Jeremiah 8 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 8:1-22

1“ ‘Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, wọn yóò mú egungun àwọn ọba Juda àti egungun àwọn ìjòyè, egungun àwọn àlùfáà àti egungun àwọn wòlíì àti egungun àwọn olùgbé Jerusalẹmu kúrò nínú ibojì. 2A ó yọ wọ́n síta fún oòrùn àti òṣùpá àti gbogbo àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run tí wọ́n ti fẹ́ràn tí wọ́n sì ti sìn, àti àwọn tí wọ́n ti tọ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti wá tí wọ́n sì ti foríbalẹ̀ fún. Kì yóò ṣà wọ́n jọ tàbí sìn wọ́n, wọn yóò dàbí ìdọ̀tí tó wà lórí ilẹ̀. 3Níbikíbi tí mo bá lé wọn lọ, gbogbo àwọn ìyókù wọn yóò fẹ́ ikú ju ìyè lọ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.’

Ẹ̀ṣẹ̀ àti ìjìyà

4“Wí fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“ ‘Bí ènìyàn bá ṣubú lulẹ̀

wọn kì í padà dìde bí? Nígbà tí

ènìyàn bá yà kúrò ní ọ̀nà rẹ,

kì í yí padà bí?

5Èéṣe nígbà náà àwọn ènìyàn wọ̀nyí

fi yà kúrò lọ́nà rẹ̀? Kí ló dé tí Jerusalẹmu

fi yà kúrò ní gbogbo ìgbà?

Wọ́n rọ̀ mọ́ ẹ̀tàn, wọ́n kọ̀ láti yípadà.

6Mo ti fetísílẹ̀ dáradára, wọn

kò sọ ohun tí ó tọ́. Kò sí ẹnìkan tó

ronúpìwàdà nínú ìwà búburú rẹ̀,

kí ó wí pé, “Kí ni mo ṣe?” Olúkúlùkù

ń tọ ọ̀nà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹṣin tó ń lọ sójú ogun.

7Kódà, ẹyẹ àkọ̀ ojú ọ̀run mọ ìgbà

tirẹ̀, àdàbà, alápáǹdẹ̀dẹ̀ àti lékèélékèé

mọ àkókò ìṣípò padà wọn. Ṣùgbọ́n àwọn

ènìyàn mi kò mọ ohun tí Ọlọ́run wọn fẹ́.

8“ ‘Báwo ni ẹ̀yin ṣe lè wí pé, “Àwa gbọ́n,

nítorí a ní òfin Olúwa,” nígbà

tí ó jẹ́ pé kálámù èké àwọn

akọ̀wé ti àwọn sọ ọ́ di ẹ̀tàn

9Ojú yóò ti àwọn ọlọ́gbọ́n, a ó dà

wọ́n láàmú, wọn yóò sì kó sí ìgbèkùn.

Nítorí wọ́n ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa. Irú ọgbọ́n

wo ló kù tí wọ́n ní?

10Nítorí náà, èmi yóò fi ìyàwó wọn fún

àwọn ọkùnrin mìíràn àti ilẹ̀ wọn

fún àwọn ẹlòmíràn láti èyí tó kéré

jù dé èyí tó dàgbà jù, gbogbo wọn

ni èrè àjẹjù ń jẹ lógún; àwọn wòlíì

àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ń hùwà ẹ̀tàn.

11Wọ́n tọ́jú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́

bí èyí tí kò jinlẹ̀.

“Àlàáfíà, àlàáfíà,” ni wọ́n ń wí,

nígbà tí kò sí àlàáfíà.

12Ǹjẹ́ wọ́n tijú fún ìṣe ìríra wọn? Bẹ́ẹ̀ kọ́,

wọn kò ní ìtìjú rárá; wọn kò tilẹ̀ mọ

bí wọ́n ti ṣe ń tì jú. Nítorí náà

wọn yóò ṣubú pẹ̀lú àwọn tó ti ṣubú,

a ó sì wó wọ́n lulẹ̀ nígbà tí a bá bẹ̀ wọ́n wò,

ni Olúwa wí.

13“ ‘Èmi yóò mú ìkórè wọn kúrò

ni Olúwa wí.

Kì yóò sí èso lórí igi àjàrà,

kì yóò sí ọ̀pọ̀tọ́ lórí igi, ewé wọn yóò sì rẹ̀ sílẹ̀.

Ohun tí mo ti fi fún wọn ni à ó gbà kúrò.’ ”

14“Èéṣe tí àwa fi jókòó ní ibí yìí?

A kó ara wa jọ!

Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi

kí a sì ṣègbé síbẹ̀.

Nítorí tí Olúwa Ọlọ́run wa ti pinnu pé a ó ṣègbé.

Yóò sì fún wa ní omi onímájèlé mu,

nítorí àwa ti ṣẹ̀ sí i.

15Àwa ń retí àlàáfíà,

kò sí ìre kan

tí ó wá ní ìgbà ìmúláradá

bí kò ṣe ìpayà nìkan.

16Ìró ìfọn imú ẹṣin àwọn ọlọ̀tẹ̀

là ń gbọ́ láti Dani,

yíyan àwọn akọ ẹṣin

mú gbogbo ilẹ̀ wárìrì.

Wọ́n wá láti pa ilẹ̀ náà run,

gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,

ìlú náà àti gbogbo olùgbé ibẹ̀.”

17“Wò ó, èmi yóò rán àwọn ejò olóró sí àárín yín,

paramọ́lẹ̀ tí ẹ kò lè pa oró wọn,

yóò sì bù yín jẹ,”

ni Olúwa wí.

18Olùtùnú mi, nígbà tí ìbànújẹ́ ọkàn mi

rẹ̀wẹ̀sì nínú mi.

19Fetí sí ẹkún àwọn ènìyàn mi láti ilẹ̀ jíjìnnà wá:

Olúwa kò ha sí ní Sioni bí?

Ọba rẹ̀ kò sí níbẹ̀ mọ́ ni?”

“Èéṣe tí wọ́n fi mú mi bínú pẹ̀lú ère wọn, pẹ̀lú àwọn

òrìṣà àjèjì tí wọn kò níláárí?”

20“Ìkórè ti rékọjá,

ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn ti parí

síbẹ̀ a kò gbà wá là.”

21Níwọ́n ìgbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run, èmi náà run pẹ̀lú,

èmi ṣọ̀fọ̀, ìrora sì mú mi káká.

22Kò ha sí ìkunra ní Gileadi bí?

Kò ha sí àwọn oníṣègùn níbẹ̀?

Kí ló ha dé tí kò fi sí ìwòsàn

fún ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi?