Gẹnẹsisi 6 – YCB & NRT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 6:1-22

Ìkún omi

16.1-4: Jb 1.6; 2.1.Nígbà tí ènìyàn bẹ̀rẹ̀ sí ní pọ̀ si ní orí ilẹ̀, wọ́n sí bí àwọn ọmọbìnrin. 2Àwọn ọmọ Ọlọ́run rí i wí pé àwọn ọmọbìnrin ènìyàn lẹ́wà, wọ́n sì fẹ́ èyíkéyìí tí ó wù wọ́n ṣe aya. 3Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Èémí ìyè tí mo mí sínú ènìyàn kò ní máa gbé inú ènìyàn títí láé, nítorí ẹran-ara sá à ni òun, ọgọ́fà ọdún ni ọjọ́ rẹ̀ yóò jẹ́.”

46.4: Nu 13.33.Àwọn òmíràn wà láyé ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àti lẹ́yìn ìgbà náà; nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run lọ bá àwọn ọmọbìnrin ènìyàn lòpọ̀ tí wọ́n sì bímọ fún wọn. Àwọn náà ni ó di akọni àti olókìkí ìgbà náà.

5Olúwa sì rí bí ìwà búburú ènìyàn ti ń gbilẹ̀ si, àti pé gbogbo èrò inú rẹ̀ kìkì ibi ni, ní ìgbà gbogbo. 6Inú Olúwa sì bàjẹ́ gidigidi nítorí pé ó dá ènìyàn sí ayé, ọkàn rẹ̀ sì gbọgbẹ́. 7Nítorí náà, Olúwa wí pé, “Èmi yóò pa ènìyàn tí mo ti dá run kúrò lórí ilẹ̀, ènìyàn àti ẹranko, àti ohun tí ń rákò, àti ẹyẹ ojú ọ̀run, nítorí inú mi bàjẹ́ pé mo ti dá wọn.” 8Ṣùgbọ́n, Noa rí ojúrere Olúwa.

96.9: 2Pt 2.5.Wọ̀nyí ni ìtàn Noa.

Noa nìkan ni ó jẹ́ olóòótọ́ ènìyàn àti ẹni tí ó pé ní ìgbà ayé rẹ̀, ó sì fi òtítọ́ bá Ọlọ́run rìn. 10Noa sì bí ọmọkùnrin mẹ́ta, Ṣemu, Hamu àti Jafeti.

11Ayé sì kún fún ìbàjẹ́ gidigidi ní ojú Ọlọ́run, ó sì kún fún ìwà ipá pẹ̀lú. 12Ọlọ́run sì rí bí ayé ti bàjẹ́ tó, nítorí àwọn ènìyàn inú ayé ti bá ara wọn jẹ́ ní gbogbo ọ̀nà wọn. 13Ọlọ́run sì wí fún Noa pé, “Èmi yóò pa gbogbo ènìyàn run, nítorí ilẹ̀ ayé kún fún ìwà ipá nípasẹ̀ wọn. Èmi yóò pa wọ́n run àti ayé pẹ̀lú. 14Nítorí náà fi igi ọ̀mọ̀ kan ọkọ̀, kí o sì yọ yàrá sí inú rẹ̀, kí o sì fi ọ̀dà-ilẹ̀ rẹ́ ẹ tinú-tẹ̀yìn. 15Báyìí ni ìwọ yóò ṣe kan ọkọ̀ náà: Gígùn rẹ̀ ní òró yóò jẹ́ ọ̀ọ́dúnrún ìgbọ̀nwọ́, ìbú rẹ̀ yóò jẹ́ àádọ́ta ìgbọ̀nwọ́, nígbà tí gíga rẹ̀ yóò jẹ́ ọgbọ̀n ìgbọ̀nwọ́. 16Ṣe òrùlé sí orí ọkọ̀ náà ní ìgbọ̀nwọ́ kan, sì ṣe ọkọ̀ náà ní alájà mẹ́ta, ipá kan ní ìsàlẹ̀, ọ̀kan ní àárín àti ọ̀kan tí ó kù ní òkè, ẹ̀gbẹ́ ni kí ó ṣe ẹnu-ọ̀nà ọkọ̀ náà sí. 17Èmi yóò mú ìkún omi wá sí ayé láti pa gbogbo ohun ẹlẹ́mìí run lábẹ́ ọ̀run. Gbogbo ẹ̀dá tí ó ní èémí ìyè ní inú. Gbogbo ohun tí ó wà nínú ayé yóò parun. 18Ṣùgbọ́n èmi ó dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì wọ ọkọ̀, ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú aya rẹ. 19Ìwọ yóò mú gbogbo ohun alààyè takọ tabo wá sí inú ọkọ̀, kí wọn le wà láààyè pẹ̀lú rẹ. 20Mú onírúurú àwọn ẹyẹ, ẹranko àti àwọn ohun tí ń rákò ní méjì méjì, kí a bá lè pa wọ́n mọ́ láààyè. 21Mú onírúurú oúnjẹ wá sínú ọkọ̀, kí o pa wọ́n mọ́ fún jíjẹ gbogbo ẹ̀yin tí ẹ wà nínú ọkọ̀ àti ènìyàn àti ẹranko.”

