Hosea 2 – YCB & NSP

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Hosea 2:1-23

1“Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘àyànfẹ́ mi.’

Ẹ̀sùn tí a fi kan ìyàwó aláìṣòótọ́

2“Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí,

nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi,

Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀.

Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀

àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.

3Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò

Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i.

Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀,

Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀

Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.

4Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀

nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́

5Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè,

ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú.

Ó wí pé, ‘èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn,

tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi,

ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi,

òróró mi àti ohun mímu mi.’

6Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà

Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.

7Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn;

Yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn.

Nígbà náà ni yóò sọ pé,

‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́

nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’

8Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni

àti ẹni tó fún un ní ọkà,

ọtí wáìnì tuntun àti òróró

ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọpọ̀ Èyí tí wọ́n lò fún Baali.

9“Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n,

èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀.

Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà

ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.

10Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn

lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀

kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi

11Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin:

àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀,

ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.

12Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run,

èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀,

Èmi yóò sọ wọ́n di igbó,

àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.

13Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀

nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali;

tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́,

tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ.

Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,”

ni Olúwa wí.

14“Nítorí náà, èmi yóò tàn án

Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀

Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀

15Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un,

Èmi yóò fi Àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un.

Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀

gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.

16“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,

Ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’;

Ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’

ni Olúwa wí.

17Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀;

ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́

18Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú

fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti

àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀.

Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́

Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà

kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.

19Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé.

Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti

òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.

20Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́

ìwọ yóò sì mọ Olúwa.

21“Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà”

ni Olúwa wí.

“Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn

àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;

22Ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà,

wáìnì tuntun àti òróró lóhùn

Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.

23Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà

Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘àánú Gbà.’

Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’

‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’ ”

New Serbian Translation

Књига пророка Осије 2:1-23

1Реците својој браћи: ’Народе мој!’2,1 Ами, позитивни облик имена из 1,9.; и својој сестри: ’Помилована!’2,1 Рухама, позитивни облик имена из 1,8.

Израиљ кажњен и обновљен

2Парничите се са мајком својом!

Судите се, јер ми она више није жена,

а ја муж њен нисам.

Нек са лица свога скине своје блудништво

и своје прељубе са груди својих,

3да је не бих скинуо,

голотињу њену разоткрио као на дан када се родила.

Претворићу је у пустињу,

претворићу је у земљу суву

и убити жеђу.

4И нећу се смиловати на њену децу,

јер су копилад!

5Њихова је мајка блудничила,

осрамотила се она што их је зачела.

Јер, рекла је: ’Идем ја за својим љубавницима,

за онима што ми храну и воду дају;

што ми дају вуну и лан, уље и пиће.’

6Зато ћу, ево, да преградим њен пут трњем;

зидом ћу је обзидати да не нађе свој пут.

7И она ће јурити за својим љубавницима,

али их неће стићи;

тражиће их, али их неће наћи.

Рећи ће:

’Отићи ћу, вратићу се своме првом мужу,

јер ми је било боље тада него сада.’

8Она не зна да сам јој ја

дао жито и вино, уље и сребро;

ја сам јој умножио злато

што га је дала да слије Вала.

9Зато ћу сада да узмем натраг своје жито у време жетве,

и своје вино у доба бербе;

склонићу своју вуну и свој лан,

чиме би покрила нагост њену.

10Разоткрићу сада њену нагост

на очи њеним љубавницима

и из руку мојих је нико избавити неће.

11Ућуткаћу све весеље

њених сабора, њених младина,

њених субота и свих њених празника.

12Опустошићу њену лозу и њене смокве,

за које је рекла:

’То је плата моја коју су ми дали љубавници моји.’

Претворићу све то у шуму,

да их једу пољске звери.

13Судићу јој ја због дана Вала,

када им је палила тамјан;

када се нагиздала својим прстењем и накитом својим,

када је отишла за својим љубавницима,

а мене је заборавила

– говори Господ.

14Зато ћу је, ево, намамити;

у пустињу одвешћу је

и благо јој говорити.

15Вратићу јој ја оданде винограде њене

и долину Ахор2,15 Долина пропасти. као врата наде.

Одазваће се она с оног места,

као кад је била млада

и као када је долазила из Египта.

16Тога ћеш ме дана – говори Господ –

звати: ’Мужу мој’,

и нећеш ме више звати: ’Господару мој.2,16 Изворна реч Вал значи и господар, тј. муж (што наглашава правни положај мушкарца у браку), али је и назив хананског божанства. Ова игра речи истиче одвратност чак и најобичније употребе ове именице.

17Уклонићу имена Вала из њених уста

да им име више никад не спомене.

18Тога ћу дана за њих сачинити савез

са пољским зверима,

са небеским птицама и са гмизавцима.

Уклонићу лук, мач и битку из земље

и даћу им да безбрижно леже.

19Верићу те довека са собом;

верићу те са собом у праведности и правди,

у милости и милосрђу.

20Верићу те са собом у верности

и познаћеш Господа.

21И ја ћу тога дана да послушам

– говори Господ –

да послушам небеса,

а она ће послушати земљу;

22земља ће послушати жито

и ново вино и свеже уље.

А они ће послушати Језраел.

23Посејаћу је за себе по земљи

и смиловаћу се Ло-Рухами2,23 Ло-Рухама значи непомилована.,

а Ло-Амију2,23 Ло-Ами значи није мој народ. ћу рећи: ’Ти си мој народ’,

а он ће рећи мени: ’Мој Бог.’“