Gẹnẹsisi 39 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 39:1-23

Josẹfu àti aya Potiferi

139.1,2,21: Ap 7.9.Nígbà tí wọ́n mú Josẹfu dé Ejibiti, Potiferi, ará Ejibiti tí i ṣe ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao. Òun ni olórí àwọn ọmọ-ogun Farao. Ó ra Josẹfu lọ́wọ́ àwọn ará Iṣmaeli tí wọ́n mú un lọ síbẹ̀.

2Olúwa sì wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì bùkún un, ó sì ń gbé ní ilé ọ̀gá rẹ̀ ará Ejibiti. 3Nígbà tí ọ̀gá rẹ̀ rí i pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀, àti pé Olúwa jẹ́ kí ó máa ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́ rẹ̀ lé. 4Josẹfu sì rí ojúrere Potiferi, ó sì di aṣojú rẹ̀, Potiferi fi Josẹfu ṣe olórí ilé rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní. 5Láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu jẹ olórí ilé rẹ̀ àti ohun ìní rẹ̀ gbogbo, ni Ọlọ́run ti bẹ̀rẹ̀ sí ní bùkún àwọn ará Ejibiti nítorí Josẹfu. Ìbùkún Olúwa wà lórí gbogbo ohun tí Potiferi ní, nílé àti lóko. 6Ó sì fi Josẹfu ṣe àkóso gbogbo ohun tí ó ní. Kò sì ṣe ìyọnu lórí ohunkóhun mọ àyàfi nípa oúnjẹ tí ó ń jẹ láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu ṣe àkóso ilé e rẹ̀.

Josẹfu sì jẹ́ arẹwà ọkùnrin ní ìdúró àti ìrísí rẹ̀, 7lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, aya rẹ̀ ṣe àkíyèsí Josẹfu, ó sì wí fún un pé, “Wá bá mi lòpọ̀!”

8Ṣùgbọ́n Josẹfu kọ̀, ó sì wí fún aya ọ̀gá rẹ̀ pé, “Kíyèsi, Olúwa mi kò fi ohunkóhun dù mi nínú ilé yìí, gbogbo ohun ìní rẹ̀ ni ó fi lé mi lọ́wọ́. 9Kò sí ẹni tí ó jù mi lọ nínú ilé yìí, ọ̀gá mi kò fi ohunkóhun dù mi àyàfi ìwọ, tí í ṣe aya rẹ̀. Báwo ni mo ṣe lè ṣe ohun búburú yìí, kí ń sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run?” 10Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo ìgbà ni ó ń tẹnumọ́ èyí fún Josẹfu, Josẹfu kọ̀ láti bá a lòpọ̀. Ó tilẹ̀ kọ̀ láti máa dúró ni ibi tí ó bá wà.

11Ní ọjọ́ kan, Josẹfu lọ sínú ilé láti ṣe iṣẹ́, kò sì sí èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ ní tòsí. 12Ó sì di aṣọ Josẹfu mú, ó sì wí pé, “Wá bá mi lòpọ̀!” Ṣùgbọ́n Josẹfu fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí i lọ́wọ́, ó sì sá jáde.

13Nígbà tí ó rí i pé ó ti fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí òun lọ́wọ́, ó sì ti sá jáde, 14ó pe àwọn ìránṣẹ́ ilé náà, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wò ó, ọkọ ọ̀ mi mú Heberu kan wọlé tọ̀ wá wá láti fi wá ṣe ẹlẹ́yà. Ó wọlé tọ̀ mí wá, láti bá mi lòpọ̀, ṣùgbọ́n mo kígbe. 15Nígbà tí ó gbọ́ pé mo gbé ohùn mi sókè, tí mo sì kígbe, ó jọ̀wọ́ aṣọ rẹ̀ sọ́dọ̀ mi, ó sì sá, ó bọ́ sóde.”

16Ó sì fi aṣọ náà sọ́dọ̀ títí tí ọkọ rẹ̀ fi dé. 17Ó rò fún un pé, “Ẹrú ará Heberu tí o rà wá ilé láti fi wá ṣẹlẹ́yà wá láti bá mi lòpọ̀. 18Ṣùgbọ́n bí mo ti kígbe fún ìrànlọ́wọ́, ó sì sá kúrò nínú ilé.”

19Nígbà tí Potiferi gbọ́ ọ̀rọ̀ aya rẹ̀ pé báyìí ni ẹrú rẹ̀ ṣe sí aya rẹ̀, ó bínú gidigidi. 20Ó sì ju Josẹfu sí ẹ̀wọ̀n, níbi tí a ń ju àwọn ẹlẹ́wọ̀n ọba sí.

