Jeremiah 2 – YCB & AKCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 2:1-37

Israẹli kọ Ọlọ́run sílẹ̀

1Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé: 2“Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé:

“Báyìí ni Olúwa wí,

“ ‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ,

ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ

àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù,

nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.

3Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa,

àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀,

gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi,

ibi yóò sì wá sí orí wọn,’ ”

bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.

4Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu

àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.

5Báyìí ni Olúwa wí:

“Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi?

Tí wọ́n fi jìnnà sí mi?

Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán,

àwọn fúnrawọn sì di asán.

6Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà,

tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá,

tí ó mú wa la aginjù já,

tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò,

ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri,

ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’

7Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá

láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀,

ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́,

ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.

8Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé,

‘Níbo ni Olúwa wà?’

Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí,

àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi.

Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali,

wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.

9“Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,”

ni Olúwa wí.

“Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ

10Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó,

ránṣẹ́ lọ sí Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi

kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?

11Orílẹ̀-èdè kan ha á pa Ọlọ́run rẹ̀ dà?

(Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ Ọlọ́run)

àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀

ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.

12Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì

kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,”

ni Olúwa wí.

13“Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì

Wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi

orísun omi ìyè, wọ́n sì ti

ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè

gba omi dúró.

14Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀

ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a

dé tí ó fi di ìkógun?

15Àwọn kìnnìún ké ramúramù

wọ́n sì ń bú mọ́ wọn

wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò

Ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì

ti di ìkọ̀sílẹ̀.

16Bákan náà, àwọn ọkùnrin

Memfisi àti Tafanesi

wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.

17Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí

ara yín nípa kíkọ Ọlọ́run sílẹ̀

nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?

18Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti

láti lọ mu omi ní Ṣihori?

Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria

láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?

19Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín

ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí

mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti

ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ

nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀,

ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,”

ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

20“Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà

rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ

ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’

Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni

àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀

ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.

21Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí

àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá,

Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi

di àjàrà búburú àti aláìmọ́?

22Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà

tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ

síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,”

ni Olúwa Olódùmarè wí.

23“Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́;

Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’?

Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì;

wo ohun tí o ṣe.

Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ

tí ń sá síhìn-ín sọ́hùn-ún.

24Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù

tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ,

ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀?

Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara,

nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.

25Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà,

àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ.

Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni!

Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì,

àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’

26“Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u,

bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli—

àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn,

àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.

27Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’

àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’

wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi,

wọn kò kọ ojú sí mi

síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro,

wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’

28Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí

ẹ ṣe fúnrayín ha a wà?

Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì

gbà yín nígbà tí ẹ bá

wà nínú ìṣòro! Nítorí pé

ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́

bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.

29“Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí?

Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,”

ni Olúwa wí.

30“Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín,

wọn kò sì gba ìbáwí.

Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run,

gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.

31“Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa:

“Mo ha ti di aginjù sí Israẹli

tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri?

Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé,

‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri;

àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’

32Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀,

tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀?

Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.

33Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́!

Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ

34Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀

àwọn tálákà aláìṣẹ̀

bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́

níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé

35Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí

ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀

kò sì bínú sí mi.’

Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ

nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’

36Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri

láti yí ọ̀nà rẹ padà?

Ejibiti yóò dójútì ọ́

gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria

37Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀

pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ,

nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn

tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀,

kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan

fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.

Akuapem Twi Contemporary Bible

Yeremia 2:1-37

Israel Pa Onyankopɔn Akyi

1Awurade asɛm baa me so: 2“Kɔpae mu ka ma Yerusalem nte:

“ ‘Mekae sɛnea wode wo ho maa me wo mmabun bere mu,

sɛnea wodɔɔ me wɔ wʼayeforo bere mu

na wudii mʼakyi wɔ sare so,

asase a wonnuaa hwee wɔ so no.

3Na Israel yɛ kronkron ma Awurade,

ne twabere mu aduankan;

wɔn a wodii nʼani no wobuu wɔn fɔ,

na amanehunu baa wɔn so,’ ”

sɛnea Awurade, se ni.

4Muntie Awurade asɛm, mo Yakob asefo,

mo Israel mmusuakuw nyinaa.

5Eyi ne nea Awurade se:

“Mfomso bɛn na mo agyanom huu wɔ me ho a

ɛma wɔtwee wɔn ho kɔɔ akyirikyiri sɛɛ?

Wodii ahoni a wɔn so nni mfaso akyi,

maa wɔn ankasa bɛyɛɛ ahuhufo.

6Wɔammisa se, ‘Ɛhe na Awurade wɔ?

Nea oyii yɛn fii Misraim

na ɔde yɛn faa sare wosee so,

nweatam ne abonabon asase

a awo na ayɛ owubon no.

Asase a obiara mfa so na obiara nte so no.’

7Mede mo beduaa asasebere so

sɛ munni so nnuaba ne ɛso nnepa.

Nanso mubeguu mʼasase ho fi,

na moyɛɛ mʼagyapade akyiwade.

8Asɔfo no ammisa se,

‘Ɛhe na Awurade wɔ?’

Wɔn a wɔde mmara yɛ adwuma no anhwehwɛ me;

ntuanofo sɔre tiaa me.

Adiyifo no de Baal hyɛɛ nkɔm,

na wodii ahoni huhuw akyi.

9“Ɛno nti, merebɔ mo kwaadu bio,”

nea Awurade se ni.

“Na mɛbɔ mo mma mma kwaadu.

10Muntwa nkɔ Kitim mpoano nkɔhwɛ,

monsoma nkɔ Kedar nkɔhwehwɛ mu yiye;

monhwɛ sɛ biribi a ɛte sɛɛ asi wɔ hɔ:

11Ɔman bi asesa wɔn anyame pɛn ana?

Nso wɔnnyɛ anyame mpo.

Nanso me nkurɔfo de wɔn anuonyam

asesa ahoni huhuw.

12Mo ɔsorosoro, momma mo ho nnwiriw mo wɔ eyi ho,

na mo ho nwosow wɔ akomatu mu,”

nea Awurade se ni.

13“Me nkurɔfo ayɛ bɔne ahorow abien:

Wɔapa me,

me a meyɛ nkwa asubura no,

na wɔatutu wɔn ankasa mmura amoa,

mmura a apaapae a entumi nkora nsu.

14Israel yɛ akoa anaa ɔsomfo fi awo mu ana?

Adɛn nti na wayɛ asade yi?

15Gyata abobɔ mu;

wɔaworo so akyerɛ no.

Wɔama nʼasase ada mpan;

wɔahyehyew ne nkurow ayɛ no amamfo.

16Afei Memfis ne Tapanhes mmarima

ayi wo ti so nwi.

17Ɛnyɛ wo na woama eyi aba wo so

sɛ wopaa Awurade wo Nyankopɔn akyi,

wɔ bere a ɔrekyerɛ wo kwan no?

18Afei adɛn nti na wokɔ Misraim

kɔnom Sihor mu nsu?

Na adɛn nti na wokɔ Asiria

kɔnom Asubɔnten no mu nsu?

19Wo amumɔyɛ bɛtwe wʼaso;

wo nsanakyi bɛka wʼanim.

Enti dwene ho na hu sɛ,

sɛ wopa Awurade wo Nyankopɔn akyi

na woannya ne ho suro a,

ɛyɛ bɔne ne ɔyaw ma wo.”

Awurade, Asafo Awurade na ose.

20“Tete mmere no, wububuu wo konnua mu,

na wotetew wo nkɔnsɔnkɔnsɔn mu;

na wokae se, ‘Merensom wo!’

Ampa, wɔ koko biara so

ne dua biara a adennan ase

na wotena bɔɔ aguaman.

21Miduaa wo sɛ bobe ankasa

a efi bobe a ase ye pa ara mu.

Na ɛyɛɛ dɛn na wodan wʼakyi kyerɛɛ me

bɛyɛɛ bobe a anyin asɛe wɔ wura mu yi?

22Sɛ wode soda

ne samina bebree guare mpo a,

wʼafɔdi nkekae da so wɔ mʼanim ara,”

sɛnea Otumfo Awurade se ni.

23“Ɛbɛyɛ dɛn na woaka se, ‘Me ho nguu fi ɛ;

minnii Baalnom akyi ɛ’?

Hwɛ sɛnea woyɛɛ wo ho wɔ obon no mu;

dwene nea woayɛ no ho.

Woyɛ yomabere hoɔharefo

a wutu mmirika kɔ ha ba ha,

24wura mu afurum a nweatam so tena akokwaw no,

ohuahua bere a ɔpɛ sɛ onini hyia no.

Sɛ nʼakɔnnɔ no ano yɛ den a hena na obesianka no?

Anini biara a wɔtaa no no nhaw wɔn ho bebree;

edu bere a ɛsɛ sɛ wohyia no a wobenya no.

25Ntu mmirika nkosi sɛ wʼanan ase bɛyɛ kwaterekwa,

na wo mene mu bɛyow.

Nanso wokae se, ‘So nni mfaso!

Mepɛ ananafo anyame,

na ɛsɛ sɛ midi wɔn akyi.’

26“Sɛnea wɔkyere ɔkorɔmfo a wogu nʼanim ase no,

saa na wɔagu Israelfi anim ase,

wɔn ankasa, wɔn ahemfo ne wɔn adwumayɛfo,

wɔn asɔfo ne wɔn adiyifo.

27Wɔka kyerɛ dua se, ‘Woyɛ mʼagya,’

ne ɔbo se, ‘Wo na wowoo me.’

Wɔadan wɔn akyi akyerɛ me

na ɛnyɛ wɔn anim;

nanso sɛ amanehunu bi ba wɔn so a, wɔka se,

‘Bra begye yɛn!’

28Anyame a moyɛ maa mo ho no wɔ he?

Momma wɔmmra sɛ wobetumi agye mo

bere a mowɔ amanehunu mu!

Efisɛ mowɔ anyame bebree

te sɛ nea mowɔ nkurow bebree no, Yuda.

29“Adɛn nti na mobɔ me sobo?

Mo nyinaa ayɛ dɔm atia me,”

Awurade na ose.

30“Metwee mo nkurɔfo aso kwa;

wɔamfa me nteɛso.

Wʼafoa akunkum wʼadiyifo

te sɛ gyata a nʼani abere.

31“Mo nnɛmmafo, munnwen Awurade asɛm ho:

“Mayɛ sɛ, nweatam ama Israel ana?

Anaasɛ asase a so aduru sum kabii ana?

Adɛn nti na me nkurɔfo ka se, ‘Yɛwɔ ho kwan sɛ yekyinkyin;

yɛremma wo nkyɛn bio.’

32Ɔbabun werɛ fi ne mpempranne,

ayeforo werɛ befi nʼahyehyɛde ana?

Nanso me nkurɔfo werɛ afi me

nna a wontumi nkan.

33Hwɛ nyansa a mowɔ de pɛ mo adɔfo!

Mmea a wɔnsɛ hwee koraa tumi sua mo akwan.

34Mo adurade mu wɔ

ahiafo a wodi bem mogya,

nanso moankyere wɔn sɛ wɔrebubu akɔ mu.

Eyinom nyinaa akyi

35woka se, ‘Midi bem;

ne bo mfuw me.’

Nanso mebu wo atɛn

efisɛ woka se, ‘Menyɛɛ bɔne biara ɛ.’

36Adɛn nti na wukyinkyin sɛɛ,

sesa wʼakwan?

Misraim bedi wo huammɔ

sɛnea Asiria yɛe no.

37Afei wubefi saa beae hɔ

a wo nsa gu wo ti so.

Efisɛ Awurade apo wɔn a wode wo ho too wɔn so no;

wɔremmoa wo.