Gẹnẹsisi 24 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 24:1-67

Isaaki àti Rebeka

1Abrahamu sì ti di arúgbó ní àkókò yìí, Olúwa sì ti bùkún fún un ni gbogbo ọ̀nà, 2Abrahamu wí fún olórí àwọn ìránṣẹ́ ilẹ̀ rẹ̀, tí ó jẹ́ alábojútó ohun gbogbo tí ó ní pé, “Fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi. 3Èmi yóò mú ọ búra lórúkọ Olúwa Ọlọ́run ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ kì yóò fẹ́ aya fún ọmọ mi nínú àwọn ọmọbìnrin ará Kenaani, láàrín àwọn ẹni tí èmi ń gbé. 4Ṣùgbọ́n, ìwọ yóò lọ sí orílẹ̀-èdè mi, láàrín àwọn ará mi láti fẹ́ aya fún Isaaki, ọmọ mi.”

5Ìránṣẹ́ náà bi í wí pé, “Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà bá kọ̀ láti bá mi wá sí ilẹ̀ yìí ńkọ́? Ǹjẹ́ mo lè mú ọmọ rẹ padà lọ sí orílẹ̀-èdè níbi tí ìwọ ti wá?”

6Abrahamu sì wí fún un pé, “Rí i dájú pé ìwọ kò mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.” 7Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run tí ó mú mi jáde láti ilẹ̀ baba mi àti ní ilẹ̀ tí a bí mi, tí ó bá mi sọ̀rọ̀ tí ó sì búra fún mi pé, ‘Irú-ọmọ rẹ ni n ó fi ilẹ̀ yìí fún,’ yóò rán angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ, kí ìwọ kí ó lè rí aya fẹ́ wá fún ọmọ mi láti ibẹ̀. 8Bí obìnrin náà kò bá fẹ́ tẹ̀lé ọ wá, nígbà náà ni a tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ìbúra yìí, ṣùgbọ́n pàtàkì ni pé ìwọ kò gbọdọ̀ mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.” 9Ìránṣẹ́ náà sì fi ọwọ́ rẹ̀ sí abẹ́ itan Abrahamu olúwa rẹ̀, ó sì búra fún nítorí ọ̀rọ̀ náà.

10Ìránṣẹ́ náà sì mú ìbákasẹ mẹ́wàá, pẹ̀lú onírúurú ohun dáradára láti ọ̀dọ̀ olúwa rẹ̀, ó sì dìde ó sì lọ sí Aramu-Naharaimu, sí ìlú Nahori, 11Ó sì mú àwọn ìbákasẹ náà kúnlẹ̀ nítòsí kànga lẹ́yìn ìlú, ó ti ń di ọwọ́ ìrọ̀lẹ́ ní àkókò tí àwọn obìnrin máa ń lọ pọn omi.

12Ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa à mi; jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lónìí, sì fi àánú hàn fún Abrahamu olúwa mi. 13Kíyèsi i, mo dúró ní ẹ̀bá kànga omi yìí, àwọn ọmọbìnrin ìlú yìí sì ń jáde wá pọn omi. 14Jẹ́ kí ó ṣe pé nígbà tí mo bá wí fún ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin pe, ‘Jọ̀wọ́ sọ ládugbó rẹ kalẹ̀, kí n le mu omi,’ tí ó bá sì wí pé, ‘mu ún, èmi ó sì fún àwọn ìbákasẹ rẹ náà mu pẹ̀lú,’ jẹ́ kí ó ṣe èyí tí o yàn fún ìránṣẹ́ rẹ Isaaki. Nípa èyí ni n ó fi mọ̀ pé o ti fi àánú hàn fún olúwa mi.”

15Kí o tó di pé, ó parí àdúrà, Rebeka dé pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀. Ọmọ Betueli ni. Betueli yìí ni Milka bí fún Nahori arákùnrin Abrahamu. 16Ọmọbìnrin náà rẹwà, wúńdíá ni, kò sì tí ì mọ ọkùnrin, ó lọ sí ibi ìsun omi náà, ó sì pọn omi sínú ìkòkò omi, ó sì gbé e, ó ń gòkè bọ̀ kúrò níbi omi.

17Ìránṣẹ́ náà súré lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fun un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ni omi díẹ̀ nínú ìkòkò omi rẹ.”

18Òun náà dáhùn pé, “Mu, olúwa mi,” ó sì yára sọ ìkòkò omi náà ka ọwọ́ rẹ̀, ó sì fún un mu.

19Lẹ́yìn tí ó ti fún un ni omi mu tán, ó wí pé, “Èmi ó bu omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú títí wọn yóò fi mu àmutẹ́rùn.” 20Ó sì yára da omi inú ìkòkò omi rẹ̀ sínú ìbùmu, ó sáré padà lọ sí ibi omi láti pọn sí i wá fún àwọn ìbákasẹ, títí tí ó fi pọn fún gbogbo wọn. 21Láìsọ ọ̀rọ̀ kan, ìránṣẹ́ yìí ń wo ọmọbìnrin náà fínní fínní láti mọ̀ bóyá Ọlọ́run ti ṣe ìrìnàjò òun ní rere tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.

22Lẹ́yìn tí àwọn ìbákasẹ náà ti mu omi tán, ni ọkùnrin náà mú òrùka wúrà ààbọ̀ ìwọ̀n ṣékélì àti júfù méjì fún ọwọ́ rẹ̀, tí ìwọ̀n ṣékélì wúrà mẹ́wàá. 23Lẹ́yìn náà, ó béèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ í ṣe? Jọ̀wọ́ wí fún mi, ǹjẹ́ ààyè wà ní ilé baba rẹ láti wọ̀ sí ní alẹ́ yìí?”

24Ó dáhùn pé, “Betueli ọmọ tí Milka bí fún Nahori ni baba mi” 25Ó sì fi kún un pé, “Àwa ní koríko àti ṣakaṣaka tó pẹ̀lú, àti ààyè láti wọ̀ sí.”

26Nígbà náà ni ọkùnrin náà tẹríba, ó sì sin Olúwa, 27wí pe, “Olùbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi ti kò jẹ́ kí àánú àti òtítọ́ rẹ̀ kí ó yẹ̀ lọ́dọ̀ olúwa mi. Ní ti èmi Olúwa ti darí ìrìnàjò mi sí ilé ìbátan olúwa mi.”

28Ọmọbìnrin náà sì sáré, ó sì lọ sọ ohun gbogbo wọ̀nyí fún àwọn ará ilé ìyá rẹ̀. 29Rebeka ní arákùnrin tí ń jẹ́ Labani; Labani sì sáré lọ bá ọkùnrin náà ní etí odò. 30Bí ó sì ti rí òrùka imú àti ẹ̀gbà ní ọwọ́ arábìnrin rẹ̀ tí ó sì tún gbọ́ ohun tí Rebeka sọ pé ọkùnrin náà sọ fún òun, ó jáde lọ bá ọkùnrin náà, ó sì bá a, ó dúró ti ìbákasẹ wọ̀n-ọn-nì ní ẹ̀bá ìsun omi. 31Ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Wá, ìwọ ẹni ìbùkún Olúwa, Èéṣe tí o dúró sí ìta níhìn-ín? Mo ti pèsè ààyè sílẹ̀ fún ọ àti ààyè fún àwọn ìbákasẹ rẹ.”

32Ọkùnrin náà sì bá Labani lọ ilé, ó sì tú ẹrù orí ìbákasẹ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fún wọn ni koríko àti oúnjẹ. Ó sì bu omi fún ọkùnrin náà àti àwọn arákùnrin rẹ̀ láti wẹ ẹsẹ̀ wọn. 33Wọ́n sì gbé oúnjẹ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n, ó wí pé, “Èmi kò ní jẹun àyàfi bí mo bá sọ ohun tí mo ní í sọ.”

Labani sì wí pé, “Kò burú, sọ ọ́.”

34Nítorí náà, ó wí pé, “ìránṣẹ́ Abrahamu ni èmi. 35Olúwa sì ti bùkún olúwa mi gidigidi. Ó sì ti di ọlọ́rọ̀, Ó sì ti fún un ní àgùntàn, màlúù, àti fàdákà àti wúrà, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin àti ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. 36Sara aya olúwa mi sì ti bí ọmọkùnrin kan fún un, ní ìgbà ogbó rẹ̀, olúwa mi sì ti fún ọmọ náà ní ohun gbogbo tí ó ní. 37Olúwa mi sì ti mú mi búra wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani, ní ilẹ̀ ibi tí èmi ń gbé, 38Ṣùgbọ́n lọ sí ìdílé baba mi láàrín àwọn ìbátan mi kí o sì fẹ́ aya fún ọmọ mi.’

39“Mo sì bí olúwa mi léèrè pé, ‘Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà kò bá fẹ́ bá mi wá ńkọ́?’

40“Ó sì dáhùn wí pé, ‘Olúwa, níwájú ẹni tí èmi ń rìn yóò rán Angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ yóò sì jẹ́ kí o ṣe àṣeyọrí ní ìrìnàjò rẹ, kí ìwọ kí ó ba le fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ìbátan mi, àti láàrín àwọn ìdílé baba mi. 41Nígbà tí ìwọ bá lọ sí ọ̀dọ̀ ìdílé baba mi (gẹ́gẹ́ bí mo tí wí), nígbà náà ni ìwọ tó bọ́ nínú ìbúra yìí.’

42“Nígbà tí mo dé ibi ìsun omi lónìí, mo wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, bí ìwọ bá fẹ́, jọ̀wọ́ jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lórí ohun tí mo bá wá yìí, 43Wò ó, mo dúró ní ẹ̀bá ìsun omi yìí, kí ó ṣe pé, nígbà tí wúńdíá kan bá jáde wá pọn omi, tí èmi sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ìwọ̀nba omi díẹ̀ mu nínú ládugbó rẹ,” 44tí ó bá sì wí fún mi pé, “Mu ún, èmi yóò sì tún pọn omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú,” Jẹ́ kí ẹni náà jẹ́ ẹni tí Olúwa yàn fún ọmọ Abrahamu, olúwa mi.’

45“Kí n sì tó gbàdúrà tán nínú ọkàn mi, Rebeka jáde wá pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀, ó sì lọ sí ibi ìsun omi ó sì pọn omi. Mo sì wí fun un pé, ‘Jọ̀wọ́ fún mi ni omi mu.’

46“Kíákíá ni ó sọ ìkòkò rẹ̀ kalẹ̀ láti èjìká rẹ̀, ó sì wí fún mi pé, ‘Mu ún, èmi yóò sì tún fún àwọn ìbákasẹ rẹ mu pẹ̀lú.’ Mo sì mu, ó sì tún fún àwọn ìbákasẹ mi mu pẹ̀lú.

47“Mo béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, ‘Ọmọ ta ní ìwọ í ṣe?’

“Ó sì wí fún mi pé, ‘ọmọbìnrin Betueli tí í ṣe ọmọ Nahori ni òun, Milka sì ni ìyá òun.’

“Nígbà náà ni mo fi òrùka náà bọ imú rẹ̀, mo sì fi ẹ̀gbà ọwọ́ náà si ní ọwọ́. 48Èmi sì tẹríba, mo sì wólẹ̀ fún Olúwa, mó sì fi ìbùkún fún Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, ẹni tí ó mú mi tọ ọ̀nà títọ́ láti rí ọmọ ọmọ arákùnrin olúwa mi mú wá fún ọmọ rẹ̀. 49Ǹjẹ́ nísinsin yìí bí ẹ̀yin yóò bá fi inú rere àti òtítọ́ bá olúwa mi lò, ẹ sọ fún mi, bí bẹ́ẹ̀ sì kọ́, ẹ sọ fún mi, kí ń le è mọ ọ̀nà tí èmi yóò yà sí.”

50Labani àti Betueli sì dáhùn pé, “Lọ́dọ̀ Olúwa ni èyí ti wá, nítorí náà àwa kò le sọ rere tàbí búburú fún ọ. 51Rebeka nìyí, mú un kí ó máa lọ, kí ó sì di aya ọmọ olúwa à rẹ, bí Olúwa ti fẹ́.”

52Nígbà tí ọmọ ọ̀dọ̀ Abrahamu gbọ́ ohun tí wọ́n wí, ó wólẹ̀ níwájú Olúwa. 53Nígbà náà ni ó kó ohun èlò wúrà àti fàdákà jáde àti aṣọ, ó sì fi wọ́n fún Rebeka, ó fún arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ ní ẹ̀bùn olówó iyebíye pẹ̀lú. 54Lẹ́yìn náà ni òun àti àwọn ọkùnrin tí ó bá a wá tó jẹ, tí wọ́n sì mu, tí wọn sì sùn níbẹ̀ ní òru ọjọ́ náà.

Bí wọ́n ti dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó wí pé, “Ẹ rán mi padà lọ sí ọ̀dọ̀ olúwa mi.”

