Jeremiah 2 – YCB & JCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 2:1-37

Israẹli kọ Ọlọ́run sílẹ̀

1Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé: 2“Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé:

“Báyìí ni Olúwa wí,

“ ‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ,

ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ

àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù,

nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.

3Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa,

àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀,

gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi,

ibi yóò sì wá sí orí wọn,’ ”

bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.

4Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu

àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.

5Báyìí ni Olúwa wí:

“Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi?

Tí wọ́n fi jìnnà sí mi?

Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán,

àwọn fúnrawọn sì di asán.

6Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà,

tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá,

tí ó mú wa la aginjù já,

tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò,

ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri,

ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’

7Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá

láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀,

ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́,

ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.

8Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé,

‘Níbo ni Olúwa wà?’

Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí,

àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi.

Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali,

wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.

9“Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,”

ni Olúwa wí.

“Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ

10Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó,

ránṣẹ́ lọ sí Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi

kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?

11Orílẹ̀-èdè kan ha á pa Ọlọ́run rẹ̀ dà?

(Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ Ọlọ́run)

àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀

ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.

12Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì

kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,”

ni Olúwa wí.

13“Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì

Wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi

orísun omi ìyè, wọ́n sì ti

ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè

gba omi dúró.

14Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀

ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a

dé tí ó fi di ìkógun?

15Àwọn kìnnìún ké ramúramù

wọ́n sì ń bú mọ́ wọn

wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò

Ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì

ti di ìkọ̀sílẹ̀.

16Bákan náà, àwọn ọkùnrin

Memfisi àti Tafanesi

wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.

17Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí

ara yín nípa kíkọ Ọlọ́run sílẹ̀

nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?

18Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti

láti lọ mu omi ní Ṣihori?

Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria

láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?

19Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín

ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí

mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti

ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ

nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀,

ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,”

ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

20“Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà

rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ

ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’

Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni

àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀

ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.

21Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí

àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá,

Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi

di àjàrà búburú àti aláìmọ́?

22Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà

tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ

síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,”

ni Olúwa Olódùmarè wí.

23“Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́;

Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’?

Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì;

wo ohun tí o ṣe.

Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ

tí ń sá síhìn-ín sọ́hùn-ún.

24Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù

tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ,

ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀?

Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara,

nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.

25Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà,

àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ.

Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni!

Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì,

àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’

26“Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u,

bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli—

àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn,

àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.

27Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’

àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’

wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi,

wọn kò kọ ojú sí mi

síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro,

wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’

28Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí

ẹ ṣe fúnrayín ha a wà?

Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì

gbà yín nígbà tí ẹ bá

wà nínú ìṣòro! Nítorí pé

ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́

bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.

29“Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí?

Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,”

ni Olúwa wí.

30“Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín,

wọn kò sì gba ìbáwí.

Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run,

gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.

31“Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa:

“Mo ha ti di aginjù sí Israẹli

tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri?

Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé,

‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri;

àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’

32Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀,

tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀?

Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.

33Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́!

Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ

34Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀

àwọn tálákà aláìṣẹ̀

bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́

níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé

35Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí

ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀

kò sì bínú sí mi.’

Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ

nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’

36Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri

láti yí ọ̀nà rẹ padà?

Ejibiti yóò dójútì ọ́

gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria

37Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀

pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ,

nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn

tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀,

kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan

fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.

