Isaiah 61 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 61:1-11

Ọdún ojúrere Olúwa

161.1-2: Mt 11.5; Lk 4.18-19; 7.22.Ẹ̀mí Olúwa Olódùmarè wà lára mi

nítorí Olúwa ti fi ààmì òróró yàn mí

láti wàásù ìhìnrere fún àwọn tálákà.

Ó ti rán mi láti ṣe àwòtán oníròbìnújẹ́

láti kéde ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn

àti ìtúsílẹ̀ kúrò nínú òkùnkùn fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n,

2Láti kéde ọdún ojúrere Olúwa

àti ọjọ́ ẹ̀san ti Ọlọ́run wa,

láti tu àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú,

3àti láti pèsè fún àwọn tí inú wọn bàjẹ́ ní Sioni

láti dé wọn ládé ẹwà dípò eérú,

òróró ayọ̀ dípò ọ̀fọ̀,

àti aṣọ ìyìn dípò ìpòrúru ọkàn.

A ó sì pè wọ́n ní igi óákù òdodo,

irúgbìn Olúwa

láti fi ọláńlá rẹ̀ hàn.

4Wọn yóò tún àwọn ahoro àtijọ́ kọ́

wọn yóò sì mú àwọn ibi ìparun àtijọ́-tijọ́ náà bọ̀ sípò;

wọn yóò jí àwọn ahoro ìlú náà padà

tí a ti parun láti ìrandíran sẹ́yìn.

5Àwọn àjèjì ni yóò máa da ọ̀wọ́ ẹran rẹ;

àwọn àlejò yóò sì ṣiṣẹ́ nínú oko àti ọgbà àjàrà rẹ.

6A ó sì máa pè yín ní àlùfáà Olúwa,

a ó pè yín ní ìránṣẹ́ Ọlọ́run wa.

Ẹ ó máa jẹ nínú ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè

àti nínú ọrọ̀ wọn ni ẹ̀yin yóò máa ṣògo.

7Dípò àbùkù wọn

àwọn ènìyàn mi yóò gba ìlọ́po méjì,

àti dípò àbùkù wọn

wọn yóò yọ̀ nínú ìní wọn;

bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jogún ìlọ́po méjì ní ilẹ̀ wọn,

ayọ̀ ayérayé yóò sì jẹ́ tiwọn.

8“Nítorí Èmi, Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òdodo;

mo kórìíra olè jíjà àti ẹ̀ṣẹ̀

Ní òtítọ́ mi èmi yóò sẹ̀san fún wọn

èmi yóò sì dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú wọn.

9A ó mọ ìrandíran wọn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè

àti àwọn ìran wọn láàrín àwọn ènìyàn

Gbogbo àwọn tí ó bá rí wọn yóò mọ̀ pé

wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tí Olúwa ti bùkún.”

10Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa;

ọkàn mi yọ̀ nínú Ọlọ́run mi.

Nítorí ó ti wọ̀ mí ní aṣọ ìgbàlà

ó sì ṣe mí lọ́ṣọ̀ọ́ nínú aṣọ òdodo;

gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ti ṣe orí rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ bí àlùfáà,

àti bí ìyàwó ṣe ń ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́.

11Gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ti í mú irúgbìn jáde

àti bí ọgbà ṣe ń mú irúgbìn dàgbà,

Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè yóò ṣe mú òdodo àti ìyìn

kí ó ru sókè níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè.