Isaiah 66 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 66:1-24

Ìdájọ́ àti ìrètí

166.1-2: Mt 5.34; Ap 7.49-50.Báyìí ni Olúwa wí:

“Ọ̀run ni ìtẹ́ mi,

ayé sì ni àpótí ìtìsẹ̀ mi,

Níbo ni ilé tí ẹ ó kọ́ fún mi wà?

Níbo ní ibi ìsinmi mi yóò gbé wà?

2Kì í ha á ṣe ọwọ́ mi ló tí ṣe nǹkan wọ̀nyí,

bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì wà?”

ni Olúwa wí.

“Eléyìí ni ẹni tí mo kà sí:

ẹni náà tí ó rẹra rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì kẹ́dùn ní ọkàn rẹ̀,

tí ó sì wárìrì sí ọ̀rọ̀ mi.

3Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fi akọ màlúù rú ẹbọ

ó dàbí ẹni tí ó pa ènìyàn kan

àti ẹni tí ó bá fi ọ̀dọ́-àgùntàn kan tọrẹ,

dàbí ẹni tí ó bẹ́ ajá kan lọ́rùn;

ẹnikẹ́ni tí ó bá fi irúgbìn ìyẹ̀fun tọrẹ

dàbí ẹni tí ó mú ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ wá,

ẹni tí ó bá sì sun tùràrí ìrántí,

dàbí ẹni tí ó súre fún òrìṣà.

Wọ́n ti yan ipa ọ̀nà tì wọ́n,

ọkàn wọn pẹ̀lú sì láyọ̀ nínú ohun ìríra wọn;

4Fún ìdí èyí ni èmi pẹ̀lú yóò ṣe fi ọwọ́ líle mú wọn

n ó sì mú ohun tí wọ́n bẹ̀rù rẹ̀ wá sórí wọn.

Nítorí nígbà tí mo pè, kò sí ẹni tí ó dáhùn,

nígbà tí mo sọ̀rọ̀, ẹnikẹ́ni kò tẹ́tí sílẹ̀.

Wọ́n ṣe ohun búburú ní ojú mi

wọ́n sì yan ohun tí mo kórìíra rẹ̀.”

5Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,

Ẹ̀yin tí ẹ ń wárìrì nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀:

“Àwọn arákùnrin yín tí wọ́n kórìíra yín,

tí wọ́n ta yín nù nítorí orúkọ mi, wí pé,

‘Jẹ́ kí a yin Olúwa lógo,

kí a le rí ayọ̀ yín!’

Ṣùgbọ́n àwọn ni ojú yóò tì.

666.6: If 16.1,17.Gbọ́ rògbòdìyàn láti ìlú wá,

gbọ́ ariwo náà láti tẹmpili wá!

Ariwo tí Olúwa ní í ṣe

tí ó ń san án fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ ohun

tí ó tọ́ sí wọn.

766.7: If 12.5.“Kí ó tó lọ sí ìrọbí,

ó ti bímọ;

kí ó tó di pé ìrora dé bá a,

ó ti bí ọmọkùnrin.

8Ta ni ó ti gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí?

Ta ni ó ti rí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí?

Ǹjẹ́ a le bí orílẹ̀-èdè kan níjọ́ kan

tàbí kí orílẹ̀-èdè lalẹ̀hù ní ìṣẹ́jú kan?

Síbẹ̀síbẹ̀ Sioni bẹ̀rẹ̀ rírọbí

bẹ́ẹ̀ ni ó sì bí àwọn ọmọ rẹ̀.

9Ǹjẹ́ èmi a ha máa mú wá sí ìrọbí

kí èmi má sì mú ni bí?”

ni Olúwa wí.

“Ǹjẹ́ èmi a ha máa ṣé ilé ọmọ

nígbà tí mo ń mú ìbí wá?”

Ni Ọlọ́run yín wí.

10“Ẹ bá Jerusalẹmu yọ̀ kí inú yín kí ó sì dùn sí i,

gbogbo ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn rẹ̀;

ẹ yọ̀ gidigidi pẹ̀lú rẹ̀,

gbogbo ẹ̀yin tí ó ti kẹ́dùn fún un.

11Nítorí pé ẹ̀yin yóò mu ẹ o sì ní ìtẹ́lọ́rùn

nínú ọmú rẹ̀ tí ó tu ni lára;

Ẹ̀yin yóò mu àmuyó

ẹ ó sì gbádùn nínú àkúnwọ́sílẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ rẹ̀.”