55Ṣùgbọ́n arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ fèsì pé, “A fẹ́ kí Rebeka wà pẹ̀lú wa fún nǹkan bí ọjọ́ mẹ́wàá sí i, lẹ́yìn èyí, ìwọ le máa mu lọ.”

56Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá mi dúró, Olúwa sá à ti ṣe ọ̀nà mi ní rere. Ẹ rán mi lọ, kí èmi kí ó le è tọ olúwa à mi lọ.”

57Nígbà náà ni wọ́n sọ pé, “Jẹ́ kí a pe ọmọ náà gan an kí a sì bi í” 58Wọ́n sì pe Rebeka wọ́n sì bi í, wí pé, “Ṣe ìwọ yóò bá ọkùnrin yìí lọ.”

Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi yóò lọ.”

59Wọ́n sì gbà kí Rebeka àti olùtọ́jú rẹ̀, pẹ̀lú ìránṣẹ́ Abrahamu àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ máa lọ. 60Wọ́n sì súre fún Rebeka, wọn sì wí fun un pé,

“Ìwọ ni arábìnrin wa,

ìwọ yóò di ìyá ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún;

Ǹjẹ́ kí àwọn irú-ọmọ rẹ

kí ó ni ẹnu ibodè ọ̀tá wọn.”

61Nígbà náà ni Rebeka àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ múra, wọn sì gun àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì bá ọkùnrin náà padà lọ. Ìránṣẹ́ náà sì mú Rebeka, ó sì bá tirẹ̀ lọ.

62Isaaki sì ń ti ọ̀nà kànga Lahai-Roi bọ, nítorí ìhà gúúsù ni ó ń gbé. 63Isaaki sì jáde lọ sí oko ni ìrọ̀lẹ́ láti ṣe àṣàrò, bí ó sì ti gbé ojú sókè, ó rí àwọn ìbákasẹ tí ń bọ̀ wá. 64Rebeka pẹ̀lú sì gbójú sókè, ó sì rí Isaaki. Ó sọ̀kalẹ̀ lórí ìbákasẹ, 65Ó sì béèrè lọ́wọ́ ìránṣẹ́ náà wí pé, “Ta ni ọkùnrin tí ń bọ̀ wá pàdé wa láti inú oko?”

Ìránṣẹ́ náà sì wí fun un pé, “Olúwa mi ni,” nítorí náà ni Rebeka mú ìbòjú, ó sì bo ojú rẹ̀.

66Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà ròyìn fún Isaaki ohun gbogbo tí ó ti ṣe. 67Nígbà náà ni Isaaki mú Rebeka wọ inú àgọ́ ìyá rẹ̀, Sara, ó sì di aya rẹ̀, ó sì fẹ́ràn rẹ̀; ó sì jẹ́ ìtùnú fún Isaaki lẹ́yìn ikú ìyá rẹ̀.

Bibelen på hverdagsdansk

1. Mosebog 24:1-67

En brud til Isak

1Abraham var nu blevet en gammel mand og havde oplevet Herrens rige velsignelse.

2En dag kaldte han på sin ældste og mest betroede tjener, som havde ansvar for alt, hvad han ejede: „Læg din hånd under min lænd,” sagde han, 3„og sværg ved Herren, Himlens og jordens Gud, at du aldrig vil lade min søn gifte sig med en af de kana’anæiske piger, som vi bor iblandt. 4Rejs til mit hjemland og min slægt og find en kone til Isak der.”

5„Men hvad nu, hvis pigen ikke er villig til at rejse tilbage sammen med mig?” spurgte tjeneren. „Skal jeg så bringe Isak tilbage til dit gamle fædreland, så han kan slå sig ned der?”

6„Nej,” sagde Abraham. „Det må du under ingen omstændigheder gøre! 7For Herren, Himlens Gud, gav mig ordre til at forlade mit land og mit folk, og han lovede at give mig og mine efterkommere det land, vi nu bor i som fremmede. Herren vil sende sin engel i forvejen og sørge for, at du finder den pige, som skal være min søns brud. 8Hvis pigen ikke vil følge med dig tilbage, er du løst fra din ed, men du må under ingen omstændigheder bringe min søn tilbage til mit hjemland!” 9Så lagde tjeneren hånden under sin herres lænd og svor på, at han ville gøre, som Abraham havde sagt.

