Gẹnẹsisi 31 – YCB & NSP

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 31:1-55

Jakọbu sá kúrò lọ́dọ̀ Labani

1Jakọbu sì gbọ́ pé àwọn ọmọ Labani ń wí pé, “Jakọbu ti gba gbogbo ohun ìní baba wa, ó sì ti kó ọrọ̀ jọ fún ara rẹ̀ lára àwọn ohun tí í ṣe ti baba wa.” 2Jakọbu sì ṣàkíyèsí pé ìwà Labani sí òun ti yí padà sí ti àtẹ̀yìnwá.

3Nígbà náà ni Olúwa wí fún Jakọbu pé, “Padà lọ sí ilẹ̀ àwọn baba à rẹ, sí ọ̀dọ̀ àwọn ará rẹ, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ.”

4Jakọbu sì ránṣẹ́ pe Rakeli àti Lea sí pápá níbi tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ wà. 5Ó sì wí fún wọn pé, “Mo rí i wí pé ìwà baba yín sí mi ti yí padà sí ti tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Ọlọ́run baba mi wà pẹ̀lú mi. 6Ẹ sá à mọ̀ pé, mo ti fi gbogbo agbára mi ṣiṣẹ́ fún baba yín, 7Síbẹ̀síbẹ̀ baba yín ti rẹ́ mi jẹ ní ẹ̀ẹ̀mẹwàá ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni ó sì ti yí owó iṣẹ́ mi padà. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò jẹ́ kí ó le è pa mi lára. 8Tí ó bá wí pé, ‘Àwọn ẹran onílà ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo àwọn ẹran ń bí onílà; bí ó bá sì wí pé, ‘Àwọn ẹran onítótòtó ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ’ nígbà náà ni gbogbo ẹran ń bi onítótòtó. 9Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run gba ẹran baba yín, ó sì fi fún mi.

10“Ní àsìkò tí àwọn ẹran ń gùn, mo la àlá mo sì ri pé àwọn òbúkọ tí wọ́n ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì. 11Angẹli Ọlọ́run wí fún mi nínú àlá náà pé, ‘Jakọbu.’ Mo sì wí pé, ‘Èmi nìyí.’ 12Ó sì wí pé, ‘Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wò ó, gbogbo àwọn òbúkọ tí ó ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì, nítorí mo ti rí gbogbo ohun ti Labani ń ṣe sí ọ. 1331.13: Gẹ 28.18-22.Èmi ni Ọlọ́run Beteli, níbi tí ìwọ ti ta òróró sí ọ̀wọ́n, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti sìn mi. Nísinsin yìí, kúrò ní ilẹ̀ yìí kíákíá kí o sì padà sí ilẹ̀ ibi tí a gbé ti bí ọ.’ ”

14Nígbà náà ni Rakeli àti Lea dáhùn pé, “Ìpín wo ní a ní nínú ogún baba wa? 15Àjèjì ha kọ́ ni ó kà wá sí? Kì í ṣe torí pé ó tà wá nìkan, ṣùgbọ́n ó ti ná gbogbo owó tí ó gbà lórí wa tán. 16Dájúdájú gbogbo ọrọ̀ ti Ọlọ́run gbà lọ́wọ́ baba wa fún ọ, tiwa àti ti àwọn ọmọ wa ní í ṣe. Nítorí náà ohun gbogbo tí Ọlọ́run bá pàṣẹ fun ọ láti ṣe ni kí ìwọ kí ó ṣe.”

17Nígbà náà ni Jakọbu gbé àwọn ọmọ àti aya rẹ̀ gun ìbákasẹ. 18Ó sì da gbogbo agbo ẹran rẹ̀ ṣáájú pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ tí ó ti kójọ ni Padani-Aramu, láti lọ sí ọ̀dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni ilẹ̀ Kenaani.

19Nígbà tí Labani sì lọ láti rẹ́run àgùntàn, Rakeli sì jí àwọn ère òrìṣà ilé baba rẹ̀. 20Síwájú sí i, Jakọbu tan Labani ará Aramu, nítorí kò sọ fún un wí pé òun ń sálọ. 21Ó sì sálọ pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ni, ó sì la odò kọjá (Eufurate), ó sì kọrí sí àwọn ilẹ̀ olókè ti Gileadi.