12Nítorí báyìí ni Olúwa wí:

“Èmi yóò fún un ní àlàáfíà gẹ́gẹ́ bí odò

àti ọrọ̀ orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí ìṣàn omi;

ẹ̀yin yóò mu ọmú, a ó sì gbé yín ní apá rẹ̀

a ó bá yín ṣeré ní orúkún rẹ̀.

13Gẹ́gẹ́ bí ìyá ti í tu ọmọ rẹ̀ nínú,

bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò tù yín nínú

a ó sì tù yín nínú lórí Jerusalẹmu.”

14Nígbà tí ẹ bá rí èyí, inú yín yóò dùn

ẹ̀yin yóò sì gbilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i koríko;

ọwọ́ Olúwa ni a ó sọ di mí mọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀,

ṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ ni a ó fihàn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.

15Kíyèsi i, Olúwa ń bọ̀ pẹ̀lú iná

àti kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ tí ó dàbí ìjì líle;

òun yóò mú ìbínú rẹ sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ìrunú,

àti ìbáwí rẹ̀ pẹ̀lú ahọ́n iná.

16Nítorí pẹ̀lú iná àti idà

ni Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ lórí i gbogbo ènìyàn,

àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí Olúwa yóò pa.

17“Gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sí mímọ́ tí wọ́n sì sọ ara wọn di mímọ́ láti lọ sínú ọgbà, tí wọ́n tẹ̀lé ẹni tí ó wà láàrín àwọn tí ó jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀ àti èkúté àti àwọn ohun ìríra mìíràn ni wọn yóò bá òpin wọn pàdé papọ̀,” ni Olúwa wí.

18“Àti Èmi, nítorí ìgbésẹ̀ wọn àti èrò wọn, èmi ti múra tán láti wá kó àwọn orílẹ̀-èdè àti ahọ́n jọ, wọn yóò sì wá wo ògo mi.

19“Èmi yóò sì gbé ààmì kan kalẹ̀ láàrín wọn, èmi yóò sì rán díẹ̀ nínú àwọn tí ó sálà lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè Tarṣiṣi, sí àwọn ará Libia àti Ludi, sí Tubali àti ará Giriki, àti sí àwọn erékùṣù tí ó jìnnà réré tí kò tí ìgbọ́ nípa òkìkí mi tàbí kí ó rí ògo mi. Wọn yóò kéde ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè. 20Wọn yóò sì mú àwọn arákùnrin yín wá, láti gbogbo orílẹ̀-èdè, sí òkè mímọ́ mi ní Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọrẹ sí Olúwa lórí ẹṣin, lórí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti ọkọ-ẹṣin, àti lórí ìbáaka àti ìbákasẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn yóò kó wọn wá, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli ti mú ọrẹ oníhóró wọn wá, sínú Tẹmpili Olúwa nínú ohun èlò mímọ́. 21Àti pé èmi yóò sì yan àwọn kan nínú wọn pẹ̀lú láti jẹ́ àlùfáà àti Lefi,” ni Olúwa wí.

2266.22: Isa 65.17; 2Pt 3.13; If 21.1.“Gẹ́gẹ́ bí àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun tí mo dá yóò ṣe wà níwájú mi títí láé,” ni Olúwa wí, “Bẹ́ẹ̀ ni orúkọ yín àti ìrandíran yín yóò pegedé. 23Láti oṣù tuntun kan dé òmíràn àti láti ọjọ́ ìsinmi kan dé òmíràn, ni gbogbo ọmọ ènìyàn yóò wá, wọn yóò sì tẹríba níwájú mi,” ni Olúwa wí. 2466.24: Mk 9.48.“Wọn yóò sì jáde lọ wọn yóò sì lọ wo òkú àwọn tí wọ́n dìtẹ̀ sí mi; kòkòrò wọn kì yóò kú, bẹ́ẹ̀ ni iná wọn ni a kì yóò pa, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jẹ́ ohun ìríra fún gbogbo ọmọ ènìyàn.”

Nova Versão Internacional

Isaías 66:1-24

Julgamento e Esperança

1Assim diz o Senhor:

“O céu é o meu trono;

e a terra, o estrado dos meus pés.

Que espécie de casa vocês me edificarão?

É este o meu lugar de descanso?

2Não foram as minhas mãos que fizeram todas essas coisas,

e por isso vieram a existir?”, pergunta o Senhor.

“A este eu estimo:

ao humilde e contrito de espírito,

que treme diante da minha palavra.

