Heberu 1 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Heberu 1:1-14

Ọmọ tí o ṣe pàtàkì fún àwọn Angẹli

1Ní ìgbà àtijọ́, Ọlọ́run bá àwọn baba ńlá wa sọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì ní ọ̀pọ̀ ìgbà àti ní onírúurú ọ̀nà, 2ṣùgbọ́n ní ìgbà ìkẹyìn yìí Ọlọ́run ń bá wa sọ̀rọ̀ nípasẹ̀ Ọmọ rẹ̀ Jesu Kristi, ẹni tí ó fi ṣe ajogún ohun gbogbo, nípasẹ̀ ẹni tí ó dá gbogbo ayé yìí àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀: 3Ọmọ tí í ṣe ìtànṣán ògo Ọlọ́run àti àwòrán òun tìkára rẹ̀, tí ó sì ń fi ọ̀rọ̀ agbára rẹ̀ mú ohun gbogbo dúró: Lẹ́yìn tí ó ti ṣe ìwẹ̀nù ẹ̀ṣẹ̀ wa tan, ó wá jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún Ọláńlá ní òkè. 4Nítorí náà, ó sì ti fi bẹ́ẹ̀ di ẹni tí ó ga ní ipò ju angẹli lọ, bí ó ti jogún orúkọ èyí tí ó tayọ̀ tiwọn.

51.5: Sm 2.7; 2Sa 7.14.Nítorí kò sí ọ̀kan nínú àwọn angẹli tí Ọlọ́run fi ìgbà kan sọ fún pé:

“Ìwọ ni ọmọ mi;

lónìí ni mo bí ọ”?

Àti pẹ̀lú pé;

“Èmi yóò jẹ́ baba fún un,

Òun yóò sì jẹ́ ọmọ mi”?

61.6: De 32.43; Sm 97.7.Àti pẹ̀lú, nígbà tí Ọlọ́run rán àkọ́bí rẹ̀ wá si ayé wa yìí. Ó pàṣẹ pé,

“Ẹ jẹ́ kí gbogbo àwọn angẹli Ọlọ́run foríbalẹ̀ fún un.”

71.7: Sm 104.4.Àti nípa ti àwọn angẹli, ó wí pé;

“Ẹni tí ó dá àwọn angẹli rẹ̀ ní ẹ̀mí,

àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ní ọwọ́ iná.”

81.8-9: Sm 45.6-7.Ṣùgbọ́n ó sọ nípa tí Ọmọ rẹ̀ pé,

“Ìtẹ́ rẹ, Ọlọ́run, láé àti láéláé ni,

ọ̀pá aládé òdodo ni ọ̀pá ìjọba rẹ.

9Ìwọ fẹ́ òdodo, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kórìíra iṣẹ́ búburú;

nítorí èyí ni Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ ṣe fi ààmì òróró ayọ̀ yàn ọ

tí ó gbé ọ ju àwọn ẹgbẹ́ rẹ lọ.”

10Ó tún sọ pé,

“Ní àtètèkọ́ṣe, ìwọ Olúwa, ìwọ fi ìdí ayé sọlẹ̀,

àwọn ọ̀run sì jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ ara rẹ.

11Wọn yóò ṣègbé, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà síbẹ̀

gbogbo wọn ni yóò di àkísà bí ẹ̀wù.

12Ní kíká ni ìwọ yóò ká wọn bí aṣọ,

bí ìpààrọ̀ aṣọ ni a ó sì pààrọ̀ wọn.

Ṣùgbọ́n ìwọ fúnrarẹ̀ kì yóò yípadà

àti pé ọdún rẹ kì yóò ní òpin.”

131.13: Sm 110.1.Èwo nínú àwọn angẹli ní a gbọ́ pé Ọlọ́run fi ìgbà kan wí fún pé,

“Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi

títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ

di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ”?

14Kì í ha á ṣe ẹ̀mí tí ń jíṣẹ́ ni àwọn angẹli í ṣe bí; tí a rán lọ síta láti máa ṣiṣẹ́ fún àwọn tí yóò jogún ìgbàlà?

New International Version

Hebrews 1:1-14

God’s Final Word: His Son

1In the past God spoke to our ancestors through the prophets at many times and in various ways, 2but in these last days he has spoken to us by his Son, whom he appointed heir of all things, and through whom also he made the universe. 3The Son is the radiance of God’s glory and the exact representation of his being, sustaining all things by his powerful word. After he had provided purification for sins, he sat down at the right hand of the Majesty in heaven. 4So he became as much superior to the angels as the name he has inherited is superior to theirs.

The Son Superior to Angels

5For to which of the angels did God ever say,

“You are my Son;

today I have become your Father”1:5 Psalm 2:7?

Or again,

“I will be his Father,

and he will be my Son”1:5 2 Samuel 7:14; 1 Chron. 17:13?

6And again, when God brings his firstborn into the world, he says,

“Let all God’s angels worship him.”1:6 Deut. 32:43 (see Dead Sea Scrolls and Septuagint)

7In speaking of the angels he says,

“He makes his angels spirits,

and his servants flames of fire.”1:7 Psalm 104:4

8But about the Son he says,

“Your throne, O God, will last for ever and ever;

a scepter of justice will be the scepter of your kingdom.

9You have loved righteousness and hated wickedness;

therefore God, your God, has set you above your companions

by anointing you with the oil of joy.”1:9 Psalm 45:6,7

10He also says,

“In the beginning, Lord, you laid the foundations of the earth,

and the heavens are the work of your hands.

11They will perish, but you remain;

they will all wear out like a garment.

12You will roll them up like a robe;

like a garment they will be changed.

But you remain the same,

and your years will never end.”1:12 Psalm 102:25-27

13To which of the angels did God ever say,

“Sit at my right hand

until I make your enemies

a footstool for your feet”1:13 Psalm 110:1?

14Are not all angels ministering spirits sent to serve those who will inherit salvation?