Habakuku 1 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Habakuku 1:1-17

1Àsọtẹ́lẹ̀ tí wòlíì Habakuku rí.

Ìráhùn Habakuku

21.2: Isa 13.1–14.23; 47; Jr 50–51.Olúwa, èmi yóò ti ké pẹ́ tó fún ìrànlọ́wọ́,

Ṣùgbọ́n ti ìwọ kò ni fetí sí mi?

Tàbí kígbe sí ọ ní ti, “Ìwà ipá!”

ṣùgbọ́n tí ìwọ kò sì gbàlà?

3Èéṣe tí ìwọ fi mú mi rí àìṣedéédéé

Èéṣe tí ìwọ sì fi ààyè gba ìwà ìkà?

Ìparun àti ìwà ipá wà ní iwájú mi;

ìjà ń bẹ, ìkọlù sì wà pẹ̀lú.

4Nítorí náà, òfin di ohun àìkàsí,

ìdájọ́ òdodo kò sì borí.

Àwọn ẹni búburú yí àwọn olódodo ká,

Nítorí náà ni ìdájọ́ òdodo ṣe yí padà.

Ìdáhùn Olúwa

51.5: Ap 13.41.“Ẹ wo inú àwọn kèfèrí, ki ẹ sí wòye,

Kí háà kí ó sì ṣe yin gidigidi.

Nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín

tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́,

bí a tilẹ̀ sọ fún yin.

61.6: If 20.9.Nítorí pé, èmi yóò gbé àwọn ara Babeli dìde,

àwọn aláìláàánú àti onínú-fùfù ènìyàn

tí ó rin gbogbo ilẹ̀ ayé já

láti fi agbára gbà àwọn ibùgbé tí kì í ṣe tiwọn.

7Wọn jẹ́ ènìyàn ti a bẹ̀rù, tí a sì páyà,

ìdájọ́ wọn, àti ọláńlá wọn,

Yóò máa ti inú wọn jáde.

8Ẹṣin wọn yára ju ẹkùn lọ,

wọ́n sì gbóná jú ìkookò àṣálẹ́ lọ

àwọn ẹlẹ́ṣin wọn yóò sí tan ara wọn ká;

wọn yóò sì wá láti ọ̀nà jíjìn réré,

wọn yóò sí fò bí ẹyẹ igún tí ń wá láti jẹrun

9Gbogbo wọn sì wà fún ìwà ipá

ìwò ojú wọn yóò sì wá síwájú;

wọn sì ko ìgbèkùn jọ bí iyanrìn.

10Wọn ó si máa fi àwọn ọba ṣẹ̀sín

wọn ó sì tún kẹ́gàn àwọn aládé.

Wọn yóò sì fi gbogbo ìlú odi alágbára nì rẹ́rìn-ín;

Nítorí pé, wọn yóò ko erùpẹ̀ jọ, wọn yóò sì gbà á

11Nígbà náà ni inú rẹ̀ yóò yípadà,

yóò sì rékọjá, yóò si ṣẹ̀ ní kíka agbára rẹ̀ yìí sí iṣẹ́ òrìṣà rẹ̀.”

Ìráhùn lẹ́ẹ̀kejì Habakuku

12Olúwa, ǹjẹ́ láti ayérayé kọ ni ìwọ tí wà?

Olúwa Ọlọ́run mi. Ẹni mímọ́ mi, àwa kì yóò kú

Olúwa, ìwọ tí yàn wọn fún ìdájọ́;

Ọlọ́run alágbára, ìwọ tí fi ẹsẹ̀ wọn múlẹ̀ fún ìbáwí

13Ojú rẹ mọ́ tónítóní láti wo ibi;

ìwọ kò le gbà ìwà ìkà

nítorí kí ni ìwọ ṣe gba àwọn alárékérekè láààyè?

Nítorí kí ni ìwọ ṣe dákẹ́ nígbà tí ẹni búburú ń pa

ẹni tí i ṣe olódodo ju wọn lọ run?

14Ìwọ sì tí sọ ènìyàn di bí ẹja inú Òkun,

bí ohun tí ń rákò tí wọn ko ni alákòóso

15Àwọn ènìyàn búburú fi àwọ̀n wọn gbé wọn sókè

ó sì kó wọn jọ nínú àwọ̀n ńlá rẹ̀;

nítorí náà, ó dunnú, ó sì yọ̀ pẹ̀lú.