10Derpå tog tjeneren ti af Abrahams kameler og alle slags kostbare gaver, og begav sig på vej til Nakors by i Aram-Naharajim.24,10 Det vil sige Aram mellem de to floder i det nordlige Mesopotamien. 11Da han nåede frem, lod han kamelerne lægge sig ned ved brønden uden for byen. Det var hen ad aften—ved den tid, hvor byens kvinder gik ud til brønden for at hente vand.

12„Herre, du, min herres Gud!” bad han. „Vis godhed mod min herre Abraham og lad det lykkes for mig at udføre den opgave, han har pålagt mig. 13Jeg stiller mig her ved brønden, nu hvor byens unge kvinder kommer ud for at hente vand. 14Når jeg så spørger en af dem, om jeg må få en slurk vand, og hun svarer: ‚Drik kun, og lad mig også sørge for, at dine kameler får noget at drikke!’—lad det så være hende, du har udset til at blive Isaks kone. På den måde vil jeg være klar over, at du har været nådig mod min herre!”

15-16Endnu mens han bad, kom en ung pige gående hen mod brønden med sin vandkrukke på skulderen. Hun hed Rebekka og var datter af Betuel, en søn af Milka og Nakor, Abrahams bror. Rebekka var meget smuk, og hun var jomfru. Hun gik ned til brønden og fyldte sin krukke. Da hun kom op igen, 17skyndte tjeneren sig hen til hende og sagde: „Giv mig lidt vand fra din krukke!”

18„Gerne!” svarede hun og tog krukken ned fra skulderen, så han kunne drikke. 19Da han havde slukket sin tørst, tilføjede hun: „Lad mig også sørge for, at dine kameler får noget at drikke!” 20Straks løb hun hen til vandtruget og tømte sin krukke. Derefter hentede hun mere vand og hældte det i truget, indtil kamelerne var færdige med at drikke. 21Imens stod tjeneren og betragtede hende i tavshed—spændt på, om Gud havde ladet hans rejse lykkes.

22Da kamelerne endelig havde slukket deres tørst, gav tjeneren pigen en guldnæsering24,22 Teksten tilføjer: „som vejede en halv shekel”, dvs. ca. 8 g. og satte to tunge guldarmbånd på hendes arme.24,22 Teksten tilføjer: „som vejede ti shekel”, ca. 160 g. 23„Sig mig, hvem du er datter af,” sagde han, „og om der er plads i din fars hus, så jeg og mine folk kan få husly der i nat.”

24Hun svarede: „Jeg er datter af Betuel, som er Milkas og Nakors søn. 25Vi har masser af halm og foder og plads, så I kan overnatte hos os.”

26Ved disse ord bøjede tjeneren sig og lovpriste Gud. 27„Tak Herre, du min herre Abrahams Gud,” udbrød han. „Tak for din godhed og trofasthed imod min herre, og tak, fordi du førte mig direkte til min herres slægtninge.”

28Imidlertid løb pigen hjem og fortalte sin familie, hvad der var sket. 29-30Da hendes bror Laban så næseringen og armbåndene på sin søsters arme og hørte hende fortælle, hvad manden havde sagt til hende, skyndte han sig ud til brønden, hvor manden stadig stod med sine kameler. 31„Velkommen, kære ven,” sagde han. „Kom dog og vær vores gæst! Hvorfor står du herude? Vi har allerede gjort klar til at modtage dig og dine kameler.”

32Så fulgte manden med Laban hjem. Bagagen blev læsset af kamelerne og Laban sørgede for halm og foder til dem. Så bragte han vand til den gamle tjener og hans kameldrivere, så de kunne vaske deres fødder. 33Derefter blev der serveret mad, men Abrahams tjener sagde: „Jeg vil ikke spise noget, før jeg har fortalt jer om mit ærinde.”

„Sig frem!” svarede Laban.

34„Jeg er Abrahams tjener,” begyndte manden. 35„Herren har velsignet min herre i rigt mål, så han er blevet en velhavende mand med masser af får, kvæg, sølv og guld, tjenere, kameler og æsler.

36Min herres kone, Sara, fødte ham en søn i hans alderdom, og den søn har han givet alt, hvad han ejer. 37Og nu har min herre ladet mig sværge på, at jeg ikke vil lade hans søn gifte sig med en af de lokale kana’anæiske piger. 38I stedet bad han mig tage hertil og opsøge hans slægt og finde en brud til hans søn. 39‚Hvad nu, hvis jeg ikke kan finde en pige, der vil følge med tilbage?’ spurgte jeg. 40Han svarede: ‚Den Herre, i hvis nærhed jeg har levet mit liv, vil sende sin engel i forvejen og lade din rejse lykkes, så du kan finde min søn en kone fra min egen slægt. 41Hvis ikke, er du løst fra din ed. Det samme er tilfældet, hvis hendes familie ikke vil lade hende følge med dig.’