Labani lépa Jakọbu

22Ní ọjọ́ kẹta ni Labani gbọ́ pé Jakọbu ti sálọ. 23Ó sì mú àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì lépa Jakọbu, ó sì lépa wọn fún ọjọ́ méje, ó sì bá wọn ní òkè Gileadi. 24Ọlọ́run sì yọ sí Labani ará Aramu lójú àlá ní òru, ó sì wí fun un pé, “Ṣọ́ra, má ṣe sọ ohunkóhun fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.”

25Jakọbu ti pa àgọ́ rẹ̀ si orí òkè kan, nígbà tí Labani bá a. Labani àti àwọn tí ó wá pẹ̀lú rẹ̀ sì pàgọ́ tì wọ́n sí ilẹ̀ òkè Gileadi. 26Nígbà náà ni Labani wí fún Jakọbu pé, “Èwo ni ìwọ ṣe yìí? Tí ìwọ sì tàn mi, ó sì kó àwọn ọmọbìnrin mi bi ìgbèkùn tí a fi idà mú. 27Èéṣe tí ìwọ yọ́ lọ tí ìwọ sì tàn mi? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé ìwọ ń lọ, kí èmi fi ayọ̀ àti orin, pẹ̀lú ìlù àti ohun èlò orin sìn ọ́. 28Ìwọ kò tilẹ̀ jẹ́ kí èmi fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ mi lẹ́nu, pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin mi pé ó dìgbà? Ìwọ ṣiwèrè ní ohun tí ìwọ ṣe yìí. 29Mo ní agbára láti ṣe ọ ni ibi, ṣùgbọ́n ní òru àná, Ọlọ́run baba rẹ sọ fún mi pé, kí èmi ṣọ́ra, kí èmi má ṣe sọ ohun kan fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú. 30Nísinsin yìí, ìwọ ti lọ nítorí ìwọ fẹ́ láti padà lọ sí ilé baba rẹ, ṣùgbọ́n èéṣe tí ìwọ fi jí àwọn òrìṣà mi?”

31Jakọbu dá Labani lóhùn pé, “Ẹ̀rù ni ó bà mi nítorí, mo rò pé ìwọ le fi tipátipá gba àwọn ọmọbìnrin rẹ lọ́wọ́ mi. 32Ṣùgbọ́n bí o bá ri ẹnikẹ́ni pẹ̀lú ère rẹ, kí ẹni náà di òkú. Ó tún wí pé, Níwájú gbogbo ìbátan wa báyìí, wò ó fúnrarẹ̀, bí o bá rí ohunkóhun tí í ṣe tìrẹ, mú un.” Jakọbu kò sì mọ̀ pé, Rakeli ni ó jí àwọn òrìṣà náà.

33Labani sì lọ sínú àgọ́ Jakọbu àti ti Lea àti ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì, kò sì rí ohunkóhun. Lẹ́yìn ìgbà tí ó jáde nínú àgọ́ Lea ni ó lọ sí àgọ́ Rakeli. 34Rakeli sì gbé àwọn òrìṣà náà sínú gàárì ìbákasẹ, ó sì jókòó lé e lórí. Labani sì wá gbogbo inú àgọ́, kò sì rí ohunkóhun.

35Rakeli sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Má ṣe bínú pé èmi ò le dìde dúró níwájú rẹ baba à mi, ohun tí ó fà á ni pé, mò ń ṣe nǹkan oṣù lọ́wọ́.” Ó sì wá àgọ́ kiri, kò sì rí àwọn òrìṣà ìdílé náà.

36Inú sì bí Jakọbu, ó sì pe Labani ní ìjà pé, “Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ tí ìwọ fi ń lépa mi bí ọ̀daràn? 37Nísinsin yìí tí ìwọ ti tú gbogbo ẹrù mi wò, kí ni ohun tí í ṣe tirẹ̀ tí ìwọ rí? Kó wọn kalẹ̀ báyìí níwájú gbogbo ìbátan rẹ àti tèmi, kí wọn kí ó sì ṣe ìdájọ́ láàrín àwa méjèèjì.

