Heberu 2 – YCB & CARS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Heberu 2:1-18

Ìkìlọ̀ láti ṣe ìgbọ́ràn

1Nítorí náà, ó yẹ kí àwa máa fi iyè sí àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì gidigidi tí àwa ti gbọ́, kí a má ba à gbá wa lọ kúrò nínú wọn nígbà kan. 2Nítorí bí ọ̀rọ̀ tí a tí ẹnu àwọn angẹli sọ bá sì dúró ṣinṣin, àti tí olúkúlùkù ẹ̀ṣẹ̀ sí òfin àti àìgbọ́ràn gba ìjìyà tí ó tọ́ sí i, 3kín ni ohun náà tí ó mú wa lérò pé a lè bọ́ kúrò nínú ìjìyà bí a kò bá náání ìgbàlà ńlá yìí? Ìgbàlà tí Olúwa fúnrarẹ̀ kọ́kọ́ kéde, èyí tí a sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ fún wa láti ọwọ́ àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà lẹ́nu rẹ̀. 4Ọlọ́run jẹ́rìí sí i nípa àwọn iṣẹ́ ààmì àti ìyanu àti oríṣìíríṣìí iṣẹ́ agbára àti nípa ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ tí a pín gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀.

Jesu bí arákùnrin rẹ̀

5Nítorí pé, kì í ṣe abẹ́ ìṣàkóso àwọn angẹli ni ó fi ayé tí ń bọ̀, tí àwa ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ sí. 62.6-9: Sm 8.4-6.Ṣùgbọ́n ibìkan wà tí ẹnìkan tí jẹ́rìí pé:

“Kí ni ènìyàn tí ìwọ fi ń ṣe ìrántí rẹ̀,

tàbí ọmọ ènìyàn, tí ìwọ fi ń bẹ̀ ẹ́ wò?

7Ìwọ dá a ní onírẹ̀lẹ̀ díẹ̀ ju àwọn angẹli lọ;

ìwọ fi ògo àti ọlá de e ni adé,

ìwọ sì fi í jẹ olórí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ:

8Ìwọ fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.”

Ní ti fífi ohun gbogbo sábẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n àwa kò ì tí ì rí ohun kan tí ó kù tí kò sí ní abẹ́ àkóso rẹ̀. Síbẹ̀ nísinsin yìí àwa kò ì tí ì rí pé ó fi ohun gbogbo sábẹ́ ìṣàkóso rẹ̀ 9Ṣùgbọ́n àwa rí Jesu ẹni tí a rẹ̀ sílẹ̀ díẹ̀ ju àwọn angẹli lọ fún àkókò díẹ̀, àní Jesu, ẹni tí a fi ògo àti ọlá dé ní adé nítorí ìjìyà wa; kí ó lè tọ́ ikú wò fún olúkúlùkù ènìyàn nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.

10Nítorí pé ó yẹ fún Ọlọ́run, nítorí nípasẹ̀ ẹni tí ohun gbogbo ṣẹ̀ wà, láti mú àwọn ọmọ púpọ̀ wá sínú ògo, láti ṣe balógun ìgbàlà wọn ni àṣepé nípa ìjìyà. 11Nítorí àti ẹni tí ń sọ ni di mímọ́ àti àwọn tí a ń sọ di mímọ́, láti ọ̀dọ̀ ẹnìkan ṣoṣo ni gbogbo wọn ti wá: Nítorí èyí ni kò ṣe tijú láti pè wọ́n ni arákùnrin. 122.12: Sm 22.22.Àti wí pé,

“Èmi ó sọ̀rọ̀ orúkọ rẹ̀ fún àwọn ará mi,

ni àárín ìjọ ni èmi yóò kọrin ìyìn rẹ̀.”

132.13: Isa 8.17-18.Àti pẹ̀lú,

“Èmi yóò gbẹ́kẹ̀ mi lé e.”

Àti pẹ̀lú,

“Kíyèsi í, èmi rèé, èmi àti àwọn ọmọ tí Ọlọ́run fi fún mi.”

