Hosea 1 – YCB & OL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Hosea 1:1-11

1Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Hosea ọmọ Beeri wá ní àkókò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah; àwọn ọba Juda àti ní àkókò ọba Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ní Israẹli:

Ìdílé Hosea

2Nígbà tí Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀ láti ẹnu Hosea, Olúwa wí fún un pé, “Lọ, fẹ́ àgbèrè obìnrin kan fún ara rẹ, kí ó sì bí ọmọ àgbèrè fún ọ nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin mìíràn, nítorí ilẹ̀ ti ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè púpọ̀ nípa yíyapa kúrò lọ́dọ̀ Olúwa.” 3Nígbà náà ni ó sì lọ, ó sì fẹ́ Gomeri ọmọbìnrin Diblaimu, ọmọbìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un.

4Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Hosea pé, “Pe orúkọ ọmọ náà ní Jesreeli, nítorí pé láìpẹ́ ni èmi yóò jẹ ìdílé Jehu ní ìyà fún ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn tó pa ní ìpakúpa ní Jesreeli, Èmi yóò sì mú ìjọba Israẹli wá sí òpin. 5Ní ọjọ́ náà ni Èmi yóò ṣẹ́ ọrun Israẹli ní Àfonífojì Jesreeli.”

61.6,9: Ho 2.23; 1Pt 2.10.Gomeri sì tún lóyún, ó sì bí ọmọbìnrin kan. Olúwa sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-rúhámà, nítorí pé Èmi kò ní ṣàánú fún ilé Israẹli mọ́, Èmi kò sì ní dáríjì wọ́n. 7Síbẹ̀, èmi yóò ṣàánú fún ilé Juda, èmi ó gbà wọ́n—kì í ṣe nípa ọfà, idà tàbí ogun, ẹṣin tàbí kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́ṣin bí kò ṣe nípa Olúwa Ọlọ́run wọn.”

8Lẹ́yìn ìgbà tí ó gba ọmú lẹ́nu Lo-rúhámà, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn. Nígbà náà ni 9Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-Ammi, nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.

10“Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli yóò pọ̀ bí i iyanrìn etí Òkun tí a kò le wọ́n, tí a kò sì le è kà, yóò sì ṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘ọmọ Ọlọ́run alààyè.’ 11Àwọn ènìyàn Juda àti àwọn ènìyàn Israẹli yóò parapọ̀, wọn yóò sì yan olórí kan tí yóò jáde láti ilẹ̀ náà, nítorí pé ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ Jesreeli yóò jẹ́.

O Livro

Oséias 1:1-11

1Estas são as mensagens que o Senhor dirigiu a Oseias, filho de Beeri, durante os reinados de Uzias, Jotão, Acaz e Ezequias, reis de Judá, e também durante o reinado de Jeroboão, filho de Jeoás, rei de Israel.

A esposa e os filhos de Oseias

2Foi esta a primeira mensagem que o Senhor comunicou a Oseias: “Casa-te com uma rapariga que seja prostituta e tem filhos com ela, de modo que sejam da mesma índole da mãe. Isto ilustrará a forma infiel como o meu povo se tem conduzido para comigo, cometendo abertamente adultério contra mim ao adorarem outros deuses.”

3Então Oseias casou com Gomer, filha de Diblaim, e ela concebeu e deu à luz um filho.

4O Senhor disse-lhe: “Põe-lhe o nome de Jezreel, porque no vale de Jezreel em breve castigarei a dinastia do rei Jeú, por causa dos assassínios que cometeu. 5Na verdade, em breve porei fim a Israel como reino independente, quebrando o arco de Israel, nesse vale de Jezreel.”

6Gomer tornou a conceber e teve outro filho, uma rapariga. Deus disse a Oseias: “Põe-lhe o nome de Lo-Ruama (sem misericórdia), porque não mais terei misericórdia de Israel para lhe perdoar. 7Contudo, da tribo de Judá, desta sim, terei misericórdia. Hei de salvá-los, porque sou o Senhor, seu Deus. E não os salvarei pelo arco ou pela espada, pela guerra ou pelos cavalos e cavaleiros.”

8Depois de ter desmamado Lo-Ruama, Gomer teve outro filho, um outro rapaz. 9E Deus mandou: “Chama-lhe Lo-Ami (não são meu povo), porque Israel não me pertence e eu não sou o seu Deus.

10Todavia, há de vir o tempo em que Israel se tornará uma grande e próspera nação. Nessa altura, o seu povo será demasiado numeroso para se poder contar; será como a areia do mar! E então, em vez de lhes dizer vocês não são meu povo, dir-lhes-ei, vocês são meus filhos, filhos do Deus vivo! 11O povo de Israel e de Judá unir-se-ão sob um único líder e regressarão juntos do exílio. Que grande dia será esse, em que Deus plantará novamente o seu povo no fértil solo da sua própria terra!