38“Mo ti wà lọ́dọ̀ rẹ fún ogún ọdún, àwọn àgùntàn tàbí ewúrẹ́ rẹ kò sọnù bẹ́ẹ̀ n kò pa ọ̀kan jẹ rí nínú àwọn àgbò rẹ. 39Èmi kò mú ọ̀kankan wá fún ọ rí nínú èyí tí ẹranko búburú fàya, èmi ni ó fi ara mọ́ irú àdánù bẹ́ẹ̀. Ẹrankẹ́ran tí wọ́n bá sì jí lọ, lọ́sàn án tàbí lóru, ìwọ ń gba owó rẹ̀ lọ́wọ́ mi 40Báyìí ni mo wà; oòrùn ń pa mi lọ́sàn án, òtútù ń pa mi lóru, mo sì ń ṣe àìsùn. 41Báyìí ni ohun gbogbo rí fún ogún ọdún tí mo fi wà nínú ilé rẹ. Ọdún mẹ́rìnlá ni mo fi sìn ọ́ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì, mo sì sìn ọ fún ọdún mẹ́fà fún àwọn ẹran ọ̀sìn, lẹ́ẹ̀mẹ́wàá ni o sì yí owó iṣẹ́ mi padà. 42Bí ó bá ṣe pé Ọlọ́run àwọn baba mi, Ọlọ́run Abrahamu àti ẹ̀rù Isaaki kò wà pẹ̀lú mi ni, ìwọ ìbá ti lé mi jáde lọ́wọ́ òfo. Ṣùgbọ́n, Ọlọ́run ti rí gbogbo ìpọ́njú mi àti iṣẹ́ àṣekára tí mo fi ọwọ́ mi ṣe, ó sì kìlọ̀ fún ọ lóru àná.”

43Labani sì dá Jakọbu lóhùn, “Tèmi ni àwọn obìnrin wọ̀nyí, ọmọ mi ni àwọn ọmọ wọ̀nyí pẹ̀lú, àwọn agbo ẹran yìí, tèmi ni wọ́n pẹ̀lú. Gbogbo ohun tí o rí wọ̀nyí, tèmi ni. Kí ni mo wá le ṣe sí àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí àti àwọn ọmọ wọn tí wọn bí? 44Wá, jẹ́ kí a dá májẹ̀mú pẹ̀lú ara wa, èyí yóò sì jẹ́ ẹ̀rí ní àárín wa.”

45Jakọbu sì mú òkúta kan ó sì gbé e dúró bí ọ̀wọ́n. 46Ó sì wí fún àwọn ìbátan rẹ̀ pé, “Ẹ kó àwọn òkúta díẹ̀ jọ.” Wọ́n sì kó òkúta náà jọ bí òkìtì wọ́n sì jẹun níbẹ̀. 47Labani sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jegari-Sahaduta, ṣùgbọ́n Jakọbu pè é ni Galeedi.

48Labani sì wí pé, “Òkìtì yìí jẹ́ ẹ̀rí láàrín èmi àti ìwọ ní òní.” Ìdí nìyí tí a fi pe orúkọ rẹ̀ ni Galeedi. 49Ó tún pè é ni Mispa nítorí, ó wí pé, “Kí Olúwa kí ó máa ṣọ́ èmi àti ìwọ nígbà tí a bá yà kúrò lọ́dọ̀ ara wa tán. 50Bí o bá fìyà jẹ àwọn ọmọbìnrin mi, tàbí tí o fẹ́ aya mìíràn yàtọ̀ sí wọn, rántí pé, Ọlọ́run ń bẹ láàrín wa bí ẹlẹ́rìí bí ẹnikẹ́ni kò tilẹ̀ sí.”

51Labani tún sọ síwájú fún Jakọbu pé, “Òkìtì àti ọ̀wọ̀n tí mo gbé kalẹ̀ láàrín èmi àti ìwọ yìí, 52yóò jẹ́ ẹ̀rí wí pé èmi kò ni ré ọ̀wọ̀n àti òkìtì yìí kọjá láti bá ọ jà àti pé ìwọ pẹ̀lú kì yóò kọjá òkìtì tàbí ọ̀wọ̀n yìí láti ṣe mí ní ibi. 53Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run Abrahamu àti Ọlọ́run Nahori, àti Ọlọ́run baba wọn ṣe ìdájọ́ láàrín wa.”

