Jeremiah 2 – YCB & CARST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 2:1-37

Israẹli kọ Ọlọ́run sílẹ̀

1Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé: 2“Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé:

“Báyìí ni Olúwa wí,

“ ‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ,

ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ

àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù,

nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.

3Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa,

àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀,

gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi,

ibi yóò sì wá sí orí wọn,’ ”

bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.

4Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu

àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.

5Báyìí ni Olúwa wí:

“Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi?

Tí wọ́n fi jìnnà sí mi?

Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán,

àwọn fúnrawọn sì di asán.

6Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà,

tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá,

tí ó mú wa la aginjù já,

tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò,

ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri,

ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’

7Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá

láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀,

ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́,

ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.

8Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé,

‘Níbo ni Olúwa wà?’

Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí,

àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi.

Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali,

wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.

9“Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,”

ni Olúwa wí.

“Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ

10Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó,

ránṣẹ́ lọ sí Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi

kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?

11Orílẹ̀-èdè kan ha á pa Ọlọ́run rẹ̀ dà?

(Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ Ọlọ́run)

àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀

ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.

12Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì

kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,”

ni Olúwa wí.

13“Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì

Wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi

orísun omi ìyè, wọ́n sì ti

ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè

gba omi dúró.

14Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀

ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a

dé tí ó fi di ìkógun?

15Àwọn kìnnìún ké ramúramù

wọ́n sì ń bú mọ́ wọn

wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò

Ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì

ti di ìkọ̀sílẹ̀.

16Bákan náà, àwọn ọkùnrin

Memfisi àti Tafanesi

wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.

17Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí

ara yín nípa kíkọ Ọlọ́run sílẹ̀

nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?

18Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti

láti lọ mu omi ní Ṣihori?

Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria

láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?

19Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín

ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí

mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti

ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ

nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀,

ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,”

ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

20“Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà

rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ

ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’

Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni

àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀

ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.

21Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí

àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá,

Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi

di àjàrà búburú àti aláìmọ́?

22Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà

tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ

síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,”

ni Olúwa Olódùmarè wí.

23“Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́;

Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’?

Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì;

wo ohun tí o ṣe.

Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ

tí ń sá síhìn-ín sọ́hùn-ún.

24Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù

tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ,

ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀?

Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara,

nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.

25Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà,

àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ.

Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni!

Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì,

àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’

26“Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u,

bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli—

àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn,

àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.

27Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’

àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’

wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi,

wọn kò kọ ojú sí mi

síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro,

wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’

28Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí

ẹ ṣe fúnrayín ha a wà?

Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì

gbà yín nígbà tí ẹ bá

wà nínú ìṣòro! Nítorí pé

ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́

bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.

29“Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí?

Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,”

ni Olúwa wí.

30“Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín,

wọn kò sì gba ìbáwí.

Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run,

gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.

31“Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa:

“Mo ha ti di aginjù sí Israẹli

tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri?

Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé,

‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri;

àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’

32Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀,

tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀?

Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.

33Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́!

Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ

34Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀

àwọn tálákà aláìṣẹ̀

bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́

níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé

35Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí

ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀

kò sì bínú sí mi.’

Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ

nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’

36Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri

láti yí ọ̀nà rẹ padà?

Ejibiti yóò dójútì ọ́

gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria

37Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀

pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ,

nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn

tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀,

kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan

fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

Иеремия 2:1-37

Отступничество Исроила

1И сказал мне Вечный:

2– Иди и провозгласи во всеуслышание в Иерусалиме: Так говорит Вечный:

«Я вспоминаю, как преданна ты была в юности,

когда ты любила Меня, как невеста,

и шла за Мной по пустыне,

по земле незасеянной.

3Исроил был святыней Вечного,

первым плодом Его жатвы;

все, кто его поедал, были преданы осуждению,

их постигала беда», –

возвещает Вечный.

4Слушайте слово Вечного, потомки Якуба,

все кланы Исроила.

5Так говорит Вечный:

– Какой грех нашли во Мне ваши отцы,

что так отдалились от Меня?

Они поклонялись ничтожным идолам

и сами стали ничтожными.

6Они не спрашивали: «Где Вечный,

Который вывел нас из Египта,

провёл нас сквозь безлюдный край,

по земле пустынь и расселин,

по земле засухи и кромешной тьмы,

где никто не странствует

и никто не живёт?»

7Я привёл вас в плодородную землю,

чтобы вы ели её плоды и пользовались её благами.

Но вы пришли и осквернили Мою землю

и в мерзость превратили Мой удел.

8Не спрашивали священнослужители:

«Где Вечный?»

Учители Закона Меня не знали;

вожди2:8 Букв.: «пастухи». восстали против Меня.

Пророки возвещали от имени Баала2:8 Баал – ханонский бог плодородия и бог-громовержец.

и поклонялись ничтожным идолам.

9Поэтому Я веду тяжбу с вами, –

возвещает Вечный, –

и с внуками вашими.

10Переправьтесь на побережье Кипра2:10 Букв.: «Киттима». Кипр – здесь символизирует все народы к западу от Исроила. и взгляните,

пойдите в Кедар2:10 Кедар – земля кочевий бедуинских племён в пустыне Аравии, здесь символизирует все народы к востоку от Исроила. и разведайте тщательно;

посмотрите, бывало ли что-нибудь подобное,

11менял ли какой народ своих богов?