16Nítorí náà, ó rú ẹbọ sí àwọ̀n rẹ̀,

ó sì ń sun tùràrí fún àwọ̀n ńlá rẹ̀

nítorí pẹ̀lú àwọ̀n rẹ̀ ni ó fi ń gbé ní ìgbádùn

tí ó sì ń gbádùn pẹ̀lú oúnjẹ tí ó bá wù ú.

17Ǹjẹ́ wọn yóò ha máa pa àwọ̀n wọn mọ́ ní òfìfo bí,

tí wọn yóò sì pa orílẹ̀-èdè run láìsí àánú?

Persian Contemporary Bible

حبقوق 1:1-17

1اين است پيغامی كه خداوند در رؤيا به حبقوق نبی نشان داد.

شكايت حبقوق

2ای خداوند، تا به كی از تو كمک بطلبم تا مرا اجابت فرمايی؟ هر چه فرياد برمی‌آورم بی‌فايده است، زيرا تو ما را از ظلم نجات نمی‌دهی. 3تا به كی بايد ناظر اين بی‌عدالتی‌ای كه اطراف مرا گرفته است باشم؟ چرا كاری نمی‌كنی؟ به هر جا كه نگاه می‌كنم خرابی و ظلم می‌بينم، همه جا را جنگ و دشمنی فرا گرفته است. 4قانون سست شده و عدالت هرگز بجا آورده نمی‌شود. شروران، درستكاران را در تنگنا گذاشته‌اند و عدالت مفهوم خود را از دست داده است.

پاسخ خداوند به قوم يهود

5«به قومهای اطراف خود نگاه كنيد و تعجب نماييد! شما از آنچه می‌خواهم انجام دهم حيران خواهيد شد! زيرا در روزگار شما كاری می‌كنم كه حتی وقتی خبرش را به شما دهند، باور نكنيد! 6من بابلی‌های ظالم و ستمگر را به قدرت می‌رسانم و آنها به سراسر جهان تاخته همه جا را به تصرف خود در خواهند آورد. 7آنها به سنگدلی معروفند، هر چه بخواهند می‌كنند، و كسی را يارای مقاومت در برابر آنها نيست. 8مردمانی هستند درنده‌خو، درنده‌تر از گرگهای گرسنه. اسبانشان از پلنگ سريعترند. سواران آنها از سرزمين دور دست می‌تازند و همچون عقاب بر سر صيد خود فرود می‌آيند. 9با خشونت به پيش می‌تازند و مثل ريگ بيابان اسير می‌گيرند.

10«پادشاهان و بزرگان را تمسخر می‌كنند و قلعه‌ها را به هيچ می‌شمارند. در پشت ديوار قلعه‌ها خاک انباشته می‌كنند و آنها را تصرف می‌نمايند! 11مثل باد يورش می‌برند و می‌گذرند. ولی گناهشان بزرگ است، زيرا قدرت خود را خدای خود می‌دانند.»

شكايت دوم حبقوق

12ای خداوند، خدای من! ای قدوس من كه از ازل هستی! تو نخواهی گذاشت كه ما نابود شويم. ای خدايی كه صخرهٔ ما هستی، تو به بابلی‌ها قدرت بخشيدی تا ما را مجازات كنند. 13درست است كه ما گناهكاريم، ولی آنها از ما گناهكارترند. چشمان تو پاكتر از آن است كه بر گناه بنگرد، و تو عادلتر از آن هستی كه بی‌انصافی را تحمل كنی. پس چرا هنگامی كه شروران مردمی را كه از خودشان بی‌گناهترند می‌بلعند، خاموش می‌مانی؟

14‏-15چرا مردم را مانند ماهيان و جانوران دريا كه مدافعی ندارند به قلاب بابلی‌ها می‌اندازی؟ آنها با تور خود مردم را به دام می‌اندازند و از صيد آنها شادی می‌كنند. 16سپس رفته، تورهای خود را پرستش می‌نمايند و برای آنها قربانی می‌كنند، زيرا خوراک و ثروت خود را مديون اين تورها می‌دانند.

17آيا تو می‌گذاری آنها دائم به كشتار خود ادامه دهند و مردم را بی‌رحمانه نابود كنند؟