Jakọbu sì fi ẹ̀rù Isaaki baba rẹ̀ búra. 54Jakọbu sì rú ẹbọ níbẹ̀ ni orí òkè, ó sì pe àwọn ẹbí rẹ̀ láti jẹun. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹun, ibẹ̀ náà ni wọ́n sùn ní ọjọ́ náà.

55Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Labani fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ lẹ́nu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì súre fún wọn. Labani sì padà lọ sí ilé.

New Serbian Translation

1. Мојсијева 31:1-55

Јаков бежи из Харана

1Чуо је Јаков да Лаванови синови говоре: „Јаков је присвојио све што припада нашем оцу. Све ово богатство је стекао од имовине нашег оца.“ 2Јаков је приметио и по Лавановом лицу да се овај према њему не држи као раније.

3Тада Господ рече Јакову: „Врати се у земљу својих отаца, у свој родни крај, и ја ћу бити с тобом.“

4Јаков је тада позвао Рахиљу и Лију у поље где је било његово стадо, 5и рекао им: „Видим по лицу вашег оца да се не држи према мени као раније. Али са мном је био Бог мога оца. 6Ви и саме знате да сам за вашег оца радио свом својом снагом. 7Међутим, ваш отац ме је варао и десет пута ми мењао плату. Ипак, Бог му није допустио да ми нанесе штету. 8Ако би он рекао: ’Свако шарено грло ће ти бити плата’, онда би цело стадо младило шарену младунчад. А ако би рекао: ’Свако пругасто грло ће ти бити плата’, онда би стадо младило пругасту младунчад. 9Тако је Бог узимао стоку од вашег оца и давао је мени.

10Једном, кад се стадо парило, у сну сам видео да су јарци који су се парили с козама били пругасти, местимично бели и шарени. 11Тада ме је Анђео Божији позвао у сну: ’Јакове!’ Ја се одазвах: ’Ево ме!’ 12Анђео ми рече: ’Подигни свој поглед и уочи да су сви јарци који се паре с козама, пругасти, местимично бели и шарени. Видео сам, наиме, све што ти је Лаван учинио. 13Ја сам Бог који ти се објавио у Ветиљу, где си помазао стуб и где си учинио завет са мном. Зато се сад спреми и напусти ову земљу, па се врати у своју родну земљу.’“

14Рахиља и Лија му одговоре на то: „Зар ми још имамо икакав део наследства у дому нашег оца? 15Није ли на нас гледао као на туђинке? Нас је продао, а новац који је за нас добио је потрошио! 16Све то богатство што га је Бог узео од нашег оца припада нама и нашој деци. Зато учини све што ти је Бог рекао.“

17Тада се Јаков спреми, те посади своју децу и своје жене на камиле. 18Затим потера сву своју стоку пред собом, сву своју имовину коју је стекао, стоку коју је сабрао у Падан-Араму, па се запути к своме оцу, Исаку, у хананску земљу.

19Кад је Лаван отишао да стриже своје овце, Рахиља је украла кућне идоле који су припадали њеном оцу. 20Јаков је, пак, заварао Лавана Арамејца тиме што није дао да овај наслути да ће он побећи. 21Тако је Јаков побегао са свим што је било његово. Прешао је реку Еуфрат и запутио се према галадском горју.

Лаван иде у потеру за Јаковом

22Трећег дана су јавили Лавану да је Јаков побегао. 23Овај је тада повео своје рођаке и кренуо у потеру за Јаковом седам дана хода. Стигао га је код брда Галад. 24Али Бог је дошао к Арамејцу Лавану ноћу, у сну и рекао му: „Пази да не предузимаш ништа против Јакова, ни добро ни зло.“

25Лаван је, дакле, стигао Јакова. Јаков је поставио свој шатор на једном брду, а Лаван је са својим рођацима поставио свој шатор на брду Галад. 26Лаван рече Јакову: „Шта си то урадио? Обмануо си ме и побегао са мојим ћеркама као да су ратне заробљенице. 27Зашто си тајно побегао и обмануо ме? Да си ми рекао да идеш ја бих те испратио с весељем и песмом, уз бубњеве и лире. 28А ниси ми дао ни да изљубим своју унучад и своје ћерке. Заиста си лудо поступио. 29У мојој је моћи да вам наудим. Али Бог твога оца ми је прошле ноћи рекао: ’Пази да не предузимаш ништа против Јакова, ни добро, ни зло.’ 30У реду, сад, отишао си јер си чезнуо за очинским домом, али зашто си украо моје богове?“

31Јаков одговори Лавану: „Био сам се уплашио, јер сам мислио да ћеш отети своје ћерке од мене. 32А ако код кога нађеш своје богове, тај неће остати на животу. Покажи овде пред нашим рођацима шта ја то имам код себе што је твоје, па носи!“ Јаков, наиме, није знао да је Рахиља украла идоле.

