Isaiah 1 – YCB & NVI

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 1:1-31

1Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.

Ọlọ̀tẹ̀ orílẹ̀-èdè kan

2Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé!

Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀:

“Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà,

Ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.

3Màlúù mọ olówó rẹ̀,

kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀,

ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀,

òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”

4Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀,

àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù,

Ìran àwọn aṣebi,

àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́!

Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀

wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli,

wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.

5Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́?

Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe?

Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́,

gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.

6Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín

kò sí àlàáfíà rárá,

àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa

àti ojú egbò,

tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.

7Orílẹ̀-èdè yín dahoro,

a dáná sun àwọn ìlú yín,

oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run

lójú ara yín náà,

ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí

àwọn àjèjì borí rẹ̀.

8Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀

gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà,

gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí,

àti bí ìlú tí a dó tì.

9Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun

bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà,

a ò bá ti rí bí Sodomu,

a ò bá sì ti dàbí Gomorra.

10Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,

ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu,

tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa,

ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!

11“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín

kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí.

“Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun

ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa,

Èmi kò ní inú dídùn

nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn

àti ti òbúkọ.

12Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi,

ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín,

Gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?

13Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́!

Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi,

oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ,

Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.

14Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn,

ni ọkàn mi kórìíra.

Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn,

Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.

15Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà,

Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín,

kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà,

Èmi kò ni tẹ́tí sí i.

“Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.

16“Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́.

Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi!

Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,

17kọ́ láti ṣe rere!

Wá ìdájọ́ òtítọ́,

tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú.

Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,

gbà ẹjọ́ opó rò.

18“Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,”

ni Olúwa wí.

“Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn,

wọn ó sì funfun bí i yìnyín,

bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀,

wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.

19Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀,

ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.

20Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀,

idà ni a ó fi pa yín run.”

Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.

21Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè!

Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí,

òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí,

ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!

22Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́,

ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.

23Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín,

akẹgbẹ́ àwọn olè,

gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀

wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri.

Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,

ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.

24Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun,

alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé:

“Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi

n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.

25Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ,

èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù,

n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.

26Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́,

àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀.

Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”

27A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà,

àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.

28Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun.

Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.

29“Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́

èyí tí ẹ ní inú dídùn sí,

a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí

tí ẹ ti yàn fúnrayín.

30Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ,

bí ọgbà tí kò ní omi.

31Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná,

iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná,

àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀,

láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”

Nueva Versión Internacional

Isaías 1:1-31

1Visión que recibió Isaías, hijo de Amoz, acerca de Judá y Jerusalén, durante los reinados de Uzías, Jotán, Acaz y Ezequías, reyes de Judá.

Judá, nación rebelde

2¡Oigan, cielos! ¡Escucha, tierra!

Porque el Señor ha hablado:

«Yo crie hijos y los hice crecer,

pero ellos se rebelaron contra mí.

3El buey conoce a su dueño

y el asno el pesebre de su amo;

¡pero Israel no conoce,

mi pueblo no comprende!».

4¡Ay, nación pecadora,

pueblo cargado de culpa,

generación de malhechores,

hijos corruptos!

¡Han abandonado al Señor!

¡Han despreciado al Santo de Israel!

¡Le han dado la espalda!

5¿Por qué recibir más golpes?

¿Por qué insistir en la rebelión?

Toda su cabeza está herida,

todo su corazón está enfermo.

6Desde la planta del pie hasta la coronilla

no les queda nada sano:

todo en ellos es heridas, moretones

y llagas abiertas,

que no les han sido curadas, ni vendadas,

ni aliviadas con aceite.

7Su país está desolado,

sus ciudades son presa del fuego;

ante sus propios ojos

los extraños devoran sus campos;

su país está desolado, como si hubiera sido destruido por extranjeros.

8La hija Sión ha quedado

como cobertizo en un viñedo,

como choza en un huerto de pepinos,

como ciudad sitiada.

9Si el Señor de los Ejércitos

no nos hubiera dejado un remanente de sobrevivientes,

seríamos ya como Sodoma,

nos pareceríamos a Gomorra.

10¡Oigan la palabra del Señor,

gobernantes de Sodoma!

¡Escuchen la instrucción de nuestro Dios,

pueblo de Gomorra!

11«¿De qué me sirven sus muchos sacrificios?»,

dice el Señor.

«Harto estoy de holocaustos de carneros

y de la grasa de animales engordados;

la sangre de novillos, corderos y machos cabríos

no me complace.

12¿Por qué vienen a presentarse ante mí?

¿Quién les mandó traer animales

para que pisotearan mis atrios?

13No me sigan trayendo vanas ofrendas;

el incienso es para mí una abominación.

Luna nueva, día de reposo, asambleas convocadas;

¡no soporto sus asambleas que me ofenden!

14Yo aborrezco sus lunas nuevas y festividades;

se me han vuelto una carga

que estoy cansado de soportar.

15Cuando levantan sus manos,

yo aparto de ustedes mis ojos;

aunque multipliquen sus oraciones,

no las escucharé.

»¡Tienen las manos llenas de sangre!

16»¡Lávense, límpiense!

¡Aparten de mi vista sus obras malvadas!

¡Dejen de hacer el mal!

17¡Aprendan a hacer el bien!

¡Busquen la justicia y restituyan al oprimido!

¡Aboguen por el huérfano

y defiendan a la viuda!».

18«Vengan, pongamos las cosas en claro»,

dice el Señor.

«Aunque sus pecados sean como escarlata,

quedarán blancos como la nieve.

Aunque sean rojos como la púrpura,

quedarán como la lana.

19¿Están ustedes dispuestos a obedecer?

¡Comerán lo bueno de la tierra!

20¿Se niegan y se rebelan?

¡Serán devorados por la espada!».

El Señor mismo lo ha dicho.

21¡Cómo se ha prostituido la ciudad fiel!

Antes estaba llena de justicia.

La rectitud moraba en ella,

pero ahora solo quedan asesinos.

22Tu plata se ha convertido en escoria;

tu buen vino está mezclado con agua.

23Tus gobernantes son rebeldes,

cómplices de ladrones;

todos aman el soborno

y van detrás de las recompensas.

No abogan por el huérfano

ni se ocupan de la causa de la viuda.

24Por eso, afirma el Señor,

el Señor de los Ejércitos, el Poderoso de Israel:

«Me desquitaré de mis adversarios,

me vengaré de mis enemigos.

25Volveré mi mano contra ti,

limpiaré tus escorias con lejía

y quitaré todas tus impurezas.

26Restauraré a tus líderes como al principio

y a tus consejeros como al comienzo.

Entonces serás llamada

“Ciudad de justicia”,

“Ciudad fiel”».

27Con justicia Sión será redimida

y con rectitud, los que se arrepientan.

28Pero los rebeldes y pecadores a una serán quebrantados

y perecerán los que abandonan al Señor.

29«Se avergonzarán de las encinas

que ustedes tanto aman;

los jardines que eligieron

les serán una afrenta,

30como una encina con hojas marchitas,

como un jardín sin agua.

31El hombre fuerte se convertirá en estopa

y su trabajo, en chispa;

arderán los dos juntos

y no habrá quien los apague».