Isaiah 1 – YCB & NIVUK

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 1:1-31

1Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.

Ọlọ̀tẹ̀ orílẹ̀-èdè kan

2Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé!

Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀:

“Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà,

Ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.

3Màlúù mọ olówó rẹ̀,

kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀,

ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀,

òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”

4Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀,

àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù,

Ìran àwọn aṣebi,

àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́!

Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀

wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli,

wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.

5Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́?

Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe?

Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́,

gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.

6Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín

kò sí àlàáfíà rárá,

àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa

àti ojú egbò,

tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.

7Orílẹ̀-èdè yín dahoro,

a dáná sun àwọn ìlú yín,

oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run

lójú ara yín náà,

ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí

àwọn àjèjì borí rẹ̀.

8Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀

gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà,

gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí,

àti bí ìlú tí a dó tì.

9Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun

bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà,

a ò bá ti rí bí Sodomu,

a ò bá sì ti dàbí Gomorra.

10Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,

ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu,

tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa,

ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!

11“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín

kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí.

“Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun

ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa,

Èmi kò ní inú dídùn

nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn

àti ti òbúkọ.

12Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi,

ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín,

Gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?

13Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́!

Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi,

oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ,

Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.

14Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn,

ni ọkàn mi kórìíra.

Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn,

Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.

15Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà,

Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín,

kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà,

Èmi kò ni tẹ́tí sí i.

“Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.

16“Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́.

Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi!

Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,

17kọ́ láti ṣe rere!

Wá ìdájọ́ òtítọ́,

tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú.

Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,

gbà ẹjọ́ opó rò.

18“Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,”

ni Olúwa wí.

“Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn,

wọn ó sì funfun bí i yìnyín,

bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀,

wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.

19Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀,

ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.

20Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀,

idà ni a ó fi pa yín run.”

Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.

21Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè!

Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí,

òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí,

ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!

22Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́,

ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.

23Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín,

akẹgbẹ́ àwọn olè,

gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀

wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri.

Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,

ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.

24Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun,

alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé:

“Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi

n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.

25Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ,

èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù,

n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.

26Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́,

àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀.

Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”

27A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà,

àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.

28Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun.

Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.

29“Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́

èyí tí ẹ ní inú dídùn sí,

a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí

tí ẹ ti yàn fúnrayín.

30Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ,

bí ọgbà tí kò ní omi.

31Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná,

iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná,

àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀,

láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”

New International Version – UK

Isaiah 1:1-31

1The vision concerning Judah and Jerusalem that Isaiah son of Amoz saw during the reigns of Uzziah, Jotham, Ahaz and Hezekiah, kings of Judah.

A rebellious nation

2Hear me, you heavens! Listen, earth!

For the Lord has spoken:

‘I reared children and brought them up,

but they have rebelled against me.

3The ox knows its master,

the donkey its owner’s manger,

but Israel does not know,

my people do not understand.’

4Woe to the sinful nation,

a people whose guilt is great,

a brood of evildoers,

children given to corruption!

They have forsaken the Lord;

they have spurned the Holy One of Israel

and turned their backs on him.

5Why should you be beaten anymore?

Why do you persist in rebellion?

Your whole head is injured,

your whole heart afflicted.

6From the sole of your foot to the top of your head

there is no soundness –

only wounds and bruises

and open sores,

not cleansed or bandaged

or soothed with oil.

7Your country is desolate,

your cities burned with fire;

your fields are being stripped by foreigners

right before you,

laid waste as when overthrown by strangers.

8Daughter Zion is left

like a shelter in a vineyard,

like a hut in a cucumber field,

like a city under siege.

9Unless the Lord Almighty

had left us some survivors,

we would have become like Sodom,

we would have been like Gomorrah.

10Hear the word of the Lord,

you rulers of Sodom;

listen to the instruction of our God,

you people of Gomorrah!

11‘The multitude of your sacrifices –

what are they to me?’

says the Lord.

‘I have more than enough of burnt offerings,

of rams and the fat of fattened animals;

I have no pleasure

in the blood of bulls and lambs and goats.

12When you come to appear before me,

who has asked this of you,

this trampling of my courts?

13Stop bringing meaningless offerings!

Your incense is detestable to me.

New Moons, Sabbaths and convocations –

I cannot bear your worthless assemblies.

14Your New Moon feasts and your appointed festivals

I hate with all my being.

They have become a burden to me;

I am weary of bearing them.

15When you spread out your hands in prayer,

I hide my eyes from you;

even when you offer many prayers,

I am not listening.

Your hands are full of blood!

16Wash and make yourselves clean.

Take your evil deeds out of my sight;

stop doing wrong.

17Learn to do right; seek justice.

Defend the oppressed.1:17 Or justice. / Correct the oppressor

Take up the cause of the fatherless;

plead the case of the widow.

18‘Come now, let us settle the matter,’

says the Lord.

‘Though your sins are like scarlet,

they shall be as white as snow;

though they are red as crimson,

they shall be like wool.

19If you are willing and obedient,

you will eat the good things of the land;

20but if you resist and rebel,

you will be devoured by the sword.’

For the mouth of the Lord has spoken.

21See how the faithful city

has become a prostitute!

She once was full of justice;

righteousness used to dwell in her –

but now murderers!

22Your silver has become dross,

your choice wine is diluted with water.

23Your rulers are rebels,

partners with thieves;

they all love bribes

and chase after gifts.

They do not defend the cause of the fatherless;

the widow’s case does not come before them.

24Therefore the Lord, the Lord Almighty,

the Mighty One of Israel, declares:

‘Ah! I will vent my wrath on my foes

and avenge myself on my enemies.

25I will turn my hand against you;1:25 That is, against Jerusalem

I will thoroughly purge away your dross

and remove all your impurities.

26I will restore your leaders as in days of old,

your rulers as at the beginning.

Afterwards you will be called

the City of Righteousness,

the Faithful City.’

27Zion will be delivered with justice,

her penitent ones with righteousness.

28But rebels and sinners will both be broken,

and those who forsake the Lord will perish.

29‘You will be ashamed because of the sacred oaks

in which you have delighted;

you will be disgraced because of the gardens

that you have chosen.

30You will be like an oak with fading leaves,

like a garden without water.

31The mighty man will become tinder

and his work a spark;

both will burn together,

with no-one to quench the fire.’