́ níbẹ̀ nítorí àwọn ènìyàn mi,

àti nítorí Israẹli ìní mi,

tí wọ́n fọ́nká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè,

wọ́n sì pín ilẹ̀ mi.

3Wọ́n si ti di ìbò fún àwọn ènìyàn mi;

wọ́n sì ti fi ọmọdékùnrin kan fún panṣágà obìnrin kan,

wọ́n sì ta ọmọdébìnrin kan fún

ọtí wáìnì, kí wọ́n kí ó lè mu.

43.4-8: Isa 23; El 26.1–28.19; Am 1.9-10; Sk 9.3-4; El 28.20-26; Sk 9.2; Isa 14.29-31; Jr 47; El 25.15-17; Am 1.6-8; Sf 2.4-7; Sk 9.5-7.“Nísinsin yìí, kí ni ẹ̀yin ní fi mí ṣe Tire àti Sidoni, àti gbogbo ẹ̀yin ẹkún Filistia? Ẹ̀yin yóò ha sàn ẹ̀san fún mi? Bí ẹ̀yin bá sì san ẹ̀san fún mi, ní kánkán àti ní kíákíá ní èmi yóò san ẹ̀san ohun ti ẹ̀yin ṣe padà sórí ara yín. 5Nítorí tí ẹ̀yin tí mú fàdákà mi àti wúrà mi, ẹ̀yin si tí mú ohun rere dáradára mi lọ sínú tẹmpili yín. 6Àti àwọn ọmọ Juda, àti àwọn ọmọ Jerusalẹmu ní ẹ̀yin ti tà fún àwọn ará Giriki, kí ẹ̀yin bá à lè sí wọn jìnnà kúrò ní agbègbè ilẹ̀ ìní wọn.

7“Kíyèsi í, èmi yóò gbé wọ́n dìde kúrò níbi tì ẹ̀yin ti tà wọ́n sí, èmi yóò sì san ẹ̀san ohun ti ẹ ṣe padà sórí ara yín. 8Èmi yóò si tà àwọn ọmọkùnrin yín àti àwọn ọmọbìnrin yín sí ọwọ́ àwọn ọmọ Juda, wọ́n yóò sì tà wọ́n fún àwọn ara Sabeani, fún orílẹ̀-èdè kan tí ó jìnnà réré.” Nítorí Olúwa ní o ti sọ ọ.

9Ẹ kéde èyí ní àárín àwọn kèfèrí;

Ẹ dira ogun,

ẹ jí àwọn alágbára,

Jẹ kí àwọn ajagun kí wọn bẹ̀rẹ̀ ogun,

103.10: Isa 2.4; Mt 4.3.Ẹ fi irin ìtulẹ̀ yín rọ idà,

àti dòjé yín rọ ọ̀kọ̀.

Jẹ́ kí aláìlera wí pé,

“Ara mi le koko.”

11Ẹ wá kánkán, gbogbo ẹ̀yin kèfèrí láti gbogbo àyíká,

kí ẹ sì gbá ara yín jọ yí káàkiri.

Níbẹ̀ ní kí o mú àwọn alágbára rẹ sọ̀kalẹ̀, Olúwa.

12“Ẹ jí, ẹ sì gòkè wá sí Àfonífojì

Jehoṣafati ẹ̀yin kèfèrí:

nítorí níbẹ̀ ní èmi yóò jókòó láti ṣe

ìdájọ́ àwọn kèfèrí yí káàkiri.

13Ẹ tẹ dòjé bọ̀ ọ́,

nítorí ìkórè pọ́n:

ẹ wá, ẹ sọ̀kalẹ̀;

nítorí ìfúntí kún, nítorí àwọn

ọpọ́n kún àkúnwọ́sílẹ̀

nítorí ìwà búburú wọn pọ̀!”

14Ọ̀pọ̀lọpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀

ní àfonífojì ìpinnu,

nítorí ọjọ́ Olúwa kù si dẹ̀dẹ̀

ní àfonífojì ìdájọ́.

15Oòrùn àti òṣùpá yóò ṣú òkùnkùn,

àti àwọn ìràwọ̀ kí yóò tan ìmọ́lẹ̀ wọn mọ́.

16Olúwa yóò sí ké ramúramù láti Sioni wá,

yóò sì fọ ohùn rẹ̀ jáde láti Jerusalẹmu wá;

àwọn ọ̀run àti ayé yóò sì mì tìtì

Ṣùgbọ́n Olúwa yóò ṣe ààbò àwọn ènìyàn rẹ̀,

àti agbára àwọn ọmọ Israẹli.

Ìbùkún fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run

17“Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín,

tí ń gbé Sioni òkè mímọ́ mi.

Ìgbà náà ni Jerusalẹmu yóò jẹ́ mímọ́;

àwọn àjèjì kì yóò sì kó o mọ́.

18“Ní ọjọ́ náà, àwọn òkè ńlá yóò máa kán ọtí wáìnì tuntun sílẹ̀,

àwọn òkè kéékèèkéé yóò máa sàn fún wàrà;

gbogbo odò Juda tí ó gbẹ́ yóò máa sàn fún omi.

Orísun kan yóò sì ṣàn jáde láti inú ilé Olúwa wá,

yóò sì rin omi sí àfonífojì Ṣittimu.

19Ṣùgbọ́n Ejibiti yóò di ahoro,

Edomu yóò sì di aṣálẹ̀ ahoro,

nítorí ìwà ipá tí a hù sì àwọn ọmọ Juda,

ní ilẹ̀ ẹni tí wọ́n ti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.

20Ṣùgbọ́n Juda yóò jẹ́ ibùgbé títí láé,

àti Jerusalẹmu láti ìran dé ìran.

21Nítorí èmi yóò wẹ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wọn nù, tí èmi kò tí ì wẹ̀nù.

Nítorí Olúwa ń gbé Sioni.”

New International Version

Joel 3:1-21

The Nations Judged

In Hebrew texts 3:1-21 is numbered 4:1-21. 1“In those days and at that time,

when I restore the fortunes of Judah and Jerusalem,

2I will gather all nations

and bring them down to the Valley of Jehoshaphat.3:2 Jehoshaphat means the Lord judges; also in verse 12.

There I will put them on trial

for what they did to my inheritance, my people Israel,

because they scattered my people among the nations

and divided up my land.

3They cast lots for my people

and traded boys for prostitutes;

they sold girls for wine to drink.

4“Now what have you against me, Tyre and Sidon and all you regions of Philistia? Are you repaying me for something I have done? If you are paying me back, I will swiftly and speedily return on your own heads what you have done. 5For you took my silver and my gold and carried off my finest treasures to your temples.3:5 Or palaces 6You sold the people of Judah and Jerusalem to the Greeks, that you might send them far from their homeland.

7“See, I am going to rouse them out of the places to which you sold them, and I will return on your own heads what you have done. 8I will sell your sons and daughters to the people of Judah, and they will sell them to the Sabeans, a nation far away.” The Lord has spoken.

9Proclaim this among the nations:

Prepare for war!

Rouse the warriors!

Let all the fighting men draw near and attack.

10Beat your plowshares into swords

and your pruning hooks into spears.

Let the weakling say,

“I am strong!”

11Come quickly, all you nations from every side,

and assemble there.

Bring down your warriors, Lord!

12“Let the nations be roused;

let them advance into the Valley of Jehoshaphat,

for there I will sit

to judge all the nations on every side.

13Swing the sickle,

for the harvest is ripe.

Come, trample the grapes,

for the winepress is full

and the vats overflow—

so great is their wickedness!”

14Multitudes, multitudes

in the valley of decision!

For the day of the Lord is near

in the valley of decision.

15The sun and moon will be darkened,

and the stars no longer shine.

16The Lord will roar from Zion

and thunder from Jerusalem;

the earth and the heavens will tremble.

But the Lord will be a refuge for his people,

a stronghold for the people of Israel.

Blessings for God’s People

17“Then you will know that I, the Lord your God,

dwell in Zion, my holy hill.

Jerusalem will be holy;

never again will foreigners invade her.

18“In that day the mountains will drip new wine,

and the hills will flow with milk;

all the ravines of Judah will run with water.

A fountain will flow out of the Lord’s house

and will water the valley of acacias.3:18 Or Valley of Shittim

19But Egypt will be desolate,

Edom a desert waste,

because of violence done to the people of Judah,

in whose land they shed innocent blood.

20Judah will be inhabited forever

and Jerusalem through all generations.

21Shall I leave their innocent blood unavenged?

No, I will not.”

The Lord dwells in Zion!