Gẹnẹsisi 50 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 50:1-26

1Josẹfu sì ṣubú lé baba rẹ̀, ó sọkún, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu. 2Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún àwọn oníṣègùn tí ó wà ní ìkáwọ́ rẹ̀ pé kí wọn kí ó ṣe òkú Israẹli baba rẹ̀ lọ́jọ̀, àwọn oníṣègùn náà sì ṣe bẹ́ẹ̀, 3Fún ogójì ọjọ́ ni wọ́n fi ṣe èyí, nítorí èyí ni àsìkò tí a máa ń fi ṣe ẹ̀ǹbáàmù òkú. Àwọn ará Ejibiti sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀ fún àádọ́rin ọjọ́.

4Nígbà tí ọjọ́ ìṣọ̀fọ̀ náà kọjá. Josẹfu wí fún àwọn ará ilé Farao pé, “Bí mo bá bá ojúrere yín pàdé, ẹ bá mi sọ fún Farao. 550.5: Gẹ 47.29-31.‘Baba mi mú mi búra ó sì wí fún mi pé, “Mo ti fẹ́rẹ kú: sinmi sínú ibojì tí mo gbẹ́ fún ara mi ní ilẹ̀ Kenaani.” Nísinsin yìí, jẹ́ kí n lọ kí n sì sìnkú baba mi, lẹ́yìn náà èmi yóò padà wa.’ ”

6Farao wí pé, “Gòkè lọ, kí o sì sin baba rẹ, bí ó tí mú ọ búra.”

7Báyìí ni Josẹfu gòkè lọ láti sìnkú baba rẹ̀. Gbogbo àwọn ìjòyè Farao ni ó sìn ín lọ—àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀, àti gbogbo àwọn àgbàgbà ilẹ̀ Ejibiti. 8Yàtọ̀ fún gbogbo àwọn ará ilé Josẹfu àti ti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti àwọn tí ó jẹ́ ilé baba rẹ̀, àwọn ọmọ wọn nìkan àti agbo ẹran pẹ̀lú agbo màlúù ni ó sẹ́ kù ní Goṣeni. 9Kẹ̀kẹ́-ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin pẹ̀lú gòkè lọ. Àìmoye ènìyàn ni ó lọ.

10Nígbà tí wọ́n dé ilẹ̀ ìpakà Atadi, ní ẹ̀bá Jordani, wọn pohùnréré ẹkún; Níbẹ̀ ni Josẹfu sì tún dúró ṣọ̀fọ̀ baba rẹ̀ fún ọjọ́ méje. 11Nígbà tí àwọn ará Kenaani tí ń gbé níbẹ̀ rí i bí wọ́n ti ń ṣọ̀fọ̀ náà ni ilẹ̀ ìpakà Atadi, wọ́n wí pé, “Ọ̀fọ̀ ńlá ni àwọn ará Ejibiti ń ṣe yìí.” Ìdí èyí ni a fi ń pe ibẹ̀ ní Abeli-Misraimu (Ìṣọ̀fọ̀ àwọn ará Ejibiti). Kò sì jìnnà sí Jordani.

12Báyìí ni àwọn ọmọ Jakọbu ṣe ohun tí baba wọn pàṣẹ fún wọn. 1350.13: Ap 7.16.Wọ́n gbé e lọ sí ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì sin ín sínú ihò àpáta tí ó wà ní oko Makpela, ní tòsí i Mamre tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti, pẹ̀lú ilẹ̀ náà. 14Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti sìnkú baba rẹ̀ tan, Josẹfu padà sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀ àti àwọn mìíràn tí ó tẹ̀lé e lọ láti sin baba rẹ̀.

Josẹfu fi ọkàn àwọn arákùnrin rẹ̀ balẹ̀

15Nígbà tí àwọn arákùnrin Josẹfu rí i pé baba wọn kú, wọ́n wí fún ara wọn pé, “Ǹjẹ́ bí ó bá ṣe pé Josẹfu ṣì fi wá sínú ńkọ́, tí ó sì fẹ́ gbẹ̀san gbogbo aburú tí a ti ṣe sí i?” 16Nítorí náà wọ́n ránṣẹ́ sí Josẹfu wí pé, “Baba rẹ fi àṣẹ yìí sílẹ̀ kí ó tó lọ wí pé: 17‘Èyí ni kí ẹ̀yin kí ó sọ fún Josẹfu: Mo bẹ̀ ọ́ kí o dáríjì àwọn arákùnrin rẹ, gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àti aburú tí wọ́n ṣe sí ọ, èyí tí ó mú ibi bá ọ’. Nísinsin yìí, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run baba rẹ jì wọ́n.” Nígbà tí iṣẹ́ ti wọ́n rán dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Josẹfu sọkún.