14Ǹjẹ́ ni ìwọ̀n bí àwọn ọmọ tí ṣe alábápín ará àti ẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni òun pẹ̀lú sì ṣe alábápín nínú ohun kan náà; kí ó lè ti ipa ikú rẹ̀ pa ẹni tí ó ní agbára ikú run, èyí ni èṣù. 15Kí o sì lè gba gbogbo àwọn tí ó tìtorí ìbẹ̀rù ikú wà lábẹ́ ìdè lọ́jọ́ ayé wọn gbogbo kúrò lọ́wọ́ ìbẹ̀rù. 162.16: Isa 41.8-9.Nítorí pé, nítòótọ́, kì í ṣe àwọn angẹli ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún, ṣùgbọ́n àwọn irú-ọmọ Abrahamu ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún. 17Nítorí náà, ó yẹ pé nínú ohun gbogbo kí ó dàbí àwọn ará rẹ̀, kí ó lè jẹ́ aláàánú àti olóòtítọ́ alábojútó Àlùfáà nínú ohun tí i ṣe ti Ọlọ́run, kí o lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn. 18Nítorí níwọ̀n bí òun tìkára rẹ̀ ti jìyà tí a sì ti dán an wò, òun ní agbára láti ran àwọn tí a ń dánwò lọ́wọ́.

Священное Писание

Евреям 2:1-18

Призыв не пренебрегать вестью о спасении

1Поэтому мы должны со всем вниманием отнестись к тому, что мы услышали, чтобы нам не отпасть. 2Весть Всевышнего, переданная через ангелов, имела силу, и каждое нарушение и непослушание влекли за собой справедливое наказание2:2 См. Деян. 7:53; Гал. 3:19.. 3Тогда как же нам избежать наказания сейчас, если мы пренебрегаем великим спасением, которое было провозглашено Самим Повелителем Исой? И нам это подтвердили те, кто лично слышал от Него эту весть, 4которую Сам Всевышний удостоверил знамениями, чудесами, различными проявлениями Его силы и дарами Святого Духа, распределяемыми по Его усмотрению.

Иса Масих стал Человеком, чтобы спасти нас

5Будущий мир, о котором мы говорим, Всевышний подчинил не ангелам. 6Но где-то некто засвидетельствовал:

«Кто такой человек, что Ты беспокоишься о нём?

Кто такой сын человека2:6 Сын человека – то есть человек вообще. Но «Сын Человека» – это также титул, указывающий на Масиха (см. Мат. 8:20 со сноской)., что Ты заботишься о нём?

7Ты на короткое время сделал его ниже ангелов2:7 Или: «Ты сделал его немного ниже ангелов».;

Ты увенчал его славой и честью,

8Ты всё подчинил под ноги его»2:6-8 Заб. 8:5-7. Всевышний поставил человека над всеми живыми существами на земле (см. Нач. 1:28)..

Всевышний всё покорил человеку, не оставив ничего непокорённым ему. Но сейчас мы пока не видим, что человеку всё подчинено. 9Однако мы видим, что Иса, Который действительно был на некоторое время поставлен ниже ангелов2:9 Или: «был поставлен немного ниже ангелов»., сейчас увенчан славой и честью, потому что претерпел смерть; по благодати Всевышнего к нам Он вкусил смерть за каждого человека.

10Надлежало, чтобы Всевышний, для Которого и благодаря Которому всё существует, полностью приготовил через страдания Ису, приводящего всё множество сынов2:10 Имеются в виду все истинные последователи Исы Масиха (см. Ин. 1:12). в славу (Он – вождь их спасения). 11Ведь и Тот, Кто освящает, и те, кто освящается Им, – все дети одного Небесного Отца, и поэтому Иса не стыдится называть их братьями. 12Он говорит:

«Я возвещу Твоё имя братьям Моим

и посреди собрания буду петь славу Тебе»2:12 Заб. 21:23..

13И ещё Он говорит:

«Я буду полагаться на Него»2:13 Ис. 8:17..

И ещё:

«Вот Я и дети, которых дал Мне Всевышний»2:13 Ис. 8:18..

14А так как дети имеют плоть и кровь, то и Он Сам получил физическое тело, чтобы Своей смертью лишить силы того, кому принадлежит власть над смертью, то есть дьявола, 15и освободить тех, кто всю свою жизнь находился в рабстве у страха перед смертью. 16Ведь не ангелам Он помогает, а потомкам пророка Ибрахима. 17Для этого Масиху2:17 Масих (переводится как «Помазанник») – праведный Царь и Освободитель, Спаситель, обещанный Всевышним ещё в Таурате, Забуре и Книге Пророков. надо было во всём стать таким, как Его братья, чтобы быть Верховным Священнослужителем, милосердным и верным в служении Всевышнему, для умилостивления за грехи народа. 18Он Сам страдал, перенося искушения, и может теперь помочь тем, кто встречает искушения в жизни.