Jeremiah 51 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 51:1-64

1Ohùn ti Olúwa wí nìyìí:

“Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè

sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai

2Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli

láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo;

wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà

ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.

3Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀

jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀;

má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin

sí, pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.

4Gbogbo wọn ni yóò ṣubú

ní Babeli tí wọn yóò sì

fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.

5Nítorí pé Juda àti Israẹli ni

Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun,

kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn

kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.

651.6,9,45: Jr 50.8; 2Kọ 6.17; If 18.4.“Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà

fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.

Àsìkò àti gbẹ̀san Ọlọ́run ni èyí,

yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.

751.7-8: Jr 25.15; If 14.8,10; 16.19; 17.4; 18.3.Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa;

ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí.

Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀,

wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.

8Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́;

Ẹ hu fun un!

Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ,

bóyá yóò le wo ọ́ sàn.

9“ ‘À bá ti wo Babeli sàn,

ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀,

kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè,

ó ga àní títí dé òfúrufú.’

10“ ‘Olúwa ti dá wa láre,

wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa

Ọlọ́run wa ti ṣe.’

11“Ṣe ọfà rẹ ní mímú,

mú apata!

Olúwa ti ru ọba Media sókè,

nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run.

Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.

12Gbé àsíá sókè sí odi Babeli!

Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí,

ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri,

ẹ ṣètò àwọn tí yóò sápamọ́

Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde,

òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.

1351.13: If 17.1.Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀,

tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé,

àní àsìkò láti ké ọ kúrò!

14Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀,

Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú,

wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.

15“Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀,

o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀,

o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.

16Nígbà tí ará omi ọ̀run hó

ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé.

Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò,

ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.

17“Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ

tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù

alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀.

Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn wọn kò ní èémí nínú.

18Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà,

nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.

19Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí;

nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo,

àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún,

Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

20“Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi,

ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú,

èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.

21Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀;

èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú

èmi ó pa awakọ̀

22Pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin,

pẹ̀lú rẹ, mo pa

àgbàlagbà àti ọmọdé,

Pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.

23Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn,

àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú,

èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú,

èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.

24“Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,”

ni Olúwa wí.

25“Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun

ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,”

ni Olúwa wí.

“Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ,

èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta,

Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.

26A kò ní mú òkúta kankan láti

ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí

fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di

ahoro títí ayé,”

Olúwa wí.

27“Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà!

Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!

Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀,

pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́:

Ararati, Minini àti Aṣkenasi.

Yan olùdarí ogun láti kọlù ú,

rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.

28Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀,

àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀,

àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.

29Ilẹ̀ wárìrì síhìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé

ète Olúwa, sí Babeli dúró

láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà

tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.

30Gbogbo àwọn jagunjagun

Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn.

Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin.

Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun,

gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.

31Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn

láti sọ fún ọba Babeli pé

gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.

32Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́

ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”

33Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí:

“Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”

34“Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run,

ó ti mú kí ìdààmú bá wa,

ó ti sọ wá di àgbá òfìfo.

Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì.

Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀,

lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.

35Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,”

èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí.

“Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,”

ni Jerusalẹmu wí.

36Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí:

“Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí

ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san,

èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.

37Babeli yóò parun pátápátá,

yóò sì di ihò àwọn akátá,

ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.

38Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù

bí ọmọ kìnnìún.

39Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè,

èmi yóò ṣe àsè fún wọn,

èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó

tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín,

lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,”

ni Olúwa wí.

40“Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn

tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.

41“Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé.

Irú ìpayà wo ni yóò bá

Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!

42Òkun yóò ru borí Babeli,

gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.

43Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro,

ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn

kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.

44Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli

àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì.

Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́.

Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.

45“Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀

ẹ̀yin ènìyàn mi!

Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ!

Sá fún ìbínú ńlá Ọlọ́run.

46Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú

tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí

a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa;

àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí,

òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá

ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.

47Nítorí ìgbà náà yóò wá

dandan nígbà tí èmi

yóò fi ìyà jẹ àwọn

òrìṣà Babeli, gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì

gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.

48Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn,

yóò sì kọrin lórí Babeli:

nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,”

ni Olúwa wí.

49“Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli,

gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.

50Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró:

Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè,

ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”

51“Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn:

ìtìjú ti bò wá lójú

nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”

52“Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí,

“tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀:

àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀

53Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run,

bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ,

síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,”

Olúwa wí.

54“Ìró igbe láti Babeli,

àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!

55Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ,

ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀;

àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.

56Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀,

àní sórí Babeli;

a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn:

nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa,

yóò san án nítòótọ́.

57Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí,

àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀

àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀,

wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,”

ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

58Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:

“Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá,

ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun:

tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán,

àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná,

tí àárẹ̀ sì mú wọn.”

59Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó. 60Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli. 61Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí. 62Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’ 6351.63-64: If 18.21.Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate. 64Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’ ”

Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.

Nova Versão Internacional

Jeremias 51:1-64

1Assim diz o Senhor:

“Vejam! Levantarei um vento destruidor

contra a Babilônia, contra o povo de Lebe-Camai51.1 Lebe-Camai é um criptograma para Caldeia, isto é, a Babilônia..

2Enviarei estrangeiros para a Babilônia

a fim de peneirá-la como trigo e devastar a sua terra.

No dia de sua desgraça

virão contra ela de todos os lados.

3Que o arqueiro não arme o seu arco

nem vista a sua armadura.

Não poupem os seus jovens guerreiros,

destruam completamente o seu exército.

4Eles cairão mortos na Babilônia51.4 Ou Caldeia; também nos versículos 24 e 35.,

mortalmente feridos em suas ruas.

5Israel e Judá não foram abandonadas

como viúvas pelo seu Deus,

o Senhor dos Exércitos,

embora a terra dos babilônios esteja cheia de culpa

diante do Santo de Israel.

6“Fujam da Babilônia! Cada um por si!

Não sejam destruídos por causa da iniquidade dela.

É hora da vingança do Senhor;

ele lhe pagará o que ela merece.

7A Babilônia era um cálice de ouro nas mãos do Senhor;

ela embriagou a terra toda.

As nações beberam o seu vinho;

por isso enlouqueceram.

8A Babilônia caiu de repente e ficou arruinada.

Lamentem-se por ela!

Consigam bálsamo para a sua ferida;

talvez ela possa ser curada.

9“ ‘Gostaríamos de ter curado Babilônia,

mas ela não pode ser curada;

deixem-na e vamos,

cada um para a sua própria terra,

pois o julgamento dela chega ao céu,

eleva-se tão alto quanto as nuvens.

10“ ‘O Senhor defendeu o nosso nome;

venham, contemos em Sião

o que o Senhor, o nosso Deus, tem feito’.

11“Afiem as flechas,

peguem os escudos!

O Senhor incitou o espírito dos reis dos medos,

porque seu propósito é destruir a Babilônia.

O Senhor se vingará,

se vingará de seu templo.

12Ergam o sinal para atacar as muralhas da Babilônia!

Reforcem a guarda!

Posicionem as sentinelas!

Preparem uma emboscada!

O Senhor executará o seu plano,

o que ameaçou fazer contra os habitantes da Babilônia.

13Você que vive junto a muitas águas

e está rico de tesouros,

chegou o seu fim,

a hora de você ser eliminado.

14O Senhor dos Exércitos jurou por si mesmo:

Com certeza a encherei de homens,

como um enxame de gafanhotos,

e eles gritarão triunfantes sobre você.

15“Mas foi Deus quem fez a terra com o seu poder;

firmou o mundo com a sua sabedoria

e estendeu os céus com o seu entendimento.

16Ao som do seu trovão, as águas no céu rugem;

ele faz com que as nuvens se levantem desde os confins da terra.

Ele faz relâmpagos para a chuva

e faz sair o vento de seus depósitos.

17“São todos eles estúpidos e ignorantes;

cada ourives é envergonhado pela imagem que esculpiu.