18Àwọn arákùnrin rẹ̀ wá, wọ́n sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, wọ́n wí pé, “Ẹrú rẹ ni a jẹ́.” 19Ṣùgbọ́n Josẹfu wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù, èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run bí? 20Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ gbèrò láti ṣe mi ní ibi, ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbèrò láti fi ṣe rere tí ń ṣe lọ́wọ́ yìí; ni gbígba ẹ̀mí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn là. 21Nítorí náà, ẹ má ṣe bẹ̀rù. Èmi yóò pèsè fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín.” Ó tún fi wọ́n lọ́kàn balẹ̀, ó sì sọ ọ̀rọ̀ rere fun wọn.

Ikú Josẹfu

22Josẹfu sì ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ìdílé baba rẹ̀. Ó sì wà láààyè fún àádọ́fà (110) ọdún. 23Ó sì rí ìran kẹta ọmọ Efraimu-Àwọn ọmọ Makiri, ọmọkùnrin Manase ni a sì gbé le eékún Josẹfu nígbà tí ó bí wọn.

24Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Mo ti fẹ́rẹ kú, ṣùgbọ́n dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, yóò sì mú un yín jáde kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí ó ti ṣèlérí ní ìbúra fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.” 25Josẹfu sì mú kí àwọn ọmọ Israẹli búra májẹ̀mú kan wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, nígbà náà ni ẹ gbọdọ̀ kó egungun mi lọ́wọ́ kúrò ní ìhín.”

26Báyìí ni Josẹfu kú nígbà tí ó pé àádọ́fà (110) ọdún. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ṣe òkú rẹ̀ lọ́jọ̀ tan, a gbé e sí inú pósí ní Ejibiti.

New International Reader’s Version

Genesis 50:1-26

1Joseph threw himself on his father’s body. He wept over him and kissed him. 2Then Joseph talked to the doctors who served him. He told them to prepare the body of his father Israel to be buried. So the doctors prepared it. 3They took 40 days to do it. They needed that much time to prepare a body in the right way. The Egyptians mourned for Jacob 70 days.

4After the days of sadness had passed, Joseph went to Pharaoh’s officials. He said to them, “If you are pleased with me, speak to Pharaoh for me. Tell him, 5‘My father made me give my word to him. He said, “I’m about to die. Bury me in the tomb I dug for myself in the land of Canaan.” So let me go there and bury my father. Then I’ll come back.’ ”

6Pharaoh said, “Go there and bury your father. Do what he made you promise to do.”

7So Joseph went to Canaan to bury his father. All Pharaoh’s officials went with him. They were the important people of his court and all the leaders of Egypt. 8Joseph’s family also went. His brothers and all the rest of his father’s family went. Only their children and their flocks and herds were left in Goshen. 9Chariots and horsemen also went up with him. It was a very large group.

10They came to Atad, a place where grain was processed. It was near the Jordan River. There they sobbed loudly and bitterly. Joseph set apart seven days of sadness to honor his father’s memory. 11The Canaanites living in that area saw how sad all of them were. They said, “The Egyptians are having a very special service for the dead.” That’s why that place near the Jordan River is called Abel of the Egyptians.

12So Jacob’s sons did exactly as he had commanded them. 13They carried his body to the land of Canaan. They buried it in the cave in the field of Machpelah near Mamre. Abraham had bought the cave as a place where he could bury his wife’s body. He had bought the cave and the field from Ephron, the Hittite. 14After Joseph buried his father, he went back to Egypt. His brothers and all the others who had gone to help him bury his father went back with him.

Joseph Calms His Brothers’ Fears

15Now that their father was dead, Joseph’s brothers were worried. They said, “Remember all the bad things we did to Joseph? What if he decides to hold those things against us? What if he pays us back for them?” 16So they sent a message to Joseph. They said, “Your father gave us directions before he died. 17He said, ‘Here’s what you must say to Joseph. Tell him, “I’m asking you to forgive your brothers. Forgive the terrible things they did to you. Forgive them for treating you so badly.” ’ Now then, please forgive our sins. We serve the God of your father.” When their message came to Joseph, he wept.

18Then his brothers came and threw themselves down in front of him. “We are your slaves,” they said.

19But Joseph said to them, “Don’t be afraid. Do you think I’m God? 20You planned to harm me. But God planned it for good. He planned to do what is now being done. He wanted to save many lives. 21So then, don’t be afraid. I’ll provide for you and your children.” He calmed their fears. And he spoke in a kind way to them.

Joseph Dies

22Joseph stayed in Egypt, along with all his father’s family. He lived 110 years. 23He lived long enough to see Ephraim’s children and grandchildren. When the children of Makir were born, they were placed on Joseph’s knees and counted as his own children. Makir was the son of Manasseh.

24Joseph said to his brothers, “I’m about to die. But God will surely come to help you. He’ll take you up out of this land. He’ll bring you to the land he promised to give to Abraham, Isaac and Jacob.” 25Joseph made the Israelites promise him. He said, “God will surely come to help you. Then you must carry my bones up from this place.”

26So Joseph died at the age of 110. They prepared his body to be buried. Then he was placed in a casket in Egypt.