42Da jeg i dag gjorde holdt ved brønden, bad jeg følgende bøn: ‚Herre, du min herre Abrahams Gud! Lad det ærinde lykkes, som jeg er kommet for at udføre. 43Jeg stiller mig her ved brønden, og så siger jeg til en af pigerne, der kommer for at hente vand: „Giv mig lidt vand at drikke fra din krukke!” 44Hvis pigen så svarer: „Drik kun, og lad mig også sørge for dine kameler!”—lad det da være tegnet på, at det er den pige, du har udset til min herres søn.’

45Mens jeg endnu bad, kom Rebekka gående med sin vandkrukke på skulderen. Hun gik ned til brønden og fyldte krukken. Da jeg sagde: ‚Giv mig lidt vand at drikke fra din krukke!’ 46sænkede hun straks krukken og gav mig vand, idet hun sagde: ‚Drik kun, herre, og lad mig også sørge for, at dine kameler får noget at drikke!’ Så drak jeg, og hun sørgede for kamelerne. 47Bagefter sagde jeg til hende: ‚Sig mig, hvem du er datter af.’ Hun svarede: ‚Min far hedder Betuel og er søn af Milka og Nakor.’ Da gav jeg hende næseringen og satte armbåndene på hendes arme. 48Og jeg takkede min herre Abrahams Gud, fordi han havde ledt mig hele vejen, til jeg stod over for min herres brors barnebarn, der skulle være hans søns brud. 49Derfor vil jeg nu gerne vide, om I vil opfylde min herres ønske. Jeg vil gerne have et klart svar, ja eller nej, så jeg ved, hvad jeg har at rette mig efter.”

50Da svarede Laban og Betuel: „Det er helt klart, at Herren har ført dig herhen! Hvad kan vi sige mere? 51Tag kun Rebekka med dig! Lad hende gifte sig med din herres søn, sådan som Herren har bestemt det.”

52Ved de ord bøjede Abrahams tjener sig med ansigtet mod jorden og lovpriste Herren. 53Så hentede han smykker af sølv og guld tillige med smukke dragter, som han gav til Rebekka. Også hendes bror og mor fik gaver. 54Så spiste han og hans ledsagere til aften og overnattede i huset. Da de var stået op næste morgen, sagde han: „Lad mig nu tage tilbage til min herre.”

55„Vi vil gerne beholde Rebekka en halv snes dage endnu,” svarede pigens bror og mor. „Derefter kan I tage af sted.”

56„Ophold mig ikke længere end nødvendigt,” bad tjeneren. „Herren har jo ladet mit ærinde lykkes, og jeg må tilbage til min herre.”

57„Lad os kalde på pigen og lade hende afgøre sagen,” svarede de. 58Så kaldte de på Rebekka og spurgte hende: „Er du parat til at rejse med denne mand?”

„Ja, jeg er,” svarede hun.

59De tog så afsked med Rebekka. Den kvinde, som havde passet Rebekka fra lille, fik besked på også at tage med. 60Familien velsignede Rebekka med følgende ord: „Må dine efterkommere blive talt i tusinder! Må dine efterkommere besejre alle deres fjender!”

61Så satte Rebekka og hendes tjenestepiger sig op på kamelerne og fulgte med Abrahams tjener.

62I mellemtiden ventede Isak hjemme hos sin far. Han boede ellers selv i Negev, ved brønden Be’er-Lahaj-Roi.24,62 Navnet betyder: „Den levende, som ser”. 63En dag hen imod aftenstid, da han gik sig en tur ude på marken fordybet i egne tanker, så han op og fik øje på en karavane af kameler, der nærmede sig. 64Da Rebekka fik øje på ham, gjorde hun straks holdt og steg af sin kamel.

65„Hvem er den mand, der kommer gående dér på marken for at møde os?” spurgte hun Abrahams tjener.

„Det er min herres søn,” svarede tjeneren. Da skyndte hun sig at trække sløret for ansigtet. 66Så fortalte tjeneren hele historien til Isak.

67Isak førte nu Rebekka ind i sin mors telt, og hun blev hans kone. Han kom til at holde meget af hende, og hun var til stor trøst for ham efter tabet af moderen.