33Лаван је ушао у Јаковљев шатор, па у шатор Лије, те у шатор двеју слушкиња, али тамо ништа није нашао. Онда је изашао из Лијиног шатора и ушао у Рахиљин. 34Рахиља је, пак, узела идоле и ставила их у седло своје камиле и села на њих. Лаван је претражио цели шатор, али идоле није нашао.

35А Рахиља је рекла своме оцу: „Нека се не љути мој господар што не могу да устанем пред њим; снашло ме је, наиме, оно што обичава у жена.“ Тако је Лаван тражио, али није могао да нађе идоле.

36Тада је Јаков плануо и стао да се препире с Лаваном: „Које је то моје злодело и која је моја кривица, те ме тако прогањаш? 37Ево, испреметао си цело моје покућство, па какав си предмет из свога дома пронашао? Стави га овде, пред моју и твоју родбину, па нек они пресуде између нас двојице.

38За ових двадесет година колико сам био с тобом, твоје овце и козе се нису јаловиле, нити сам јео од овнова из твога стада. 39Оно што би дивља звер растргла, теби нисам доносио, него бих губитак сам надокнадио. То си захтевао од мене без обзира да ли је грло било украдено дању или ноћу. 40Дању ме је сатирала жега, а ноћу хладноћа. Сан се није спуштао на моје очи. 41Од ових двадесет година које сам провео у твојој кући, четрнаест година сам ти служио за твоје две ћерке, а шест година за твоје стадо, иако си ми мењао плату десет пута. 42Да са мном није био Бог мога оца, Бог Аврахамов и Страх Исаков, ти би ме отпустио празних руку. Али Бог је видео моју муку и труд мојих руку, те је синоћ пресудио.“

43Лаван одговори Јакову: „Ћерке су моје ћерке, деца су моја деца, стадо је моје стадо и све што видиш је моје. А ипак, шта данас могу да учиним овим својим ћеркама или деци коју су родиле? 44Стога, хајде да ја и ти склопимо савез, па да то буде сведок између мене и тебе.“

45Јаков је тада узео један камен и усправио га као стуб. 46Онда је рекао својим рођацима: „Сакупите камење.“ Они су узели камење и начинили од њега гомилу. Затим су заједно јели код те гомиле. 47Лаван ју је назвао Јегар-Сахадута31,47 Јегар-Сахадута на арамејском значи Гомила сведочанства., а Јаков је назвао Галед31,47 Галед на јеврејском значи исто што и Јегар-Сахадута на арамејском..

48Онда Лаван рече: „Нека ова гомила данас буде сведок између тебе и мене.“ Зато је названа Галед, 49али и Миспа, јер је Лаван рекао: „Нека Господ мотри на мене и на тебе кад не будемо видели један другога. 50Ако будеш злостављао моје ћерке, или ако поред мојих ћерки узмеш себи друге жене, па да и нико не буде био с нама, пази: Господ је сведок између мене и тебе.“

51Лаван још рече Јакову: „Ево, овде је гомила а овде је стуб који сам усправио да буде међа између мене и тебе. 52Сведок је ова гомила, а сведок је и овај стуб, да ја нећу прелазити ову гомилу да ти наудим, нити да ћеш ти прелазити овај стуб и ову гомилу да мени наудиш. 53Нека Бог Аврахамов и бог Нахоров, и бог њиховог оца, суде међу нама.“

Јаков се тада заклео Страхом свога оца Исака. 54Затим је Јаков принео жртву на брду и позвао своју родбину на обед. Након обеда су преноћили на брду.

55У рано јутро Лаван устане, изљуби своје унуке и ћерке и благослови их. Затим крене и врати се у своје место.