Japanese Contemporary Bible

エレミヤ書 2:1-37

2

イスラエル、神を捨てる

1主は再び、私に語りました。

2「さあ、エルサレムの町の通りへ行き、大声で次のように語りなさい。

ずっと昔、おまえがまだ若い花嫁だったころ、

わたしを喜ばせようとして

どんなに尽くしてくれたかを覚えている。

また、わたしを愛し、

草木の生えていない荒野にいる時でさえ、

わたしについて来てくれたことも覚えている。

3そのころ、イスラエルはきよい民、

わたしの初子だった。

これに害を加える者はだれでも犯罪人とみなされ、

これに触れる者には大きな災いが降りかかった。

4-5ああ、イスラエルよ。

おまえの先祖は、

どうしてわたしを置き去りにしたのか。

わたしに何か罪でもあったというのか。

わたしに背き、偶像を拝むなど、全く愚かなことだ。

6彼らは、自分たちをエジプトから無事に連れ出し、

だれも足を踏み入れたことのない、

乾ききった死の地である荒野を導き通したのが、

主であるわたしであったことに、

目をふさいでいる。

7わたしは彼らを、実り豊かな地に連れて入り、

大いに祝福した。

ところが、彼らはそこを罪と腐敗の地に変え、

わたしが与えた相続地を汚した。

8祭司でさえ、主を軽んじ、

裁判官もわたしを無視した。

指導者たちはわたしに盾つき、

預言者はバアルを拝み、

意味のないことで時間をつぶした。

9だがわたしは、

まだおまえたちのことをあきらめていない。

わたしに立ち返るようにと、根気強く、

何度でも説得する。

のちのちの子孫にも、同じようにする。

10-11あなたがたの周囲に、

それがどんなものであれ、

昔からいた神々を新しい神々と取り替えた国が

あったかどうか、調べてみよ。

西にあるキプロスに使いを出し、

東にあるケダルの荒野に人を遣わし、

今までにこんなことを聞いたことがあるかどうか、

調べさせてみよ。

ところがわたしの民は、栄光に輝く神を捨て、

代わりに何の役にも立たない偶像を取り入れた。

12天はこれを知って衝撃を受け、恐怖に身をすくめる。

13わたしの民は悪事に悪事を重ねた。

いのちの水の泉であるわたしを捨て、

水をためることもできない、壊れた水ためを作った。

14イスラエルは、どうして奴隷の国になり下がったのか。

どうして捕虜となり、遠い国へ連れて行かれたのか。

15わたしには、

エルサレムに向かって進んで来る大軍が見える。

彼らは天まで届く大声を上げて

エルサレムを破壊し、焼き払い、

人の住めない荒れ地とする。

16エルサレムへ攻め上ろうとする

エジプトの軍隊も見える。

メンピスとタフパヌヘスの町々から行軍し、

イスラエルの栄光と力を踏みにじろうとしている。

17神であるわたしが、行くべき道を示したのに、

おまえが反抗したからだ。

18おまえはエジプトやアッシリヤと手を組んで、

どんな得をしたのか。

19おまえ自身の悪が、おまえを罰する。

神である主に刃向かい、神を捨てることが

どんなに悪いことであり、恐ろしいことであるかを、

身をもって知るようになる。」

こう天の軍勢の主は宣告します。

20「おまえはとうの昔に、わたしのくびきを払いのけ、

わたしのきずなを断ち切った。

わたしの言うことを頑として聞こうとしない。

すべての丘の上、またすべての木の下で、

偶像に深々と頭を下げた。

21こんなことが、ありえるだろうか。

どうして、こんなことになったのか。

おまえを植えた時、あれほど注意して、

最上の苗木を選んだのに、

どうしてこれほど堕落した悪い作物がなったのか。

22石けんと灰汁をどんなにたくさん使っても、

おまえはきれいにならない。

どうしても洗い流せない罪の汚れが、

こびりついている。

それがいつも、わたしの目の前に見え隠れしている。」

こう神は言います。

23「それでもなお、そんなはずはない、

偶像を拝んだ覚えなどない、と言いはるのか。

なぜ、そんなことが言えるのか。

試しに、この国のどの谷へでも行ってみよ。

必死に雄を探し求める雌のらくだよ、

おまえの犯した恐ろしい罪を直視せよ。

24おまえは、くんくんと鼻を鳴らす、

さかりのついた野ろばそのものではないか。

だれが、おまえの欲情を抑えることができようか。

雄は、おまえを探す必要がない。

おまえのほうから飛んで来るのだから。

25ほかの神々を追い回すのは、

いいかげんにやめたらどうだ。

けれどもおまえは言う。

『言ってもむだですよ。

私はこの他国人に恋をしてしまいました。

あとについて行きたいのです。』

26-27イスラエルは、

捕まることだけを恥と考えているどろぼうのようだ。

王、指導者、祭司、それに預言者も、

みな同じだ。

彼らは木彫りの像を父と呼び、

石細工の偶像を母と呼ぶ。

ところが、いざ困ったことが起こると、

助けてくださいと、わたしに泣きつく。

28自分たちが作った神々に呼ばわったらどうだ。

危険が近づいたら、彼らに助けてもらえばいい。

ユダの町の数ほど神々をかかえているのだから。

29おまえたちはみな反逆者だ。

なぜわたしを主と呼ぶのか。

30おまえたちの子らを懲らしめたが、むだだった。

彼らは、いっこうに従おうとしない。

おまえたち自身も、ライオンが獲物を殺すように、

わたしの預言者たちを殺した。

31ああ、わたしの民よ、神のことばに耳を傾けよ。

わたしはイスラエルに、何か不正をしただろうか。

わたしは彼らにとって、

暗闇に覆われた地のようだったか。

それなのにどうして、わたしの民は

『やっと神から自由になれた。

もう二度とかかわり合いになりたくない』

と言うのか。

32どうして、いとも簡単に

神を捨てることができるのか。

おとめは、自分の大切な宝石を忘れはしない。

どんな花嫁も、

結婚衣装を隠すような愚かなまねはしない。

ところがどうだ。

わたしの民は、最も貴重な宝であるわたしを、

長い間忘れたままでいる。

33おまえたちは恋人を手に入れるためには、

なんと念入りで巧みな計画を立てることか。

そのやり方は、ベテランの売春婦でさえ、

学ぶところが多いくらいだ。

34着ている物には、罪のない貧しい人の血がついている。

おまえたちは理由もなく、

平然と人殺しをやってのける。

35しかも、そのあとは口をぬぐい、

『神を怒らせることなど、何もしていない。

神が腹を立てるわけがない』としらを切る。

『罪を犯していない』と、あくまでもしらを切るので、

わたしはおまえたちをきびしく罰する。

36おまえたちは、ここかしこと飛び回り、

次々と同盟国を乗り換え、助けを求めて歩き回る。

だが、そんなことをしてもむだだ。

おまえたちの新しい友人、エジプトは、

かつてのアッシリヤのように、おまえたちを見捨てる。

37わたしがおまえたちの頼りにしている者を退けるので、

おまえたちは両手で顔を覆い、

失望のあまりしゃがみ込んでしまう。

たとえ彼らの助けがあったにしても、

うまくいくはずはない。