Jeremiah 2 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 2:1-37

Israẹli kọ Ọlọ́run sílẹ̀

1Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé: 2“Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé:

“Báyìí ni Olúwa wí,

“ ‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ,

ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ

àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù,

nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.

3Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa,

àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀,

gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi,

ibi yóò sì wá sí orí wọn,’ ”

bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.

4Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu

àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.

5Báyìí ni Olúwa wí:

“Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi?

Tí wọ́n fi jìnnà sí mi?

Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán,

àwọn fúnrawọn sì di asán.

6Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà,

tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá,

tí ó mú wa la aginjù já,

tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò,

ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri,

ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’

7Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá

láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀,

ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́,

ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.

8Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé,

‘Níbo ni Olúwa wà?’

Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí,

àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi.

Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali,

wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.

9“Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,”

ni Olúwa wí.

“Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ

10Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó,

ránṣẹ́ lọ sí Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi

kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?

11Orílẹ̀-èdè kan ha á pa Ọlọ́run rẹ̀ dà?

(Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ Ọlọ́run)

àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀

ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.

12Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì

kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,”

ni Olúwa wí.

13“Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì

Wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi

orísun omi ìyè, wọ́n sì ti

ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè

gba omi dúró.

14Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀

ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a

dé tí ó fi di ìkógun?

15Àwọn kìnnìún ké ramúramù

wọ́n sì ń bú mọ́ wọn

wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò

Ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì

ti di ìkọ̀sílẹ̀.

16Bákan náà, àwọn ọkùnrin

Memfisi àti Tafanesi

wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.

17Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí

ara yín nípa kíkọ Ọlọ́run sílẹ̀

nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?

18Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti

láti lọ mu omi ní Ṣihori?

Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria

láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?

19Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín

ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí

mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti

ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ

nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀,

ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,”

ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

20“Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà

rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ

ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’

Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni

àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀

ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.

21Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí

àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá,

Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi

di àjàrà búburú àti aláìmọ́?

22Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà

tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ

síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,”

ni Olúwa Olódùmarè wí.

23“Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́;

Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’?

Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì;

wo ohun tí o ṣe.

Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ

tí ń sá síhìn-ín sọ́hùn-ún.

24Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù

tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ,

ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀?

Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara,

nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.

25Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà,

àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ.

Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni!

Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì,

àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’

26“Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u,

bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli—

àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn,

àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.

27Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’

àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’

wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi,

wọn kò kọ ojú sí mi

síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro,

wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’

28Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí

ẹ ṣe fúnrayín ha a wà?

Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì

gbà yín nígbà tí ẹ bá

wà nínú ìṣòro! Nítorí pé

ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́

bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.

29“Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí?

Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,”

ni Olúwa wí.

30“Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín,

wọn kò sì gba ìbáwí.

Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run,

gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.

31“Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa:

“Mo ha ti di aginjù sí Israẹli

tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri?

Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé,

‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri;

àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’

32Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀,

tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀?

Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.

33Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́!

Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ

34Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀

àwọn tálákà aláìṣẹ̀

bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́

níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé

35Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí

ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀

kò sì bínú sí mi.’

Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ

nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’

36Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri

láti yí ọ̀nà rẹ padà?

Ejibiti yóò dójútì ọ́

gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria

37Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀

pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ,

nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn

tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀,

kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan

fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.

Nova Versão Internacional

Jeremias 2:1-37

A Infidelidade de Israel

1A palavra do Senhor veio a mim: 2“Vá proclamar aos ouvidos de Jerusalém:

“Eu me lembro de sua fidelidade

quando você era jovem:

como noiva, você me amava

e me seguia pelo deserto,

por uma terra não semeada.

3Israel, meu povo, era santo para o Senhor,

os primeiros frutos de sua colheita;

todos os que o devoravam

eram considerados culpados,

e a desgraça os alcançava”, declara o Senhor.

4Ouça a palavra do Senhor, ó comunidade de Jacó,

todos os clãs da comunidade de Israel.

5Assim diz o Senhor:

“Que falta os seus antepassados encontraram em mim,

para que me deixassem e se afastassem de mim?

Eles seguiram ídolos sem valor,

tornando-se eles próprios sem valor.

6Eles não perguntaram:

‘Onde está o Senhor, que nos trouxe do Egito

e nos conduziu pelo deserto,

por uma terra árida e cheia de covas,

terra de seca e de trevas2.6 Ou e da sombra da morte,

terra pela qual ninguém passa e onde ninguém vive?’

7Eu trouxe vocês a uma terra fértil,

para que comessem dos seus frutos

e dos seus bons produtos.

Entretanto, vocês contaminaram a minha terra;

tornaram a minha herança repugnante.

8Os sacerdotes não perguntavam pelo Senhor;

os intérpretes da lei não me conheciam,

e os líderes do povo se rebelaram contra mim.

Os profetas profetizavam em nome de Baal,

seguindo deuses inúteis.

9“Por isso, eu ainda faço denúncias contra vocês”, diz o Senhor,

“e farei denúncias contra os seus descendentes.