Ṣùgbọ́n, nígbà tí Josẹfu wà nínú ẹ̀wọ̀n níbẹ̀, 2139.21: Ap 7.9.Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀, ó sì ṣàánú fún un, ó sì mú kí ó rí ojúrere àwọn alábojútó ọgbà ẹ̀wọ̀n (wọ́dà). 22Nítorí náà, alábojútó ọgbà ẹlẹ́wọ̀n fi Josẹfu ṣe alákòóso ohun gbogbo tí ó wà nínú ẹ̀wọ̀n, àti ohun tí wọn ń ṣe níbẹ̀. 23Wọ́dà náà kò sì mikàn nípa gbogbo ohun tí ó fi sí abẹ́ àkóso Josẹfu, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì ń jẹ́ kí ó ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́lé.

Nouă Traducere În Limba Română

Geneza 39:1-23

Iosif și soția lui Potifar

1Iosif a fost dus în Egipt, iar Potifar, comandant al gărzii1 Vezi nota de la 37:36. și unul dintre demnitarii lui Faraon, l‑a cumpărat de la ismaeliții care‑l coborâseră acolo. 2Domnul a fost cu Iosif, astfel încât acesta a prosperat și a locuit în casa stăpânului său, egipteanul. 3Stăpânul său a văzut că Domnul era cu Iosif și că Domnul îl ajuta să‑i prospere în mâini tot ce făcea. 4Iosif a găsit bunăvoință înaintea4 Lit.: în ochii. acestuia și i‑a slujit, iar stăpânul său l‑a pus responsabil peste casa lui și i‑a dat în grijă tot ce avea. 5De când Potifar l‑a pus responsabil peste casa lui și peste tot ce avea, Domnul a binecuvântat casa egipteanului datorită lui Iosif. Și binecuvântarea Domnului a fost peste tot ce avea el, atât în casă, cât și pe câmp. 6Astfel, stăpânul a lăsat în grija lui Iosif tot ce avea și nu se preocupa de nimic, în afară de hrana pe care o mânca. Iosif era frumos la chip și frumos la înfățișare.

7După toate acestea, soția stăpânului său a pus ochii pe Iosif și a zis:

– Culcă‑te cu mine!

8Dar el a refuzat și i‑a zis soției stăpânului său:

– Iată, pentru că știe că sunt aici, stăpânul meu nu se preocupă de ce este în casă și mi‑a dat pe mână tot ce are. 9Nimeni nu este mai mare decât mine în această casă, iar el nu m‑a oprit de la nimic, în afară de tine, pentru că ești soția lui. Deci cum aș putea să fac un rău așa de mare și să păcătuiesc împotriva lui Dumnezeu? 10Deși ea îi vorbea lui Iosif în fiecare zi, el n‑a ascultat de ea și n‑a vrut să se întindă lângă ea ca să fie cu ea.

11Într‑o zi însă, când Iosif a intrat în casă pentru a‑și îndeplini lucrarea și nimeni altcineva dintre oamenii casei nu era acolo, 12ea l‑a apucat de haină, zicând: „Culcă‑te cu mine!“ Dar el și‑a lăsat haina în mâna ei, a fugit și a ieșit afară. 13Când ea a văzut că și‑a lăsat haina în mâna ei și a fugit afară, 14i‑a chemat pe oamenii casei ei și le‑a zis: „Vedeți, ne‑a adus un evreu ca să‑și bată joc de noi. El a intrat la mine ca să se culce cu mine, dar eu am strigat cu glas tare. 15Când a auzit că îmi ridic glasul și strig, și‑a lăsat haina lângă mine, a fugit și a ieșit afară.“ 16Ea i‑a ținut haina lângă ea până când a venit stăpânul lui acasă. 17Apoi a vorbit cu el despre aceste lucruri, zicând: „Robul acela evreu, pe care ni l‑ai adus, a intrat la mine ca să‑și bată joc de mine. 18Dar când mi‑am ridicat glasul și am strigat, și‑a lăsat haina lângă mine și a fugit afară.“

19Când stăpânul său a auzit cuvintele soției sale, care spunea: „Așa s‑a purtat robul tău cu mine!“, s‑a aprins de mânie. 20Stăpânul lui Iosif l‑a luat și l‑a aruncat în temniță, în locul în care erau închiși prizonierii regelui. Și astfel a rămas acolo, în închisoare. 21Dar Domnul a fost cu Iosif, Și‑a întins îndurarea peste el și a făcut să găsească bunăvoință la comandantul temniței. 22Comandantul temniței i‑a dat în grija lui Iosif pe toți prizonierii care erau în temniță. Tot ceea ce se făcea acolo, se făcea prin el. 23Comandantul temniței nu mai cerceta nimic din ceea ce era în grija lui Iosif, pentru că Domnul era cu acesta și îl ajuta să prospere în orice făcea.