(Хоть они и не боги вовсе.)

А Мой народ променял Меня, их Славу2:11 Или: «променял Мою славу».,

на ничтожных идолов.

12Поразитесь этому, небеса,

содрогнитесь от ужаса, –

возвещает Вечный. –

13Два греха совершил Мой народ:

оставил Меня – источник живой воды,

и вытесал себе водоёмы,

разбитые водоёмы, которые не могут хранить воду.

14Разве Исроил слуга?

Разве он раб по рождению?

Почему же он стал наживой?

15Львы взревели,

зарычали на него,

сделали его землю пустыней;

его города сожжены и покинуты жителями.

16Египтяне из Мемфиса2:16 Букв.: «Нофа». и Тахпанхеса

обгрызли твоё темя2:16 Или: «проломили тебе голову»..

17Разве не ты сама навлекла это на себя,

оставив Вечного, своего Бога,

когда Он вёл тебя по дороге?

18А теперь что толку ходить в Египет,

чтобы пить воду из Нила?2:18 Букв.: «из Шихора». Шихор – восточный рукав Нила.

Какой прок ходить в Ассирию,

чтобы пить воду из Евфрата?2:18 За свою историю Исроил часто обращался за помощью не к Всевышнему, а к Египту и Ассирии (см. ст. 36-37; Ис. 30:2-3; Ос. 5:13; 7:11).

19Твоё беззаконие накажет тебя,

и твоё отступничество осудит.

Подумай же и посмотри,

как плохо тебе и горько от того,

что оставила ты Вечного, своего Бога,

и нет в тебе страха предо Мной, –

возвещает Владыка Вечный, Повелитель Сил. –

20Давным-давно ты разбила своё ярмо

и разорвала свои оковы

и сказала: «Не буду служить!»2:20 Под ярмом и оковами подразумеваются обязательства священного соглашения со Всевышним, а Исроил предстаёт здесь в образе строптивого животного.

На любом высоком холме

и под каждым тенистым деревом

ты распутствовала2:20 Здесь образно говорится об идолопоклонстве в капищах на возвышенностях и в рощах, которое в глазах Всевышнего то же, что и блуд..

21Я посадил тебя благородной лозой

от самого чистого семени.

Как же превратилась ты у Меня

в пустоцвет и дикую лозу?

22Помоешься ли ты щёлоком,

изведёшь ли много мыла,

твои грехи всё равно передо Мной, –

возвещает Владыка Вечный. –

23Как ты можешь говорить: «Я не осквернилась,

я не поклонялась статуям Баала»?

Посмотри, как вела ты себя в долине,

подумай о том, что сделала.

Ты – норовистая верблюдица,

мечущаяся из стороны в сторону,

24дикая ослица, выросшая в пустыне,

задыхающаяся от страсти, –

кто умерит её пыл?

Все, кто ищет её, без труда

найдут её в пору случки.

25Побереги свои ноги, чтобы не остаться разутой,

и своё горло – чтобы не пересохло.

Но ты сказала: «Бесполезно!

Я люблю чужих богов

и буду бегать за ними».

26Как вор опозорен, когда он пойман,

так будет опозорен и Исроил –

его народ, его цари, его вельможи,

его священнослужители и пророки.

27Дереву они говорят: «Ты отец мой» –

и камню: «Ты меня родил».

Они повернулись ко Мне спиной,

отвратили лица свои,

а когда случается беда, они говорят:

«Приди и спаси нас!»

28А где же те боги, которых вы сделали себе?

Пусть придут, если в силах спасти вас,

когда случится беда!

Ведь богов у тебя, Иудея,

столько же, сколько и городов.

29Почему вы хотите тягаться со Мной?

Все вы восстали против Меня, –

возвещает Вечный. –

30Напрасно наказывал Я вас –

урока вы не усвоили.

Ваш меч пожрал ваших пророков,

точно лев-убийца.

31О нынешнее поколение, поразмысли над словом Вечного:

– Разве Я был пустыней Исроилу

или краем кромешной тьмы?

Почему Мой народ говорит:

«Мы свободны бродить;

мы больше к Тебе не придём»?

32Позабудет ли девушка украшения,

и невеста – свой свадебный наряд?

А Мой народ уже давно забыл Меня.

33Как же умело ты домогаешься любви!

Даже блудницам есть чему у тебя поучиться.

34Найдена на твоих одеждах

кровь невинных бедняков,

которых ты убила,

хотя и не застала, как воров, при взломе2:34 Ср. Исх. 22:2-3..

Но, несмотря на всё это,

35ты говоришь: «Я безвинна;

Он на меня не гневается».

Я осуждаю тебя за то,

что ты говоришь: «Я не согрешила».

36Как легко тебе бродить,

меняя свой путь!

Ты будешь опозорена Египтом,

как была опозорена Ассирией.

37И уйдёшь ты оттуда,

обхватив голову руками:

Вечный отверг тех, кому ты поверила,

и они тебе не помогут.