10Atravessem o mar até o litoral de Chipre2.10 Hebraico: as ilhas de Quitim. e vejam;

mandem observadores a Quedar2.10 Terra natal de tribos beduínas do deserto siro-árabe. e reparem de perto;

e vejam se alguma vez aconteceu algo assim:

11alguma nação já trocou os seus deuses?

E eles nem sequer são deuses!

Mas o meu povo trocou a sua2.11 Uma antiga tradição de escribas hebreus diz minha. Glória

por deuses inúteis.

12Espantem-se diante disso, ó céus!

Fiquem horrorizados e abismados”, diz o Senhor.

13“O meu povo cometeu dois crimes:

eles me abandonaram,

a mim, a fonte de água viva;

e cavaram as suas próprias cisternas,

cisternas rachadas que não retêm água.

14Acaso Israel, meu povo, é escravo,

escravo de nascimento?

Por que foi então que se tornou presa

15de leões que rugem e urram contra ele?

Arrasaram a sua terra,

queimaram as suas cidades

e as deixaram desabitadas.

16Até mesmo os homens de Mênfis e de Tafnes

raparam2.16 Ou racharam a sua cabeça.

17“Não foi você mesmo o responsável

pelo que aconteceu a você,

ao abandonar o Senhor, o seu Deus?2.17 Conforme a Septuaginta. O Texto Massorético acrescenta quando ele a conduziu pelo caminho?

18Agora, por que você vai ao Egito

beber água do Nilo2.18 Hebraico: Sior, um braço do Nilo.?

E por que vai à Assíria

beber água do Eufrates?

19O seu crime a castigará

e a sua rebelião a repreenderá.

Compreenda e veja como é mau e amargo

abandonar o Senhor, o seu Deus,

e não ter temor de mim”, diz o Soberano,

o Senhor dos Exércitos.

20“Há muito tempo eu quebrei o seu jugo

e despedacei as correias que a prendiam.

Mas você disse: ‘Eu não servirei!’

Ao contrário, em todo monte elevado

e debaixo de toda árvore verdejante,

você se deitava como uma prostituta.

21Eu a plantei como uma videira seleta,

de semente absolutamente pura.

Como, então, contra mim você se tornou uma videira

degenerada e selvagem?

22Mesmo que você se lave com soda

e com muito sabão,

a mancha da sua iniquidade permanecerá diante de mim”,

diz o Soberano Senhor.

23“Como você pode dizer que não se contaminou

e que não correu atrás dos baalins?

Reveja o seu procedimento no vale

e considere o que você tem feito.

Você é como uma camela jovem e arisca

que corre para todos os lados;

24como uma jumenta selvagem habituada ao deserto,

farejando o vento em seu desejo.

Quem é capaz de controlá-la quando está no cio?

Os machos que a procuram não precisam se cansar,

porque logo encontrarão a que está no mês do cio.

25Não deixe que os seus pés se esfolem

nem que a sua garganta fique seca.

Mas você disse: ‘Não adianta!

Eu amo os deuses estrangeiros

e continuarei a ir atrás deles’.

26“Assim como o ladrão fica envergonhado

quando é apanhado em flagrante,

também a comunidade de Israel ficará envergonhada:

seus reis e oficiais,

seus sacerdotes e profetas.

27Pois dizem à madeira: ‘Você é meu pai’

e à pedra: ‘Você me deu à luz’.

Voltaram para mim as costas e não o rosto,

mas na hora da adversidade dizem:

‘Venha salvar-nos!’

28E onde estão os deuses que você fabricou para si?

Que eles venham, se puderem salvá-la

na hora da adversidade!

Porque os seus deuses são tão numerosos

como as suas cidades, ó Judá!

29“Por que vocês fazem denúncias contra mim?

Todos vocês se rebelaram contra mim”,

declara o Senhor.

30“De nada adiantou castigar o seu povo,

eles não aceitaram a correção.

A sua espada tem destruído os seus profetas

como um leão devorador.

31“Vocês, desta geração,

considerem a palavra do Senhor:

“Tenho sido um deserto para Israel?

Uma terra de grandes trevas?

Por que o meu povo diz:

‘Nós assumimos o controle!

Não mais viremos a ti’?

32Será que uma jovem se esquece das suas joias,

ou uma noiva, de seus enfeites nupciais?

Contudo, o meu povo esqueceu-se de mim

por dias sem fim.

33Com quanta habilidade você busca o amor!

Mesmo as mulheres da pior espécie

aprenderam com o seu procedimento.

34Nas suas roupas encontrou-se

o sangue de pobres inocentes,

que não foram flagrados arrombando casas.

Contudo, apesar de tudo isso,

35você diz: ‘Sou inocente;

ele não está irado comigo’.

Mas eu passarei sentença contra você

porque você disse que não pecou.

36Por que você não leva a sério

a sua mudança de rumo?

Você ficará decepcionada com o Egito,

como ficou com a Assíria.

37Você também deixará aquele lugar

com as mãos na cabeça,

pois o Senhor rejeitou aqueles em quem você confia;

você não receberá a ajuda deles.