Suas imagens esculpidas são uma fraude,

elas não têm fôlego de vida.

18Elas são inúteis, são objeto de zombaria.

Quando vier o julgamento delas, perecerão.

19Aquele que é a Porção de Jacó não é como esses,

pois ele é quem forma todas as coisas,

e Israel é a tribo de sua propriedade;

Senhor dos Exércitos é o seu nome.

20“Você é o meu martelo,

a minha arma de guerra.

Com você eu despedaço nações,

com você eu destruo reinos,

21com você despedaço cavalo e cavaleiro,

com você despedaço carro de guerra e cocheiro,

22com você despedaço homem e mulher,

com você despedaço velho e jovem,

com você despedaço rapaz e moça,

23com você despedaço pastor e rebanho,

com você despedaço lavrador e bois,

com você despedaço governadores e oficiais.

24“Retribuirei à Babilônia e a todos os que vivem na Babilônia toda a maldade que fizeram em Sião diante dos olhos de vocês”, declara o Senhor.

25“Estou contra você, ó montanha destruidora,

você que destrói a terra inteira”,

declara o Senhor.

“Estenderei minha mão contra você,

eu a farei rolar dos penhascos,

e farei de você uma montanha calcinada.

26Nenhuma pedra sua será cortada

para servir de pedra angular,

nem para um alicerce,

pois você estará arruinada para sempre”,

declara o Senhor.

27“Ergam um estandarte na terra!

Toquem a trombeta entre as nações!

Preparem as nações para o combate contra ela;

convoquem contra ela estes reinos:

Ararate, Mini e Asquenaz.

Nomeiem um comandante contra ela;

lancem os cavalos ao ataque

como um enxame de gafanhotos.

28Preparem as nações para o combate contra ela:

os reis dos medos, seus governadores e todos os seus oficiais

e todos os países que governam.

29A terra treme e se contorce de dor,

pois permanecem em pé

os planos do Senhor contra a Babilônia: desolar a terra da Babilônia

para que fique desabitada.

30Os guerreiros da Babilônia pararam de lutar;

permanecem em suas fortalezas.

A força deles acabou;

tornaram-se como mulheres.

As habitações dela estão incendiadas;

as trancas de suas portas estão quebradas.

31Um emissário vai após outro,

e um mensageiro sai após outro mensageiro

para anunciar ao rei da Babilônia

que sua cidade inteira foi capturada,

32os vaus do rio foram tomados,

a vegetação dos pântanos foi incendiada,

e os soldados ficaram aterrorizados.”

33Assim diz o Senhor dos Exércitos, Deus de Israel:

“A cidade51.33 Hebraico: filha. de Babilônia é como uma eira;

a época da colheita logo chegará para ela”.

34“Nabucodonosor, rei da Babilônia,

devorou-nos, lançou-nos em confusão,

fez de nós um jarro vazio.

Tal como uma serpente ele nos engoliu,

encheu seu estômago com nossas finas comidas

e então nos vomitou.

35Que a violência cometida contra nossa carne51.35 Ou feita a nós e a nossos filhos

esteja sobre a Babilônia”, dizem os habitantes de Sião.

“Que o nosso sangue esteja sobre aqueles que moram na Babilônia”,

diz Jerusalém.

36Por isso, assim diz o Senhor:

“Vejam, defenderei a causa de vocês e os vingarei;

secarei o seu mar e esgotarei as suas fontes.

37A Babilônia se tornará um amontoado de ruínas,

uma habitação de chacais,

objeto de pavor e de zombaria,

um lugar onde ninguém vive.

38O seu povo todo ruge como leõezinhos,

rosnam como filhotes de leão.

39Mas, enquanto estiverem excitados,

prepararei um banquete para eles

e os deixarei bêbados,

para que fiquem bem alegres

e, então, durmam e jamais acordem”,

declara o Senhor.

40“Eu os levarei como cordeiros

para o matadouro,

como carneiros e bodes.

41“Como Sesaque51.41 Sesaque é um criptograma para Babilônia. será capturada!

Como o orgulho de toda a terra será tomado!

Que horror a Babilônia

será entre as nações!

42O mar se levantará sobre a Babilônia;

suas ondas agitadas a cobrirão.

43Suas cidades serão arrasadas,

uma terra seca e deserta,

uma terra onde ninguém mora,

pela qual nenhum homem passa.

44Castigarei Bel na Babilônia

e o farei vomitar o que engoliu.

As nações não mais acorrerão a ele.

E a muralha da Babilônia cairá.

45“Saia dela, meu povo!

Cada um salve a sua própria vida,

da ardente ira do Senhor.

46Não desanimem nem tenham medo

quando ouvirem rumores na terra;

um rumor chega este ano, outro no próximo,

rumor de violência na terra

e de governante contra governante.

47Portanto, certamente vêm os dias

quando castigarei as imagens esculpidas da Babilônia;

toda a sua terra será envergonhada,

e todos os seus mortos jazerão caídos dentro dela.

48Então o céu e a terra e tudo o que existe neles

gritarão de alegria por causa da Babilônia,

pois do norte destruidores a atacarão”,

declara o Senhor.

49“A Babilônia cairá por causa dos mortos de Israel,

assim como os mortos de toda a terra

caíram por causa da Babilônia.

50Vocês que escaparam da espada,

saiam! Não permaneçam!

Lembrem-se do Senhor numa terra distante,

e pensem em Jerusalém.

51“Vocês dirão: ‘Estamos envergonhados,

pois fomos insultados

e a vergonha cobre o nosso rosto,

porque estrangeiros penetraram nos lugares santos

do templo do Senhor’.

52“Portanto, certamente vêm os dias”, declara o Senhor,

“quando castigarei as suas imagens esculpidas,

e por toda a sua terra

os feridos gemerão.

53Mesmo que a Babilônia chegue ao céu

e fortifique no alto a sua fortaleza,

enviarei destruidores contra ela”,

declara o Senhor.

54“Vem da Babilônia o som de um grito;

o som de grande destruição

vem da terra dos babilônios.

55O Senhor destruirá a Babilônia;

ele silenciará o seu grande ruído.

Ondas de inimigos avançarão como grandes águas;

o rugir de suas vozes ressoará.

56Um destruidor virá contra a Babilônia;

seus guerreiros serão capturados,

e seus arcos serão quebrados.

Pois o Senhor é um Deus de retribuição;

ele retribuirá plenamente.

57Embebedarei os seus líderes e os seus sábios;

os seus governadores, os seus oficiais e os seus guerreiros.

Eles dormirão para sempre e jamais acordarão”,

declara o Rei, cujo nome é Senhor dos Exércitos.

58Assim diz o Senhor dos Exércitos:

“A larga muralha da Babilônia será desmantelada

e suas altas portas serão incendiadas.

Os povos se exaurem por nada,

o trabalho das nações não passa de combustível para as chamas”.

59Esta é a mensagem que Jeremias deu ao responsável pelo acampamento, Seraías, filho de Nerias, filho de Maaseias, quando ele foi à Babilônia com o rei Zedequias de Judá, no quarto ano do seu reinado. 60Jeremias escreveu num rolo todas as desgraças que sobreviriam à Babilônia, tudo que fora registrado acerca da Babilônia. 61Ele disse a Seraías: “Quando você chegar à Babilônia, tenha o cuidado de ler todas estas palavras em alta voz. 62Então diga: Ó Senhor, disseste que destruirás este lugar, para que nem homem nem animal viva nele, pois ficará em ruínas para sempre. 63Quando você terminar de ler este rolo, amarre nele uma pedra e atire-o no Eufrates. 64Então diga: Assim Babilônia afundará para não mais se erguer, por causa da desgraça que trarei sobre ela. E seu povo cairá”.

Aqui terminam as palavras de Jeremias.