3Mas aquele que sacrifica um boi

é como quem mata um homem;

aquele que sacrifica um cordeiro,

é como quem quebra o pescoço de um cachorro;

aquele que faz oferta de cereal

é como quem apresenta sangue de porco,

e aquele que queima incenso memorial,

é como quem adora um ídolo.

Eles escolheram os seus caminhos,

e suas almas têm prazer em suas práticas detestáveis.

4Por isso também escolherei um duro tratamento para eles

e trarei sobre eles o que eles temem.

Pois eu chamei, e ninguém respondeu;

falei, e ninguém deu ouvidos.

Fizeram o mal diante de mim

e escolheram o que me desagrada”.

5Ouçam a palavra do Senhor,

vocês que tremem diante da sua palavra:

“Seus irmãos que os odeiam e os excluem

por causa do meu nome, disseram:

‘Que o Senhor seja glorioso,

para que vejamos a alegria de vocês!’

Mas eles é que passarão vergonha.

6Ouçam o estrondo que vem da cidade,

o som que vem do templo!

É o Senhor

que está dando a devida retribuição aos seus inimigos.

7“Antes de entrar em trabalho de parto,

ela dá à luz;

antes de lhe sobrevirem as dores,

ela ganha um menino.

8Quem já ouviu uma coisa dessas?

Quem já viu tais coisas?

Pode uma nação nascer num só dia,

ou, pode-se dar à luz um povo num instante?

Pois Sião ainda estava em trabalho de parto,

e deu à luz seus filhos.

9Acaso faço chegar a hora do parto

e não faço nascer?”,

diz o Senhor.

“Acaso fecho o ventre,

sendo que eu faço dar à luz?”,

pergunta o seu Deus.

10“Regozijem-se com Jerusalém e alegrem-se por ela,

todos vocês que a amam;

regozijem-se muito com ela,

todos vocês que por ela pranteiam.

11Pois vocês irão mamar e saciar-se

em seus seios reconfortantes,

e beberão à vontade

e se deleitarão em sua fartura.”

12Pois assim diz o Senhor:

“Estenderei para ela a paz como um rio

e a riqueza das nações, como uma corrente avassaladora;

vocês serão amamentados nos braços dela

e acalentados em seus joelhos.

13Assim como uma mãe consola seu filho,

também eu os consolarei;

em Jerusalém vocês serão consolados”.

14Quando vocês virem isso, o seu coração se regozijará,

e vocês florescerão como a relva;

a mão do Senhor estará com os seus servos,

mas a sua ira será contra os seus adversários.

15Vejam! O Senhor vem num fogo,

e os seus carros são como um turbilhão!

Transformará em fúria a sua ira

e em labaredas de fogo, a sua repreensão.

16Pois com fogo e com a espada

o Senhor executará julgamento sobre todos os homens,

e muitos serão os mortos pela mão do Senhor.

17“Os que se consagram para entrar nos jardins indo atrás do sacerdote66.17 Ou da deusa que está no meio, comem66.17 Ou jardins atrás de um de seus templos, e aqueles que comem carne de porco, ratos e outras coisas repugnantes, todos eles perecerão”, declara o Senhor.

18“E, por causa dos seus atos e das suas conspirações, virei ajuntar todas as nações e línguas, e elas virão e verão a minha glória.

19“Estabelecerei um sinal entre elas, e enviarei alguns dos sobreviventes às nações: a Társis, aos líbios66.19 Conforme alguns manuscritos da Septuaginta. O Texto Massorético diz a Pul. e aos lídios, famosos flecheiros, a Tubal, à Grécia, e às ilhas distantes, que não ouviram falar de mim e não viram a minha glória. Eles proclamarão a minha glória entre as nações. 20Também dentre todas as nações trarão os irmãos de vocês ao meu santo monte, em Jerusalém, como oferta ao Senhor. Virão a cavalo, em carros e carroças, e montados em mulas e camelos”, diz o Senhor.

“Farão como fazem os israelitas quando apresentam as suas ofertas de cereal, trazendo-as em vasos cerimonialmente puros; 21também escolherei alguns deles para serem sacerdotes e levitas”, diz o Senhor.

22“Assim como os novos céus e a nova terra que vou criar serão duradouros diante de mim”, declara o Senhor, “assim serão duradouros os descendentes de vocês e o seu nome. 23De uma lua nova a outra e de um sábado a outro, toda a humanidade virá e se inclinará diante de mim”, diz o Senhor. 24“Sairão e verão os cadáveres dos que se rebelaram contra mim; o verme destes não morrerá, e o seu fogo não se apagará, e causarão repugnância a toda a humanidade.”