226.22: Hb 11.7.Noa sì ṣe ohun gbogbo bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.

New Russian Translation

Бытие 6:1-22

Замысел об уничтожении человечества

1Люди начали умножаться на земле, и у них стали рождаться дочери. 2Сыны Божьи увидели, что человеческие дочери прекрасны, и стали брать их себе в жены, каждый по своему выбору.

3Господь сказал:

– Не вечно будет Дух Мой в противоборстве с человеком6:3 Или: «Мой Дух не останется в человеке»., потому что человек развращен6:3 Букв.: «плоть».; пусть будут дни их сто двадцать лет.

4В те дни, после того как сыны Божьи входили к человеческим дочерям и имели от них детей, были на земле исполины6:4 На языке оригинала это название звучит как слово, означающее: «падшие люди» (евр.: «нефилим»). Позднее они стали знаменитым родом воинственных гигантов (см. Чис. 13:34).. Это были герои, знаменитые с древних времен.

5Господь увидел, что люди на земле развратились, и все их мысли постоянно склоняются к злу. 6Господь пожалел, что сотворил человека на земле, и сердце Его наполнилось болью.

7И сказал Господь:

– Я сотру с лица земли человеческий род, который Я сотворил. Я уничтожу и людей, и животных, и пресмыкающихся, и птиц небесных, потому что Я сожалею, что создал их.

Построение ковчега для спасения Ноя

8Но Ной нашел милость в глазах Господа.

9Вот рассказ о Ное.

Среди людей того времени лишь только Ной был праведен и безупречен; он ходил с Богом. 10У Ноя было трое сыновей: Сим, Хам и Иафет.

11В Божьих глазах земля преисполнилась разврата и насилия. 12Бог увидел, как испорчена земля из-за того, что все люди на земле извратили свои пути.

13Тогда Бог сказал Ною:

– Я положу конец всякому живому существу6:13 Букв.: «всякой плоти»., потому что из-за них земля преисполнилась насилия. Я погублю их вместе со всей землей. 14Сделай себе ковчег из кипарисового6:14 Значение этого слова в еврейском тексте неясно. дерева, и сделай в нем комнаты, и осмоли его изнутри и снаружи. 15Вот как ты должен его построить: ковчег должен быть 300 локтей в длину, 50 локтей в ширину и 30 локтей в высоту6:15 Около 150 м в длину, 25 м в ширину и 15 м в высоту.. 16Сделай для него крышу6:16 Или: «отверстие для света». и в верху сведи ковчег к одному локтю6:16 Около 50 см.. Поставь сбоку дверь и сделай нижнюю, среднюю и верхнюю палубы. 17Я наведу на землю воды потопа, чтобы погубить все, что живет под небом, всякое существо, в котором дышит жизнь. Все, что есть на земле, погибнет. 18Но с тобой Я заключу завет, и ты войдешь в ковчег – ты, и твои сыновья, и твоя жена, и жены твоих сыновей. 19Введи в ковчег всех живых существ по паре, самца и самку, чтобы они остались в живых вместе с тобой. 20К тебе придут, чтобы тоже остаться в живых, по паре от каждого вида птиц, зверей и каждого вида пресмыкающихся. 21Возьми в запас самой разной еды, чтобы кормиться и тебе, и им.

22Ной сделал все точно так, как велел ему Бог.